< Jeremiah 26 >

1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìjọba ọba Jehoiakimu ọmọ Josiah tí ń ṣe ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa:
La începutul domniei lui Ioiachim fiul lui Iosia, împăratul lui Iuda, a venit acest cuvânt de la DOMNUL, spunând:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Dúró ní àgbàlá ilé Olúwa, kí o sì sọ fún gbogbo ènìyàn ilẹ̀ Juda tí ó ti wá láti wá jọ́sìn ní ilé Olúwa, sọ fún gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ; má ṣaláìsọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà.
Astfel spune DOMNUL: Stai în picioare în curtea casei DOMNULUI și vorbește tuturor cetăților lui Iuda care vin să se închine în casa DOMNULUI, toate cuvintele pe care ți le poruncesc să le vorbești lor; să nu scazi niciun cuvânt;
3 Bóyá gbogbo wọn máa gbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn yóò kúrò nínú ìwà búburú wọn. Èmi ó yí ọkàn padà, n kò sì ní fi ibi tí mo ti rò sí wọn ṣe wọ́n.
Și dacă ei vor da ascultare și se vor întoarce fiecare om de la calea lui rea, atunci mă voi pocăi de răul pe care plănuiesc să li-l fac din cauza răutății facerilor lor.
4 Sọ fún wọn wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Tí ẹ kò bá fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, tí ẹ kò sì gbọ́ òfin mi, ti mo gbé kalẹ̀ níwájú yín,
Și să le spui: Astfel spune DOMNUL: Dacă nu îmi veți da ascultare, pentru a umbla în legea mea pe care am pus-o înaintea voastră,
5 àti tí ẹ kò bá gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì tí mo rán sí i yín léraléra (ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́),
Pentru a da ascultare cuvintelor servitorilor mei, profeții, pe care i-am trimis la voi, deopotrivă ridicându-i devreme și trimițându-i, iar voi nu ați dat ascultare;
6 nígbà náà ni èmi yóò ṣe ilé yìí bí Ṣilo, èmi yóò sì ṣe ìlú yìí ní ìfibú sí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé.’”
Atunci voi face această casă ca Șilo și voi face această cetate un blestem pentru toate națiunile pământului.
7 Àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo ènìyàn ni ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Jeremiah tí ó sọ ní ilé Olúwa.
Astfel preoții și profeții și tot poporul l-au auzit pe Ieremia vorbind aceste cuvinte în casa DOMNULUI.
8 Ṣùgbọ́n ní kété tí Jeremiah ti parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí Olúwa pàṣẹ láti sọ; àwọn àlùfáà, àti gbogbo ènìyàn dìímú, wọ́n sì wí pé, “Kíkú ni ìwọ yóò kú!
Și s-a întâmplat, după ce Ieremia a terminat de vorbit tot ceea ce DOMNUL îi poruncise să vorbească întregului popor, că preoții și profeții și tot poporul l-au apucat, spunând: Vei muri negreșit.
9 Kí ló dé tí ìwọ ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa pé, ilé yìí yóò dàbí Ṣilo, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro tí kì yóò ní olùgbé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì kójọpọ̀ pẹ̀lú Jeremiah nínú ilé Olúwa.
De ce ai profețit în numele DOMNULUI, spunând: Această casă va fi ca Șilo și această cetate va fi pustiită, fără vreun locuitor? Și tot poporul s-a adunat împotriva lui Ieremia în casa DOMNULUI.
10 Nígbà tí àwọn aláṣẹ Juda gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, wọ́n lọ láti ààfin ọba sí ilé Olúwa, wọ́n sì mú ààyè wọn, wọ́n jókòó ní ẹnu-ọ̀nà tuntun ilé Olúwa.
Când prinții lui Iuda au auzit aceste lucruri, atunci s-au urcat din casa împăratului la casa DOMNULUI și au șezut la intrarea porții noi a casei DOMNULUI.
11 Àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì sọ fún àwọn aláṣẹ àti gbogbo ènìyàn pé, “Arákùnrin yìí gbọdọ̀ gba ìdájọ́ ikú nítorí pé ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórí ìlú yìí: bí ẹ̀yin ti fi etí yín gbọ́!”
Atunci preoții și profeții au vorbit prinților și întregului popor, spunând: Acest om este demn de moarte pentru că a profețit împotriva acestei cetăți, precum ați auzit cu urechile voastre.
12 Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún gbogbo àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn wí pé: “Olúwa rán mi láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ilé yìí àti ìlú yìí, gbogbo ohun tí ẹ ti gbọ́.
Atunci Ieremia a vorbit tuturor prinților și întregului popor, spunând: DOMNUL m-a trimis să profețesc împotriva acestei case și împotriva acestei cetăți, toate cuvintele pe care le-ați auzit.
13 Nísinsin yìí, tún ọ̀nà rẹ ṣe àti ìṣe rẹ, kí ẹ sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín. Olúwa yóò yí ọkàn rẹ̀ padà, kò sì ní mú ohun gbogbo tí ó ti sọ jáde ní búburú ṣẹ lórí yín.
