< Jeremiah 27 >

1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé.
Na początku królowania Joakima, syna Jozjasza, króla Judy, doszło to słowo do Jeremiasza od PANA mówiące:
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ṣe àjàgà àti ọ̀pá irin fún ara rẹ, kí o sì fiwé ọrùn rẹ.
Tak mówi do mnie PAN: Sporządź sobie więzy i jarzma i nałóż je na swoją szyję;
3 Kí o rán ọ̀rọ̀ sí ọba ti Edomu, Moabu, Ammoni, Tire àti Sidoni láti ọwọ́ àwọn ikọ̀ tí ó wá sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ Sedekiah ọba Juda.
Potem poślij je do króla Edomu, do króla Moabu, do króla Ammonitów, do króla Tyru i do króla Sydonu przez posłańców, którzy przyjdą do Jerozolimy, do Sedekiasza, króla Judy;
4 Kí o sì pàṣẹ fún wọn láti wí fún àwọn olúwa wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Sọ èyí fún àwọn olúwa rẹ.
I rozkaż im, aby swym panom powiedzieli: Tak mówi PAN zastępów, Bóg Izraela. Tak powiecie swym panom:
5 Pẹ̀lú agbára ńlá mi àti ọwọ́ nínà mi ni Èmi dá ayé, ènìyàn àti ẹranko tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, mo sì fún ẹni tí ó wu ọkàn mi.
Ja uczyniłem ziemię, człowieka i zwierzęta, które są na powierzchni ziemi, swoją wielką mocą i wyciągniętym ramieniem, i daję temu, który w moich oczach ma upodobanie.
6 Nísinsin yìí, Èmi yóò fa gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ fún Nebukadnessari ọba Babeli ìránṣẹ́ mi; Èmi yóò sì mú àwọn ẹranko búburú wọ̀n-ọn-nì jẹ́ tirẹ̀.
A teraz dałem te wszystkie ziemie do rąk Nabuchodonozora, króla Babilonu, mego sługi; oddałem mu nawet zwierzęta polne, aby mu służyły.
7 Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóò máa sìn ín àti àwọn ọmọdọ́mọ rẹ̀ títí ilẹ̀ rẹ yóò fi dé; ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá ni yóò tẹríba fún.
Dlatego będą mu służyły te wszystkie narody, jego synowi i synowi jego syna, aż nadejdzie czas na jego ziemię. Wtedy ujarzmią go liczne narody i wielcy królowie.
8 “‘“Ṣùgbọ́n tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan kò bá ní sin Nebukadnessari ọba Babeli, tàbí kí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní abẹ́ àjàgà rẹ̀, Èmi yóò fi ìyà jẹ orílẹ̀-èdè náà nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, ni Olúwa wí títí Èmi yóò fi run wọ́n nípa ọwọ́ rẹ̀.
A ten naród i to królestwo, które nie będzie służyło Nabuchodonozorowi, królowi Babilonu, i które nie podda swego karku pod jarzmo króla Babilonu, taki naród nawiedzę mieczem, głodem i zarazą, mówi PAN, aż wytracę je jego ręką.
9 Nítorí náà, ẹ má ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí àwọn wòlíì yín, àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, àwọn tí ń rọ́ àlá fún un yín, àwọn oṣó yín, tàbí àwọn àjẹ́ yín tí wọ́n ń sọ fún un yín pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli.’
Dlatego nie słuchajcie swoich proroków, wróżbitów ani tych, co mają sny, ani swoich wróżbiarzy, ani swoich czarowników, którzy wam mówią: Nie będziecie służyć królowi Babilonu.
10 Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún un yín èyí tí yóò mú u yín jìnnà réré kúrò ní ilẹ̀ yín; kí Èmi kí ó lè lé yín jáde, kí ẹ̀yin ó sì ṣègbé.
Oni bowiem prorokują wam kłamstwo, aby was oddalić od waszej ziemi, abym was wygnał i abyście poginęli.
