< Jeremiah 28 >

1 Ní oṣù karùn-ún ní ọdún kan náà, ọdún kẹrin ní ìbẹ̀rẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọba Juda, wòlíì Hananiah ọmọ Assuri, tí ó wá láti Gibeoni, sọ fún mi ní ilé Olúwa tí ó wà ní iwájú àwọn àlùfáà àti gbogbo ènìyàn:
And it was don in that yeer, in the bigynnyng of the rewme of Sedechie, kyng of Juda, in the fourthe yeer, in the fyuethe monethe, Ananye, the sone of Azur, a profete of Gabaon, seide to me in the hous of the Lord, bifor the preestis, and al the puple,
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi yóò mú àjàgà ọba Babeli rọrùn.
`and seide, The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Y haue al to-broke the yok of the kyng of Babiloyne.
3 Láàrín ọdún méjì, Èmi yóò mú gbogbo ohun èlò tí ọba Nebukadnessari; ọba Babeli kó kúrò ní ilé Olúwa tí ó sì kó lọ sí Babeli padà wá.
Yit twei yeeris of daies ben, and Y schal make to be brouyt ayen to this place alle the vessels of the Lord, whiche Nabugodonosor, kyng of Babiloyne, took fro this place, and translatide tho in to Babiloyne.
4 Èmi á tún mú ààyè Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda padà, àti gbogbo àwọn tí ń ṣe àtìpó láti Juda ní Babeli,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘àjàgà yín láti ọwọ́ ọba Babeli yóò rọrùn.’”
And Y schal turne to this place, seith the Lord, Jeconye, the sone of Joachym, the kyng of Juda, and al the passyng ouer of Juda, that entriden in to Babiloyne; for Y schal al to-breke the yok of the kyng of Babiloyne.
5 Wòlíì Jeremiah wí fún wòlíì Hananiah ní iwájú ọmọ àlùfáà àti àwọn ènìyàn tí wọ́n dúró ní ilé Olúwa.
And Jeremye, the profete, seide to Ananye, the profete, bifore the iyen of preestis, and bifore the iyen of al the puple that stoden in the hous of the Lord.
6 Jeremiah wòlíì wí pé, “Àmín! Kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀! Kí Olúwa kí ó mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ìwọ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ṣẹ, láti mú ohun èlò ilé Olúwa àti gbogbo àwọn ìgbèkùn láti ilẹ̀ Babeli padà wá sí ibí yìí.
And Jeremye, the profete, seide to Ananye, Amen! so do the Lord; the Lord reise thi wordis whiche thou profesiedist, that the vessels be brouyt ayen in to the hous of the Lord, and al the passyng ouer fro Babiloyne, to this place.
7 Nísinsin yìí, ìwọ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí tí mo sọ sí etí rẹ àti sí etí gbogbo ènìyàn.
Netheles here thou this word, which Y speke in thin eeris, and in the eeris of al the puple.
8 Ní ìbẹ̀rẹ̀ àwọn wòlíì tí ó ṣáájú rẹ àti èmi ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ogun, ibi àti àjàkálẹ̀ sí ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè.
Profetis that weren bifore me, and bifor thee, fro the bigynnyng, and profesieden on many londis, and on many rewmes, of batel, and of turment, and of hungur.
9 Ṣùgbọ́n, àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ àlàáfíà ni a mọ̀ gẹ́gẹ́ bí wòlíì olóòtítọ́ tí Olúwa rán, tí àsọtẹ́lẹ̀ rẹ bá wá sí ìmúṣẹ.”
The profete that profesiede pees, whanne his word cometh, shal be knowun the profete whom the Lord sente in treuthe.
10 Wòlíì Hananiah gbé àjàgà ọrùn wòlíì Jeremiah kúrò, ó sì fọ́ ọ.
And Ananye, the profete, took the chayne fro the necke of Jeremye, the profete, and brak it.
11 Hananiah sọ níwájú gbogbo ènìyàn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Bákan náà ni Èmi yóò fọ́ àjàgà ọrùn Nebukadnessari, ọba Babeli láàrín ọdún méjì.’” Wòlíì Jeremiah sì bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ.
And Ananye, the profete, seide in the siyt of al the puple, `and seide, The Lord seith these thingis, So Y schal breke the yok of Nabugodonosor, kyng of Babiloyne, aftir twei yeeris of daies, fro the necke of alle folkis.
12 Láìpẹ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì wá lẹ́yìn ìgbà tí wòlíì Hananiah ti gbé àjàgà kúrò ní ọrùn wòlíì Jeremiah wí pé:
And Jeremye, the profete, yede in to his weie. And the word of the Lord was maad to Jeremye, aftir that Ananye, the profete, brak the chayne fro the necke of Jeremye; and the Lord seide,
13 “Lọ sọ fún Hananiah, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ìwọ ti wó àjàgà onígi, ṣùgbọ́n ní ààyè wọn, wà á bá àjàgà onírin.
Go thou, and seie to Ananye, The Lord seith these thingis, Thou hast al to-broke the chaynes of tre, and thou schalt make yrun chaynes for tho.
14 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi yóò fi àjàgà onírin sí ọrùn gbogbo orílẹ̀-èdè láti lè máa sin Nebukadnessari ọba Babeli, àti pé gbogbo yín ni ẹ̀ ó máa sìn ín. Èmi yóò tún fún un ní àṣẹ lórí àwọn ẹranko búburú.’”
For the Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Y haue set an yrun yok on the necke of alle these folkis, that thei serue Nabugodonosor, the king of Babiloyne, and thei schulen serue hym; ferthermore and Y yaf to hym the beestis of erthe.
15 Wòlíì Jeremiah sọ fún wòlíì Hananiah pé, “Gbọ́ ọ, Hananiah! Olúwa kò rán ọ, síbẹ̀, ìwọ jẹ́ kí orílẹ̀-èdè yìí gba irọ́ gbọ́.
And Jeremye, the profete, seide to Ananye, the profete, Ananye, here thou; the Lord sente not thee, and thou madist this puple for to triste in a leesyng.
16 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Mo ṣetán láti mú ọ kúrò nínú ayé, ní ọdún yìí ni ìwọ yóò kú nítorí o ti wàásù ọ̀tẹ̀ sí Olúwa.’”
Therfor the Lord seith these thingis, Lo! Y schal sende thee out fro the face of erthe; in this yeer thou schalt die, for thou spakest ayens the Lord.
17 Ní oṣù keje ọdún yìí ni Hananiah wòlíì kú.
And Ananye, the profete, diede in that yeer, in the seuenthe monethe.

< Jeremiah 28 >