De aceea acum, îndreptați-vă căile și facerile voastre și ascultați de vocea DOMNULUI Dumnezeului vostru; și DOMNUL se va pocăi de răul pe care el l-a vorbit împotriva voastră.
14 Bí ó bá ṣe tèmi ni, èmi wà ní ọwọ́ yín, ẹ ṣe ohun tí ẹ̀yin bá rò pé ó dára, tí ó sì tọ́ lójú yín fún mi.
Cât despre mine, iată, eu sunt în mâna voastră; faceți cu mine precum vi se pare bine și precum vă este cuvenit.
15 Ẹ mọ̀ dájú pé tí ẹ bá pa mí, ẹ ó mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ wá sórí ara yín, sórí ìlú yìí àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; nítorí pé nítòótọ́ ni Olúwa ti rán mi láti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún un yín.”
Dar să știți cu siguranță, că dacă mă dați la moarte, veți aduce negreșit sânge nevinovat asupra voastră și asupra acestei cetăți și asupra locuitorilor ei, pentru că, în adevăr, DOMNUL m-a trimis la voi să vorbesc toate aceste cuvinte în urechile voastre.
16 Nígbà náà ni àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì pé, “Ẹ má ṣe pa ọkùnrin yìí nítorí ó ti bá wa sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.”
Atunci prinții și tot poporul au spus preoților și profeților: Acest om nu este demn să moară, pentru că el ne-a vorbit în numele DOMNULUI Dumnezeului nostru.
17 Lára àwọn àgbàgbà ilẹ̀ náà sì sún síwájú, wọ́n sì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé,
Atunci s-au ridicat unii dintre bătrânii țării și au vorbit întregii adunări a poporului, spunând:
18 “Mika ti Moreṣeti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Ó sọ fún gbogbo ènìyàn Juda pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘A ó sì fa Sioni tu bí oko Jerusalẹmu yóò di òkìtì àlàpà àti òkè ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ibi gíga igbó.’
Mica din Moreșet profețea în zilele lui Ezechia, împăratul lui Iuda, și a vorbit întregului popor al lui Iuda, spunând: Astfel spune DOMNUL oștirilor: Sionul va fi arat ca un câmp și Ierusalimul va deveni mormane și muntele casei ca înălțimile unei păduri.
19 Ǹjẹ́ Hesekiah ọba Juda tàbí ẹnikẹ́ni ní Juda pa á bí? Ǹjẹ́ Hesekiah kò bẹ̀rù Olúwa tí ó sì wá ojúrere rẹ̀? Ǹjẹ́ Olúwa kò ha a sì yí ìpinnu rẹ̀ padà, tí kò sì mú ibi tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ yẹ̀ kúrò lórí wọn? Ibi ni a fẹ́ mú wá sórí ara wa yìí.”
L-a pus Ezechia, împăratul lui Iuda, și întregul Iuda, cumva la moarte? Nu s-a temut el de DOMNUL și a implorat pe DOMNUL și DOMNUL s-a pocăit de răul pe care îl vorbise împotriva lor? Astfel am face noi un mare rău împotriva sufletelor noastre.
20 (Bákan náà Uriah ọmọ Ṣemaiah láti Kiriati-Jearimu jẹ́ ọkùnrin mìíràn tí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà ní orúkọ Olúwa. Ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà sí ìlú náà àti ilẹ̀ yín bí Jeremiah ti ṣe.
Și a mai fost de asemenea un om care profețea în numele DOMNULUI: Urie, fiul lui Șemaia, din Chiriat-Iearim, care a profețit împotriva acestei cetăți și împotriva acestei țări, conform cu toate cuvintele lui Ieremia;
21 Nígbà tí ọba Jehoiakimu àti gbogbo àwọn aláṣẹ gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀, ọba ń wá láti pa á: ṣùgbọ́n Uriah gbọ́ èyí, ẹ̀rù bà á, ó sì sálọ sí Ejibiti.
Și când împăratul Ioiachim, împreună cu toți războinicii lui și toți prinții, au auzit cuvintele lui, împăratul a căutat să îl dea la moarte; dar când Urie a auzit aceasta, s-a temut și a fugit și a mers în Egipt;
22 Ọba Jehoiakimu rán Elnatani ọmọ Akbori lọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mìíràn.
Și Ioiachim împăratul a trimis oameni în Egipt, adică, pe Elnatan, fiul lui Acbor, și pe anumiți bărbați, împreună cu el, în Egipt.
23 Wọ́n sì mú Uriah láti Ejibiti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Jehoiakimu; ẹni tí ó fi idà pa, ó sì sọ òkú rẹ̀ sí inú isà òkú àwọn ènìyàn lásán.)
Și ei l-au scos pe Urie din Egipt și l-au adus la împăratul Ioiachim, care l-a ucis cu sabia și i-a aruncat trupul său mort în mormintele oamenilor de rând.
24 Ahikamu ọmọ Ṣafani ń bẹ pẹ̀lú Jeremiah, wọn kò sì fi í lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti pa á.
Totuși, mâna lui Ahicam, fiul lui Șafan, a fost cu Ieremia, ca ei să nu îl dea în mâna poporului pentru a fi dat la moarte.

< Jeremiah 26 >