< Jeremiah 27 >
1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé.
In [the] beginning of [the] reign of Jehoiakim [the] son of Josiah [the] king of Judah it came the word this to Jeremiah from with Yahweh saying.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ṣe àjàgà àti ọ̀pá irin fún ara rẹ, kí o sì fiwé ọrùn rẹ.
Thus he said Yahweh to me make for yourself fetters and yoke-bars and you will put them on neck your.
3 Kí o rán ọ̀rọ̀ sí ọba ti Edomu, Moabu, Ammoni, Tire àti Sidoni láti ọwọ́ àwọn ikọ̀ tí ó wá sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ Sedekiah ọba Juda.
And you will send them to [the] king of Edom and to [the] king of Moab and to [the] king of [the] people of Ammon and to [the] king of Tyre and to [the] king of Sidon by [the] hand of messengers who have come Jerusalem to Zedekiah [the] king of Judah.
4 Kí o sì pàṣẹ fún wọn láti wí fún àwọn olúwa wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Sọ èyí fún àwọn olúwa rẹ.
And you will command them to masters their saying thus he says Yahweh of hosts [the] God of Israel thus you will say to masters your.
5 Pẹ̀lú agbára ńlá mi àti ọwọ́ nínà mi ni Èmi dá ayé, ènìyàn àti ẹranko tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, mo sì fún ẹni tí ó wu ọkàn mi.
I I made the earth humankind and the animal[s] which [are] on [the] surface of the earth by power my great and by arm my outstretched and I give it to [those] whom it is pleasing in view my.
6 Nísinsin yìí, Èmi yóò fa gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ fún Nebukadnessari ọba Babeli ìránṣẹ́ mi; Èmi yóò sì mú àwọn ẹranko búburú wọ̀n-ọn-nì jẹ́ tirẹ̀.
And now I I give all the lands these in [the] hand of Nebuchadnezzar [the] king of Babylon servant my and also [the] animal[s] of the field I give to him to serve him.
7 Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóò máa sìn ín àti àwọn ọmọdọ́mọ rẹ̀ títí ilẹ̀ rẹ yóò fi dé; ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá ni yóò tẹríba fún.
And they will serve him all the nations and son his and [the] son of son his until comes [the] time of land his also he and they will work by him nations many and kings great.
8 “‘“Ṣùgbọ́n tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan kò bá ní sin Nebukadnessari ọba Babeli, tàbí kí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní abẹ́ àjàgà rẹ̀, Èmi yóò fi ìyà jẹ orílẹ̀-èdè náà nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, ni Olúwa wí títí Èmi yóò fi run wọ́n nípa ọwọ́ rẹ̀.
And it will be the nation and the kingdom which not they will serve him Nebuchadnezzar [the] king of Babylon and which not it will put neck its in [the] yoke of [the] king of Babylon with the sword and with famine and with pestilence I will visit [judgment] on the nation that [the] utterance of Yahweh until have consumed I them by hand his.
9 Nítorí náà, ẹ má ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí àwọn wòlíì yín, àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, àwọn tí ń rọ́ àlá fún un yín, àwọn oṣó yín, tàbí àwọn àjẹ́ yín tí wọ́n ń sọ fún un yín pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli.’
And you may not you listen to prophets your and to diviners your and to dreams your and to soothsayers your and to sorcerers your who they [are] saying to you saying not you will serve [the] king of Babylon.
10 Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún un yín èyí tí yóò mú u yín jìnnà réré kúrò ní ilẹ̀ yín; kí Èmi kí ó lè lé yín jáde, kí ẹ̀yin ó sì ṣègbé.
For falsehood they [are] prophesying to you so as to remove far away you from on land your and I will drive out you and you will perish.
11 Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kankan bá tẹ orí rẹ̀ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, tí ó sì sìn ín, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà wà lórí ilẹ̀ rẹ̀ láti máa ro ó, àti láti máa gbé ibẹ̀ ni Olúwa wí.”’”
And the nation which it will bring neck its in [the] yoke of [the] king of Babylon and it will serve him and I will let remain it on land its [the] utterance of Yahweh and it will work it and it will dwell in it.
12 Èmi sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Sedekiah ọba Juda wí pé: “Tẹ orí rẹ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, sìn ín ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ yóò sì yè.
And to Zedekiah [the] king of Judah I spoke according to all the words these saying bring necks your in [the] yoke of [the] king of Babylon and serve him and people his and live.
13 Kí ló dé tí ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, èyí tí Olúwa fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bá sin ọba Babeli?
Why? will you die you and people your by the sword by famine and by pestilence just as he has spoken Yahweh to the nation which not it will serve [the] king of Babylon.
14 Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tí ó ń sọ wí pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli,’ nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín.
And may not you listen to [the] words of the prophets who say to you saying not you will serve [the] king of Babylon for falsehood they [are] prophesying to you.
15 ‘Èmi kò rán wọn ni Olúwa wí. Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Nítorí náà, Èmi yóò lé wọn, wọn yóò sì ṣègbé, ẹ̀yin pẹ̀lú àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín.’”
For not I sent them [the] utterance of Yahweh and they [are] prophesying in name my to falsehood so as to drive out I you and you will perish you and the prophets who are prophesying to you.
16 Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹ má ṣe fetí sí nǹkan tí àwọn wòlíì ń sọ pé, ‘Láìpẹ́ ohun èlò ilé Olúwa ni a ó kó padà láti Babeli,’ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ. Ẹ má tẹ́tí sí wọn.
And to the priests and to all the people this I spoke saying thus he says Yahweh may not you listen to [the] words of prophets your who are prophesying to you saying there! [the] articles of [the] house of Yahweh [are] about to be brought back from Babylon now quickly for falsehood they [are] prophesying to you.
17 Má ṣe tẹ́tí sí wọn, ẹ máa sin ọba Babeli, ẹ̀yin yóò sì yè. Èéṣe tí ìlú yóò fi di ahoro?
May not you listen to them serve [the] king of Babylon and live why? will it become the city this a ruin.
18 Tí wọ́n bá jẹ́ wòlíì, tí wọ́n sì ní ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ kí wọ́n bẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun kí a má ṣe kó ohun èlò tí ó kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
And if [are] prophets they and if there [is] [the] word of Yahweh with them let them entreat please Yahweh of hosts to not go the articles - which remain in [the] house of Yahweh and [the] house of [the] king of Judah and in Jerusalem Babylon towards.
19 Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ nípa àwọn opó, omi Òkun ní ti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti ní ti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní ìlú náà.
For thus he says Yahweh of hosts concerning the pillars and on the sea and on the stands and on [the] remainder of the articles which remain in the city this.
20 Èyí tí Nebukadnessari ọba Babeli kò kó lọ nígbà tí ó mú Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Juda àti Jerusalẹmu.
Which not he took them Nebuchadnezzar [the] king of Babylon when took into exile he (Jeconiah *Q(k)*) [the] son of Jehoiakim [the] king of Judah from Jerusalem Babylon towards and all [the] nobles of Judah and Jerusalem.
21 Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti ní Jerusalẹmu:
For thus he says Yahweh of hosts [the] God of Israel on the articles which remain [the] house of Yahweh and [the] house of [the] king of Judah and Jerusalem.
22 ‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Babeli, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, Èmi yóò mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’”
Babylon towards they will be taken and there they will remain until [the] day give attention to I them [the] utterance of Yahweh and I will bring up them and I will bring back them to the place this.