< Jeremiah 26 >

1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìjọba ọba Jehoiakimu ọmọ Josiah tí ń ṣe ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa:
Jojaķima, Josijas dēla, Jūda ķēniņa, valdīšanas iesākumā šis vārds no Tā Kunga notika sacīdams:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Dúró ní àgbàlá ilé Olúwa, kí o sì sọ fún gbogbo ènìyàn ilẹ̀ Juda tí ó ti wá láti wá jọ́sìn ní ilé Olúwa, sọ fún gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ; má ṣaláìsọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà.
Tā saka Tas Kungs: stājies Tā Kunga nama pagalmā, un runā uz visām Jūda pilsētām, kas nāk pielūgt Tā Kunga namā, visus vārdus, ko Es tev esmu pavēlējis uz tiem runāt, neatrauj ne vārda.
3 Bóyá gbogbo wọn máa gbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn yóò kúrò nínú ìwà búburú wọn. Èmi ó yí ọkàn padà, n kò sì ní fi ibi tí mo ti rò sí wọn ṣe wọ́n.
Varbūt tie klausīs un atgriezīsies ikviens no sava niknā ceļa, tad Man arī būs žēl tā ļaunuma, ko Es tiem domāju darīt viņu darbu ļaunuma dēļ.
4 Sọ fún wọn wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Tí ẹ kò bá fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, tí ẹ kò sì gbọ́ òfin mi, ti mo gbé kalẹ̀ níwájú yín,
Saki tad uz tiem: tā saka Tas Kungs: ja jūs Man neklausīsiet un nestaigāsiet Manā bauslībā, ko Es jums esmu devis,
5 àti tí ẹ kò bá gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì tí mo rán sí i yín léraléra (ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́),
Ka jūs klausiet Manu kalpu, to praviešu, vārdiem, ko Es vienmēr pie jums sūtu vienā sūtīšanā, kam jūs taču neesat klausījuši,
6 nígbà náà ni èmi yóò ṣe ilé yìí bí Ṣilo, èmi yóò sì ṣe ìlú yìí ní ìfibú sí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé.’”
Tad Es šo namu darīšu tā kā Šīlo, un šo pilsētu Es likšu par lāstu visām zemes tautām.
7 Àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo ènìyàn ni ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Jeremiah tí ó sọ ní ilé Olúwa.
Un priesteri un pravieši un visi ļaudis dzirdēja Jeremiju šos vārdus runājam Dieva namā.
8 Ṣùgbọ́n ní kété tí Jeremiah ti parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí Olúwa pàṣẹ láti sọ; àwọn àlùfáà, àti gbogbo ènìyàn dìímú, wọ́n sì wí pé, “Kíkú ni ìwọ yóò kú!
Kad Jeremija bija pabeidzis visu runāt, ko Tas Kungs bija pavēlējis runāt uz visiem ļaudīm, tad priesteri un pravieši un visi ļaudis viņu sagrāba un sacīja: tiešām, mirt tev jāmirst.
9 Kí ló dé tí ìwọ ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa pé, ilé yìí yóò dàbí Ṣilo, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro tí kì yóò ní olùgbé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì kójọpọ̀ pẹ̀lú Jeremiah nínú ilé Olúwa.
Kā tu drīksti Tā Kunga Vārdā sludināt un sacīt: šis nams būs tā kā Šīlo, šī pilsēta būs postā bez iedzīvotāja! Un visi ļaudis sapulcējās pret Jeremiju Tā Kunga namā.
10 Nígbà tí àwọn aláṣẹ Juda gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, wọ́n lọ láti ààfin ọba sí ilé Olúwa, wọ́n sì mú ààyè wọn, wọ́n jókòó ní ẹnu-ọ̀nà tuntun ilé Olúwa.
Kad nu Jūda lielkungi to dzirdēja, tad tie nogāja no ķēniņa nama uz Tā Kunga namu un apsēdās priekš Tā Kunga jauno vārtu durvīm.
11 Àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì sọ fún àwọn aláṣẹ àti gbogbo ènìyàn pé, “Arákùnrin yìí gbọdọ̀ gba ìdájọ́ ikú nítorí pé ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórí ìlú yìí: bí ẹ̀yin ti fi etí yín gbọ́!”
Tad tie priesteri un tie pravieši runāja uz tiem lielkungiem un uz visiem ļaudīm un sacīja: šis vīrs ir nāvi pelnījis, jo viņš pret šo pilsētu ir sludinājis, kā jūs savām ausīm dzirdējuši.
12 Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún gbogbo àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn wí pé: “Olúwa rán mi láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ilé yìí àti ìlú yìí, gbogbo ohun tí ẹ ti gbọ́.
Bet Jeremija runāja uz visiem lielkungiem un uz visiem ļaudīm un sacīja: Tas Kungs mani sūtījis, sludināt pret šo namu un pret šo pilsētu visus vārdus, ko jūs esat dzirdējuši.
13 Nísinsin yìí, tún ọ̀nà rẹ ṣe àti ìṣe rẹ, kí ẹ sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín. Olúwa yóò yí ọkàn rẹ̀ padà, kò sì ní mú ohun gbogbo tí ó ti sọ jáde ní búburú ṣẹ lórí yín.
