< Jeremiah 26 >
1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìjọba ọba Jehoiakimu ọmọ Josiah tí ń ṣe ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa:
No início do reinado de Jeoiaquim, filho de Josias, rei de Judá, esta palavra veio de Javé:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Dúró ní àgbàlá ilé Olúwa, kí o sì sọ fún gbogbo ènìyàn ilẹ̀ Juda tí ó ti wá láti wá jọ́sìn ní ilé Olúwa, sọ fún gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ; má ṣaláìsọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà.
“Yahweh diz: 'Fique na corte da casa de Yahweh, e fale a todas as cidades de Judá que vêm para adorar na casa de Yahweh, todas as palavras que eu lhe ordeno que fale com eles. Não omitam uma palavra.
3 Bóyá gbogbo wọn máa gbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn yóò kúrò nínú ìwà búburú wọn. Èmi ó yí ọkàn padà, n kò sì ní fi ibi tí mo ti rò sí wọn ṣe wọ́n.
Talvez eles ouçam, e cada homem se volte de seu mau caminho, para que eu me arrependa do mal que pretendo fazer com eles por causa do mal de seus atos”.
4 Sọ fún wọn wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Tí ẹ kò bá fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, tí ẹ kò sì gbọ́ òfin mi, ti mo gbé kalẹ̀ níwájú yín,
Dir-lhes-eis: “Javé diz: 'Se não me escutardes, para andardes na minha lei que vos apresentei,
5 àti tí ẹ kò bá gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì tí mo rán sí i yín léraléra (ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́),
para escutardes as palavras dos meus servos, os profetas que vos envio, mesmo que se levantem cedo e os enviem - mas não ouvistes -
6 nígbà náà ni èmi yóò ṣe ilé yìí bí Ṣilo, èmi yóò sì ṣe ìlú yìí ní ìfibú sí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé.’”
então farei desta casa como Shiloh, e farei desta cidade uma maldição para todas as nações da terra'”.
7 Àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo ènìyàn ni ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Jeremiah tí ó sọ ní ilé Olúwa.
Os sacerdotes, os profetas e todo o povo ouviram Jeremias falar estas palavras na casa de Iavé.
8 Ṣùgbọ́n ní kété tí Jeremiah ti parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí Olúwa pàṣẹ láti sọ; àwọn àlùfáà, àti gbogbo ènìyàn dìímú, wọ́n sì wí pé, “Kíkú ni ìwọ yóò kú!
Quando Jeremias terminou de falar tudo o que Iavé lhe ordenara que falasse a todo o povo, aos sacerdotes e profetas e a todo o povo o agarraram, dizendo: “Certamente morrereis!
9 Kí ló dé tí ìwọ ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa pé, ilé yìí yóò dàbí Ṣilo, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro tí kì yóò ní olùgbé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì kójọpọ̀ pẹ̀lú Jeremiah nínú ilé Olúwa.
Por que você profetizou em nome de Javé, dizendo: “Esta casa será como Shiloh, e esta cidade será desolada, sem habitantes”? Todas as pessoas estavam lotadas ao redor de Jeremias na casa de Yahweh.
10 Nígbà tí àwọn aláṣẹ Juda gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, wọ́n lọ láti ààfin ọba sí ilé Olúwa, wọ́n sì mú ààyè wọn, wọ́n jókòó ní ẹnu-ọ̀nà tuntun ilé Olúwa.
Quando os príncipes de Judá ouviram estas coisas, eles subiram da casa do rei para a casa de Iavé; e sentaram-se na entrada do novo portão da casa de Iavé.
11 Àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì sọ fún àwọn aláṣẹ àti gbogbo ènìyàn pé, “Arákùnrin yìí gbọdọ̀ gba ìdájọ́ ikú nítorí pé ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórí ìlú yìí: bí ẹ̀yin ti fi etí yín gbọ́!”
Então os sacerdotes e os profetas falaram aos príncipes e a todo o povo, dizendo: “Este homem é digno de morte, pois profetizou contra esta cidade, como vocês ouviram com seus ouvidos”.
12 Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún gbogbo àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn wí pé: “Olúwa rán mi láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ilé yìí àti ìlú yìí, gbogbo ohun tí ẹ ti gbọ́.
Então Jeremias falou a todos os príncipes e a todo o povo, dizendo: “Javé me enviou para profetizar contra esta casa e contra esta cidade todas as palavras que vocês ouviram.
13 Nísinsin yìí, tún ọ̀nà rẹ ṣe àti ìṣe rẹ, kí ẹ sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín. Olúwa yóò yí ọkàn rẹ̀ padà, kò sì ní mú ohun gbogbo tí ó ti sọ jáde ní búburú ṣẹ lórí yín.
