< Jeremiah 28 >
1 Ní oṣù karùn-ún ní ọdún kan náà, ọdún kẹrin ní ìbẹ̀rẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọba Juda, wòlíì Hananiah ọmọ Assuri, tí ó wá láti Gibeoni, sọ fún mi ní ilé Olúwa tí ó wà ní iwájú àwọn àlùfáà àti gbogbo ènìyàn:
To saning thung, Judah siangpahrang Zedekiah prae uk amtonghaih saning palito haih, khrah pangato naah, Gibeon ah kaom tahmaa Azzur capa Hananiah mah, Angraeng im ah, qaimanawk hoi kaminawk boih hmaa ah, ang thuih ih lok loe,
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Èmi yóò mú àjàgà ọba Babeli rọrùn.
misatuh kaminawk ih Angraeng, Israel Sithaw mah, Babylon sianhgpahrang ih hnam to ka khaeh pae boeh, tiah thuih.
3 Láàrín ọdún méjì, Èmi yóò mú gbogbo ohun èlò tí ọba Nebukadnessari; ọba Babeli kó kúrò ní ilé Olúwa tí ó sì kó lọ sí Babeli padà wá.
Babylon siangpahrang Nebuchadnezzar mah, hae ahmuen hoi ah lak moe, Babylon ah sin ving ih, Angraeng imthung ih laom sabaenawk boih to saning hnetto thungah hae ahmuen ah ka sin let han.
4 Èmi á tún mú ààyè Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda padà, àti gbogbo àwọn tí ń ṣe àtìpó láti Juda ní Babeli,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘àjàgà yín láti ọwọ́ ọba Babeli yóò rọrùn.’”
Judah siangpahrang Jehoiakim capa Jekoniah doeh, Babylon ah misong ah kalaem Judah kaminawk boih hoi nawnto, hae ahmuen ah ka hoih let han, nihcae ih hnam to ka khaeh pae boeh, tiah Angraeng mah thuih, tiah a naa.
5 Wòlíì Jeremiah wí fún wòlíì Hananiah ní iwájú ọmọ àlùfáà àti àwọn ènìyàn tí wọ́n dúró ní ilé Olúwa.
Tahmaa Jeremiah mah, qaimanawk hoi Angraeng ih im thungah angdoe kaminawk boih mikhnuk ah tahmaa Hananiah khaeah lok a thuih pae.
6 Jeremiah wòlíì wí pé, “Àmín! Kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀! Kí Olúwa kí ó mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ìwọ sọ àsọtẹ́lẹ̀ ṣẹ, láti mú ohun èlò ilé Olúwa àti gbogbo àwọn ìgbèkùn láti ilẹ̀ Babeli padà wá sí ibí yìí.
Tahmaa Jeremiah mah, anih khaeah, Amen! Angraeng mah sah nasoe! Angraeng im ih laom sabaenawk boih, hae ahmuen hoiah Babylon ah misong ah caeh kaminawk kawng pongah, na thuih ih lok baktih toengah Angraeng mah koepsak nasoe!
7 Nísinsin yìí, ìwọ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí tí mo sọ sí etí rẹ àti sí etí gbogbo ènìyàn.
Toe nangmah hoi kaminawk boih khaeah, vaihi ka thuih ih lok hae tahngai ah;
8 Ní ìbẹ̀rẹ̀ àwọn wòlíì tí ó ṣáájú rẹ àti èmi ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ogun, ibi àti àjàkálẹ̀ sí ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè.
kai hoi nangcae om ai nathuem, canghnii ah kaom tahmaanawk mah kapop parai praenawk hoi misa ohhaih kawng, thacak praenawk hoi misa angcoenghaih kawng, misa angtukhaih kawng, kasae tonghaih hoi kasae nathaih kawngnawk to a thuih o.
9 Ṣùgbọ́n, àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ àlàáfíà ni a mọ̀ gẹ́gẹ́ bí wòlíì olóòtítọ́ tí Olúwa rán, tí àsọtẹ́lẹ̀ rẹ bá wá sí ìmúṣẹ.”