Nu tad, griežaties uz labiem ceļiem un pie labiem darbiem, un paklausiet Tā Kunga, sava Dieva, balsij, tad Tam Kungam būs žēl tā ļaunuma, ko Viņš pret jums runājis.
14 Bí ó bá ṣe tèmi ni, èmi wà ní ọwọ́ yín, ẹ ṣe ohun tí ẹ̀yin bá rò pé ó dára, tí ó sì tọ́ lójú yín fún mi.
Bet es, redzi, es esmu jūsu rokās, dariet man, kā jūsu acīs labi un pareizi!
15 Ẹ mọ̀ dájú pé tí ẹ bá pa mí, ẹ ó mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ wá sórí ara yín, sórí ìlú yìí àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; nítorí pé nítòótọ́ ni Olúwa ti rán mi láti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún un yín.”
Bet tomēr ziniet, kad jūs mani nokausiet, tad jūs nenoziedzīgas asinis krāsiet uz sevi un uz šo pilsētu un uz viņas iedzīvotājiem, jo Tas Kungs mani patiesi pie jums sūtījis, visus šos vārdus runāt jūsu ausīs.
16 Nígbà náà ni àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì pé, “Ẹ má ṣe pa ọkùnrin yìí nítorí ó ti bá wa sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.”
Tad tie lielkungi un visi ļaudis sacīja uz tiem priesteriem un uz tiem praviešiem: pie šā vīra nav nāves vainas, jo viņš uz mums runājis Tā Kunga, mūsu Dieva, vārdā.
17 Lára àwọn àgbàgbà ilẹ̀ náà sì sún síwájú, wọ́n sì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé,
Arī citi vīri no zemes vecajiem cēlās un runāja uz visu ļaužu draudzi un sacīja:
18 “Mika ti Moreṣeti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Ó sọ fún gbogbo ènìyàn Juda pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘A ó sì fa Sioni tu bí oko Jerusalẹmu yóò di òkìtì àlàpà àti òkè ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ibi gíga igbó.’
Miha no Marezas ir sludinājis Hizkijas, Jūda ķēniņa dienās, un uz visiem Jūda ļaudīm runājis un sacījis: tā saka Tas Kungs Cebaot: Ciāna taps arta kā tīrums, un Jeruzāleme būs par akmeņu kopu, un šā nama kalns taps par meža kalnu.
19 Ǹjẹ́ Hesekiah ọba Juda tàbí ẹnikẹ́ni ní Juda pa á bí? Ǹjẹ́ Hesekiah kò bẹ̀rù Olúwa tí ó sì wá ojúrere rẹ̀? Ǹjẹ́ Olúwa kò ha a sì yí ìpinnu rẹ̀ padà, tí kò sì mú ibi tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ yẹ̀ kúrò lórí wọn? Ibi ni a fẹ́ mú wá sórí ara wa yìí.”
Vai Hizkija, Jūda ķēniņš, un visa Jūda cilts viņu nokāvuši? Vai viņš nebijās To Kungu un nepielūdza Tā Kunga priekšā. Tad Tam Kungam bija žēl tā ļaunuma, ko Viņš pret tiem bija runājis. Un vai mēs lai darām lielu ļaunumu pret savām dvēselēm?
20 (Bákan náà Uriah ọmọ Ṣemaiah láti Kiriati-Jearimu jẹ́ ọkùnrin mìíràn tí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà ní orúkọ Olúwa. Ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà sí ìlú náà àti ilẹ̀ yín bí Jeremiah ti ṣe.
Un atkal viens vīrs bija sludinājis Tā Kunga Vārdā, Ūrija, Šemajas dēls, no KiriatIearimas, un tas sludināja pret šo pilsētu un šo zemi ar tādiem pat vārdiem kā Jeremija.
21 Nígbà tí ọba Jehoiakimu àti gbogbo àwọn aláṣẹ gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀, ọba ń wá láti pa á: ṣùgbọ́n Uriah gbọ́ èyí, ẹ̀rù bà á, ó sì sálọ sí Ejibiti.
Kad nu ķēniņš Jojaķims un visi viņa varenie un visi lielkungi viņa vārdus dzirdēja, tad ķēniņš viņu meklēja nokaut. Bet Ūrija to dzirdējis bijās un bēga un nāca uz Ēģiptes zemi.
22 Ọba Jehoiakimu rán Elnatani ọmọ Akbori lọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mìíràn.
Bet ķēniņš Jojaķims sūtīja vīrus uz Ēģiptes zemi, Elnatanu, Akbora dēlu, un citus vīrus uz Ēģipti.
23 Wọ́n sì mú Uriah láti Ejibiti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Jehoiakimu; ẹni tí ó fi idà pa, ó sì sọ òkú rẹ̀ sí inú isà òkú àwọn ènìyàn lásán.)
Tie izveda Ūriju no Ēģiptes un atveda pie ķēniņa Jojaķima, un tas viņu nokāva ar zobenu, un meta viņa miesas zemu ļaužu kapos.
24 Ahikamu ọmọ Ṣafani ń bẹ pẹ̀lú Jeremiah, wọn kò sì fi í lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti pa á.
Bet Aīkama, Safana dēla, roka bija ar Jeremiju, ka viņš tiem ļaudīm netapa rokā dots, viņu nokaut.

< Jeremiah 26 >