< Jeremiah 27 >

1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé.
В начале царства Иоакима сына Иосиина, царя Иудина, бысть слово сие ко Иеремии от Господа глаголя:
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ṣe àjàgà àti ọ̀pá irin fún ara rẹ, kí o sì fiwé ọrùn rẹ.
тако рече Господь: сотвори себе узы и клады и возложи на выю свою,
3 Kí o rán ọ̀rọ̀ sí ọba ti Edomu, Moabu, Ammoni, Tire àti Sidoni láti ọwọ́ àwọn ikọ̀ tí ó wá sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ Sedekiah ọba Juda.
и да послеши я ко царю Идумейску и ко царю Моавску и ко царю сынов Аммоних, и ко царю Тирску и ко царю Сидонску, в руку послов их идущих сретением своим во Иерусалим ко Седекии царю Иудину,
4 Kí o sì pàṣẹ fún wọn láti wí fún àwọn olúwa wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Sọ èyí fún àwọn olúwa rẹ.
и завещай им ко господем их рещи: тако рече Господь Бог Израилев: тако рцыте ко господем своим:
5 Pẹ̀lú agbára ńlá mi àti ọwọ́ nínà mi ni Èmi dá ayé, ènìyàn àti ẹranko tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, mo sì fún ẹni tí ó wu ọkàn mi.
Аз сотворих землю и человека и скоты, яже на лицы земли, крепостию Моею великою и мышцею Моею высокою, и дам ю, емуже будет угодно пред очима Моима.
6 Nísinsin yìí, Èmi yóò fa gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ fún Nebukadnessari ọba Babeli ìránṣẹ́ mi; Èmi yóò sì mú àwọn ẹranko búburú wọ̀n-ọn-nì jẹ́ tirẹ̀.
И ныне Аз дах всю землю сию в руце Навуходоносору царю Вавилонску, да ему работают, и звери селныя дах делати ему:
7 Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóò máa sìn ín àti àwọn ọmọdọ́mọ rẹ̀ títí ilẹ̀ rẹ yóò fi dé; ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá ni yóò tẹríba fún.
и послужат ему вси языцы и сыну его и сыну сына его, дондеже приидет время земли его и его самого, и послужат ему мнози народи и царие велицы:
8 “‘“Ṣùgbọ́n tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan kò bá ní sin Nebukadnessari ọba Babeli, tàbí kí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní abẹ́ àjàgà rẹ̀, Èmi yóò fi ìyà jẹ orílẹ̀-èdè náà nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, ni Olúwa wí títí Èmi yóò fi run wọ́n nípa ọwọ́ rẹ̀.
страна же и царство, елицы аще не поработают царю Вавилонску и елицы не вдежут выи своея в ярем царя Вавилонска, мечем и гладом посещу их, рече Господь, дондеже скончаются в руце его.
9 Nítorí náà, ẹ má ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí àwọn wòlíì yín, àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, àwọn tí ń rọ́ àlá fún un yín, àwọn oṣó yín, tàbí àwọn àjẹ́ yín tí wọ́n ń sọ fún un yín pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli.’
Вы же не слушайте лжепророк ваших и волхвующих вам и видящих сония вам, ни чарований ваших, ни обаятелей ваших глаголющих: не послужите царю Вавилонскому:
10 Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún un yín èyí tí yóò mú u yín jìnnà réré kúrò ní ilẹ̀ yín; kí Èmi kí ó lè lé yín jáde, kí ẹ̀yin ó sì ṣègbé.
яко лжу прорицают тии вам, еже бы удалитися вам от земли вашея, извергнути вас и еже погибнути вам.
11 Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kankan bá tẹ orí rẹ̀ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, tí ó sì sìn ín, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà wà lórí ilẹ̀ rẹ̀ láti máa ro ó, àti láti máa gbé ibẹ̀ ni Olúwa wí.”’”
Страна же, яже склонит выю свою под ярем царя Вавилонска и послужит ему, оставлю ю на земли своей, глаголет Господь: и орати будет ю и вселится на ней.
12 Èmi sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Sedekiah ọba Juda wí pé: “Tẹ orí rẹ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, sìn ín ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ yóò sì yè.
И ко Седекии царю Иудину глаголах по всем словесем сим, глаголя: склоните выи вашя под иго царя Вавилонска и служите ему и людем его, и живи будете:
13 Kí ló dé tí ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, èyí tí Olúwa fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bá sin ọba Babeli?
почто умираете, ты и людие твои, мечем и гладом и мором, якоже рече Господь ко странам, не хотевшым служити царю Вавилонску?
14 Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tí ó ń sọ wí pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli,’ nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín.
Не послушайте слов пророков глаголющих вам: не послужите царю Вавилонску:
15 ‘Èmi kò rán wọn ni Olúwa wí. Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Nítorí náà, Èmi yóò lé wọn, wọn yóò sì ṣègbé, ẹ̀yin pẹ̀lú àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín.’”
яко неправедно тии прорицают вам: яко не послах их, рече Господь, тии же прорицают именем Моим о неправде, еже бы погубити вас, и погибнете вы и пророцы ваши, прорицающии вам о неправде ложная.
16 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹ má ṣe fetí sí nǹkan tí àwọn wòlíì ń sọ pé, ‘Láìpẹ́ ohun èlò ilé Olúwa ni a ó kó padà láti Babeli,’ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ. Ẹ má tẹ́tí sí wọn.
Вам и всем людем сим и жерцем глаголах, рекий: тако рече Господь: не слушайте словес пророческих, прорицающих вам лжу и глаголющих: се, сосуди дому Господня возвратятся от Вавилона ныне вскоре: яко лжу прорицают вам,
17 Má ṣe tẹ́tí sí wọn, ẹ máa sin ọba Babeli, ẹ̀yin yóò sì yè. Èéṣe tí ìlú yóò fi di ahoro?
не послушайте их, но служите царю Вавилонскому, да живи будете. Вскую даете град сей в запустение?
18 Tí wọ́n bá jẹ́ wòlíì, tí wọ́n sì ní ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ kí wọ́n bẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun kí a má ṣe kó ohun èlò tí ó kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
Аще суть пророцы и есть слово Господне в них, да предстанут Господу Вседержителю, да не отидут сосуди, оставшиися в дому Господни и в дому царя Иудина и во Иерусалиме, в Вавилон.
19 Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ nípa àwọn opó, omi Òkun ní ti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti ní ti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní ìlú náà.
Тако бо глаголет Господь Вседержитель о столпех и о умывалнице, и о подставах и о прочих сосудех оставшихся во граде сем,
20 Èyí tí Nebukadnessari ọba Babeli kò kó lọ nígbà tí ó mú Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Juda àti Jerusalẹmu.
ихже не взя Навуходоносор царь Вавилонский, егда пресели Иехонию сына Иоакимова, царя Иудина, из Иерусалима в Вавилон, и вся старейшины Иудины и Иерусалимли.
21 Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti ní Jerusalẹmu:
Тако бо глаголет Господь Вседержитель Бог Израилев о сосудех оставшихся в дому Господни и в дому царя Иудина и в Иерусалиме:
22 ‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Babeli, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, Èmi yóò mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’”
в Вавилон принесутся и тамо будут даже до дне посещения своего, глаголет Господь: и повелю принести я и возвратити на место сие.

< Jeremiah 27 >