Misa amdinghaih kawng kathui, tahmaa mah thuih ih lok to koep naah ni, to tahmaa loe Angraeng mah patoeh tangtang, tiah panoek o tih, tiah a naa.
10 Wòlíì Hananiah gbé àjàgà ọrùn wòlíì Jeremiah kúrò, ó sì fọ́ ọ.
To naah tahmaa Hananiah mah tahmaa Jeremiah tahnong pong ih hnam to lak moe, a khaeh pae.
11 Hananiah sọ níwájú gbogbo ènìyàn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Bákan náà ni Èmi yóò fọ́ àjàgà ọrùn Nebukadnessari, ọba Babeli láàrín ọdún méjì.’” Wòlíì Jeremiah sì bá ọ̀nà tirẹ̀ lọ.
Hananiah mah kaminawk boih hmaa ah, Babylon siangpahrang Nebuchadnezzar mah, prae kaminawk ih tahnong ah bang ih hnam to saning hnetto thung, hae tiah ka khaeh pae boih han, tiah Angraeng mah thuih, tiah a naa. To naah tahmaa Jeremiah mah anih to caehtaak ving.
12 Láìpẹ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì wá lẹ́yìn ìgbà tí wòlíì Hananiah ti gbé àjàgà kúrò ní ọrùn wòlíì Jeremiah wí pé:
Tahmaa Jeremiah tahnong pong ih hnam to tahmaa Hananiah mah khaeh pae pacoengah, Angraeng ih lok tahmaa Jeremiah khaeah angzoh,
13 “Lọ sọ fún Hananiah, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ìwọ ti wó àjàgà onígi, ṣùgbọ́n ní ààyè wọn, wà á bá àjàgà onírin.
Caeh ah loe, Hananiah khaeah, Angraeng mah, Thing hoi sak ih hnam to na khaeh pae; toe sum hoi sak ih hnam to na hnu tih, tiah thuih, tiah thui paeh, tiah a naa.
14 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi yóò fi àjàgà onírin sí ọrùn gbogbo orílẹ̀-èdè láti lè máa sin Nebukadnessari ọba Babeli, àti pé gbogbo yín ni ẹ̀ ó máa sìn ín. Èmi yóò tún fún un ní àṣẹ lórí àwọn ẹranko búburú.’”
Nihcae mah Babylon siangpahrang Nebukhanezzar ih toksak pae o hanah, sum hoi sak ih hnam to hae prae kaminawk boih ih tahnong ah ka suek pae han; nihcae mah anih ih tok to sah pae o tih; taw ah kaom moisannawk doeh anih han ka paek boih boeh, tiah misatuh kaminawk ih Angraeng, Israel Sithaw mah thuih.
15 Wòlíì Jeremiah sọ fún wòlíì Hananiah pé, “Gbọ́ ọ, Hananiah! Olúwa kò rán ọ, síbẹ̀, ìwọ jẹ́ kí orílẹ̀-èdè yìí gba irọ́ gbọ́.
To pacoengah tahmaa Jeremiah mah, tahmaa Hananiah khaeah, Hananiah, vaihi tahngai ah! Nang loe Angraeng mah patoeh ih kami na ai ni; toe hae kaminawk mah na thuih ih amsawnlok to tang o thai hanah, na zoek khing.
16 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Mo ṣetán láti mú ọ kúrò nínú ayé, ní ọdún yìí ni ìwọ yóò kú nítorí o ti wàásù ọ̀tẹ̀ sí Olúwa.’”
To pongah Angraeng mah hae tiah thuih; Khenah, long hoiah kang takhoe ving han; Angraeng ih lok aek hanah na patuk pongah, vaining saning thungah na dueh tih, tiah a naa.
17 Ní oṣù keje ọdún yìí ni Hananiah wòlíì kú.
To na saning khrah sarihto naah tahmaa Hananiah to duek.