< Jeremiah 26 >
1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìjọba ọba Jehoiakimu ọmọ Josiah tí ń ṣe ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa:
Au début du règne de Joïakim, fils de Josias, roi de Juda, la parole que voici arriva de la part de l’Eternel:
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Dúró ní àgbàlá ilé Olúwa, kí o sì sọ fún gbogbo ènìyàn ilẹ̀ Juda tí ó ti wá láti wá jọ́sìn ní ilé Olúwa, sọ fún gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ; má ṣaláìsọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà.
Ainsi parle l’Eternel: "Tiens-toi dans la cour de la maison de l’Eternel, et adresse aux gens de toutes les villes de Juda qui sont venus se prosterner dans la maison de l’Eternel toutes les paroles que je t’ordonne de leur adresser; n’en retranche pas un mot.
3 Bóyá gbogbo wọn máa gbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn yóò kúrò nínú ìwà búburú wọn. Èmi ó yí ọkàn padà, n kò sì ní fi ibi tí mo ti rò sí wọn ṣe wọ́n.
Peut-être écouteront-ils, se repentiront-ils chacun de leur mauvaise conduite et pourrai-je révoquer le malheur que je me propose de leur infliger à cause de la perversité de leurs actes.
4 Sọ fún wọn wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Tí ẹ kò bá fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, tí ẹ kò sì gbọ́ òfin mi, ti mo gbé kalẹ̀ níwájú yín,
Tu leur diras donc: Ainsi parle l’Eternel: Si vous refusez de m’écouter, de suivre ma doctrine que j’ai promulguée devant vous,
5 àti tí ẹ kò bá gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì tí mo rán sí i yín léraléra (ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́),
d’obéir aux paroles de mes serviteurs les prophètes que sans cesse et dès la première heure j’envoie vers vous, sans que vous leur prêtiez attention,
6 nígbà náà ni èmi yóò ṣe ilé yìí bí Ṣilo, èmi yóò sì ṣe ìlú yìí ní ìfibú sí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé.’”
je traiterai cette maison pareillement à silo, et de cette ville je ferai un objet de malédiction pour tous les peuples de la terre."
7 Àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo ènìyàn ni ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Jeremiah tí ó sọ ní ilé Olúwa.
Or, les prêtres, les prophètes et tout le peuple entendirent Jérémie prononcer ces paroles dans la maison de Dieu.
8 Ṣùgbọ́n ní kété tí Jeremiah ti parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí Olúwa pàṣẹ láti sọ; àwọn àlùfáà, àti gbogbo ènìyàn dìímú, wọ́n sì wí pé, “Kíkú ni ìwọ yóò kú!
Et quand Jérémie eut achevé de dire ce que l’Eternel lui avait ordonné de dire à tout le peuple, les prêtres, les prophètes et tout le peuple se saisirent de lui en s’écriant: "Il faut que tu meures!
9 Kí ló dé tí ìwọ ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa pé, ilé yìí yóò dàbí Ṣilo, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro tí kì yóò ní olùgbé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì kójọpọ̀ pẹ̀lú Jeremiah nínú ilé Olúwa.
Pourquoi as-tu prophétisé au nom de l’Eternel en disant: Cette maison deviendra semblable à silo, et cette ville sera ruinée, privée d’habitants?" Tout le peuple s’attroupa autour de Jérémie dans la maison de Dieu.
10 Nígbà tí àwọn aláṣẹ Juda gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, wọ́n lọ láti ààfin ọba sí ilé Olúwa, wọ́n sì mú ààyè wọn, wọ́n jókòó ní ẹnu-ọ̀nà tuntun ilé Olúwa.
Lorsque les grands de Juda eurent connaissance de ces faits, ils se rendirent du palais du roi au Temple de l’Eternel et prirent place à l’entrée de la porte Neuve de l’Eternel.
11 Àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì sọ fún àwọn aláṣẹ àti gbogbo ènìyàn pé, “Arákùnrin yìí gbọdọ̀ gba ìdájọ́ ikú nítorí pé ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórí ìlú yìí: bí ẹ̀yin ti fi etí yín gbọ́!”
Alors les prêtres et les prophètes dirent aux grands et à tout le peuple: "Cet homme mérite la mort, car il a prophétisé contre cette ville, comme vous l’avez entendu de vos propres oreilles."
12 Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún gbogbo àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn wí pé: “Olúwa rán mi láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ilé yìí àti ìlú yìí, gbogbo ohun tí ẹ ti gbọ́.