11 Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kankan bá tẹ orí rẹ̀ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, tí ó sì sìn ín, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà wà lórí ilẹ̀ rẹ̀ láti máa ro ó, àti láti máa gbé ibẹ̀ ni Olúwa wí.”’”
A naród, który podda swój kark pod jarzmo króla Babilonu i będzie mu służył, ten pozostawię w jego ziemi, mówi PAN, aby ją uprawiał i mieszkał w niej.
12 Èmi sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Sedekiah ọba Juda wí pé: “Tẹ orí rẹ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, sìn ín ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ yóò sì yè.
A do Sedekiasza, króla Judy, powiedziałem zgodnie ze wszystkimi tymi słowami: Poddajcie swoje karki pod jarzmo króla Babilonu i służcie mu i jego ludowi, a będziecie żyć.
13 Kí ló dé tí ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, èyí tí Olúwa fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bá sin ọba Babeli?
Czemu macie zginąć, ty i twój lud, od miecza, od głodu i od zarazy, jak mówił PAN o narodzie, który nie chce służyć królowi Babilonu?
14 Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tí ó ń sọ wí pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli,’ nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín.
Nie słuchajcie więc słów tych proroków, którzy mówią do was: Nie będziecie służyć królowi Babilonu. Oni bowiem prorokują wam kłamstwo.
15 ‘Èmi kò rán wọn ni Olúwa wí. Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Nítorí náà, Èmi yóò lé wọn, wọn yóò sì ṣègbé, ẹ̀yin pẹ̀lú àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín.’”
Nie posłałem ich, mówi PAN, a jednak oni prorokują kłamliwie w moje imię, abym was wypędził i abyście zginęli, wy i prorocy, którzy wam prorokują.
16 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹ má ṣe fetí sí nǹkan tí àwọn wòlíì ń sọ pé, ‘Láìpẹ́ ohun èlò ilé Olúwa ni a ó kó padà láti Babeli,’ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ. Ẹ má tẹ́tí sí wọn.
Także do kapłanów i do całego ludu powiedziałem: Tak mówi PAN: Nie słuchajcie słów swoich proroków, którzy prorokują wam, mówiąc: Oto naczynia domu PANA zostaną już wkrótce przywrócone z Babilonu. Oni bowiem prorokują wam kłamstwo.
17 Má ṣe tẹ́tí sí wọn, ẹ máa sin ọba Babeli, ẹ̀yin yóò sì yè. Èéṣe tí ìlú yóò fi di ahoro?
Nie słuchajcie ich, służcie królowi Babilonu, a będziecie żyć. Czemu to miasto miałoby stać się ruiną?
18 Tí wọ́n bá jẹ́ wòlíì, tí wọ́n sì ní ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ kí wọ́n bẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun kí a má ṣe kó ohun èlò tí ó kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
A jeśli oni są prorokami i jeśli słowo PANA jest u nich, proszę, niech wstawią się u PANA zastępów, aby te naczynia, które pozostały w domu PANA, w domu króla Judy i w Jerozolimie, nie dostały się do Babilonu.
19 Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ nípa àwọn opó, omi Òkun ní ti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti ní ti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní ìlú náà.
Tak bowiem mówi PAN zastępów o tych kolumnach, o morzu, o podstawkach i reszcie naczyń, które pozostały w tym mieście;
20 Èyí tí Nebukadnessari ọba Babeli kò kó lọ nígbà tí ó mú Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Juda àti Jerusalẹmu.
Których nie zabrał Nabuchodonozor, król Babilonu, gdy uprowadził do niewoli Jechoniasza, syna Joakima, króla Judy, z Jerozolimy do Babilonu, oraz wszystkich dostojników z Judy i Jerozolimy.
21 Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti ní Jerusalẹmu:
Tak mówi PAN zastępów, Bóg Izraela, o tych naczyniach, które pozostały w domu PANA, w domu króla Judy i w Jerozolimie:
22 ‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Babeli, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, Èmi yóò mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’”
Zostaną zawiezione do Babilonu i będą tam aż do dnia, w którym upomnę się o nie, mówi PAN. Wtedy sprowadzę je i przywrócę na to miejsce.

< Jeremiah 27 >