Agora, portanto, modifique seus caminhos e seus feitos, e obedeça a Yahweh a voz de seu Deus; então Yahweh se arrependerá do mal que ele pronunciou contra você.
14 Bí ó bá ṣe tèmi ni, èmi wà ní ọwọ́ yín, ẹ ṣe ohun tí ẹ̀yin bá rò pé ó dára, tí ó sì tọ́ lójú yín fún mi.
Mas quanto a mim, eis que estou em suas mãos. Fazei comigo o que é bom e correto aos vossos olhos.
15 Ẹ mọ̀ dájú pé tí ẹ bá pa mí, ẹ ó mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ wá sórí ara yín, sórí ìlú yìí àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; nítorí pé nítòótọ́ ni Olúwa ti rán mi láti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún un yín.”
Saiba apenas com certeza que, se me matar, trará sangue inocente sobre si mesmo, sobre esta cidade e sobre seus habitantes; pois, na verdade, Javé me enviou a você para dizer todas estas palavras aos seus ouvidos”.
16 Nígbà náà ni àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì pé, “Ẹ má ṣe pa ọkùnrin yìí nítorí ó ti bá wa sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.”
Então os príncipes e todo o povo disseram aos sacerdotes e aos profetas: “Este homem não é digno de morte; pois nos falou em nome de Javé, nosso Deus”.
17 Lára àwọn àgbàgbà ilẹ̀ náà sì sún síwájú, wọ́n sì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé,
Então alguns dos anciãos da terra se levantaram, e falaram a toda a assembléia do povo, dizendo:
18 “Mika ti Moreṣeti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Ó sọ fún gbogbo ènìyàn Juda pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘A ó sì fa Sioni tu bí oko Jerusalẹmu yóò di òkìtì àlàpà àti òkè ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ibi gíga igbó.’
“Miquéias, o morastita, profetizou nos dias de Ezequias, rei de Judá; e falou a todo o povo de Judá, dizendo: 'Javé dos Exércitos diz: 'Javé dos Exércitos diz “'Zion será arado como um campo, e Jerusalém se tornará montões de lixo, e a montanha da casa como os lugares altos de uma floresta”.
19 Ǹjẹ́ Hesekiah ọba Juda tàbí ẹnikẹ́ni ní Juda pa á bí? Ǹjẹ́ Hesekiah kò bẹ̀rù Olúwa tí ó sì wá ojúrere rẹ̀? Ǹjẹ́ Olúwa kò ha a sì yí ìpinnu rẹ̀ padà, tí kò sì mú ibi tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ yẹ̀ kúrò lórí wọn? Ibi ni a fẹ́ mú wá sórí ara wa yìí.”
Ezequias, rei de Judá, e todo Judá o mataram? Ele não temeu a Iavé e suplicou o favor de Iavé, e Iavé se arrependeu do desastre que ele havia pronunciado contra eles? Cometeríamos um grande mal contra nossas próprias almas dessa maneira”!
20 (Bákan náà Uriah ọmọ Ṣemaiah láti Kiriati-Jearimu jẹ́ ọkùnrin mìíràn tí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà ní orúkọ Olúwa. Ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà sí ìlú náà àti ilẹ̀ yín bí Jeremiah ti ṣe.
Havia também um homem que profetizou em nome de Javé, Urias, filho de Semaías de Kiriath Jearim; e profetizou contra esta cidade e contra esta terra de acordo com todas as palavras de Jeremias.
21 Nígbà tí ọba Jehoiakimu àti gbogbo àwọn aláṣẹ gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀, ọba ń wá láti pa á: ṣùgbọ́n Uriah gbọ́ èyí, ẹ̀rù bà á, ó sì sálọ sí Ejibiti.
Quando o rei Jeoiaquim, com todos os seus poderosos e todos os príncipes ouviram suas palavras, o rei tentou matá-lo; mas quando Urias o ouviu, teve medo e fugiu, e foi para o Egito.
22 Ọba Jehoiakimu rán Elnatani ọmọ Akbori lọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mìíràn.
Então o rei Jeoiaquim enviou Elnatã, filho de Achbor, e alguns homens com ele para o Egito.
23 Wọ́n sì mú Uriah láti Ejibiti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Jehoiakimu; ẹni tí ó fi idà pa, ó sì sọ òkú rẹ̀ sí inú isà òkú àwọn ènìyàn lásán.)
Eles tiraram Urias do Egito e o levaram ao rei Jeoiaquim, que o matou com a espada e lançou seu corpo morto nos túmulos do povo comum.
24 Ahikamu ọmọ Ṣafani ń bẹ pẹ̀lú Jeremiah, wọn kò sì fi í lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti pa á.
Mas a mão de Ahikam, o filho de Shaphan, estava com Jeremias, de modo que não o entregaram na mão do povo para o condenar à morte.