Jérémie, s’adressant à tous les grands et au peuple entier, leur dit: "C’Est l’Eternel qui m’a envoyé pour prophétiser contre cette maison et contre cette ville toutes les paroles que vous avez entendues.
13 Nísinsin yìí, tún ọ̀nà rẹ ṣe àti ìṣe rẹ, kí ẹ sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín. Olúwa yóò yí ọkàn rẹ̀ padà, kò sì ní mú ohun gbogbo tí ó ti sọ jáde ní búburú ṣẹ lórí yín.
Or, donc, améliorez votre conduite et vos oeuvres, écoutez la voix de l’Eternel, votre Dieu, pour que l’Eternel révoque le malheur qu’il a décrété contre vous.
14 Bí ó bá ṣe tèmi ni, èmi wà ní ọwọ́ yín, ẹ ṣe ohun tí ẹ̀yin bá rò pé ó dára, tí ó sì tọ́ lójú yín fún mi.
Quant à moi, je suis en votre pouvoir, traitez-moi comme il vous paraîtra bon et équitable.
15 Ẹ mọ̀ dájú pé tí ẹ bá pa mí, ẹ ó mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ wá sórí ara yín, sórí ìlú yìí àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; nítorí pé nítòótọ́ ni Olúwa ti rán mi láti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún un yín.”
Toutefois, sachez bien que si vous me faites mourir, c’est du sang innocent que vous répandez sur vous, sur cette ville et ses habitants; car, en vérité, c’est l’Eternel qui m’a envoyé vers vous, pour faire entrer dans vos oreilles tous ces discours que je tiens."
16 Nígbà náà ni àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì pé, “Ẹ má ṣe pa ọkùnrin yìí nítorí ó ti bá wa sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.”
Alors les grands et tout le peuple dirent aux prêtres et aux prophètes: "Cet homme ne mérite pas la mort, car c’est au nom de l’Eternel, notre Dieu, qu’il nous a parlé."
17 Lára àwọn àgbàgbà ilẹ̀ náà sì sún síwájú, wọ́n sì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé,
Puis, quelques-uns parmi les anciens du pays se levèrent et s’adressèrent en ces termes à toute l’assemblée du peuple:
18 “Mika ti Moreṣeti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Ó sọ fún gbogbo ènìyàn Juda pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘A ó sì fa Sioni tu bí oko Jerusalẹmu yóò di òkìtì àlàpà àti òkè ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ibi gíga igbó.’
"Michée, de Moréchet, prophétisait du temps d’Ezechias, roi de Juda, et voici ce qu’il disait à tout le peuple de Juda: Ainsi a parlé l’Eternel-Cébaoth: Sion sera labourée comme un champ, Jérusalem deviendra un monceau de ruines et la montagne du Temple une hauteur boisée.
19 Ǹjẹ́ Hesekiah ọba Juda tàbí ẹnikẹ́ni ní Juda pa á bí? Ǹjẹ́ Hesekiah kò bẹ̀rù Olúwa tí ó sì wá ojúrere rẹ̀? Ǹjẹ́ Olúwa kò ha a sì yí ìpinnu rẹ̀ padà, tí kò sì mú ibi tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ yẹ̀ kúrò lórí wọn? Ibi ni a fẹ́ mú wá sórí ara wa yìí.”
Ezéchias, roi de Juda, et tout le peuple de Juda l’ont-ils condamné à mourir? N’A-t-on pas craint l’Eternel et cherché à apaiser sa colère? Aussi l’Eternel révoqua-t-il le mal qu’il avait décrété contre eux; et nous, nous chargerions nos âmes d’un si grand crime!"
20 (Bákan náà Uriah ọmọ Ṣemaiah láti Kiriati-Jearimu jẹ́ ọkùnrin mìíràn tí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà ní orúkọ Olúwa. Ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà sí ìlú náà àti ilẹ̀ yín bí Jeremiah ti ṣe.
Il y eut encore un homme qui prophétisait au nom de l’Eternel: c’était Ouria, fils de Chemaya, de Kiriat-Yearim. II prophétisait contre cette ville et contre ce pays exactement dans les mêmes termes que Jérémie.
21 Nígbà tí ọba Jehoiakimu àti gbogbo àwọn aláṣẹ gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀, ọba ń wá láti pa á: ṣùgbọ́n Uriah gbọ́ èyí, ẹ̀rù bà á, ó sì sálọ sí Ejibiti.
Le roi Joïakim eut connaissance de ses discours ainsi que tous ses hommes de guerre et tous les grands, et il chercha à le mettre à mort. Ouria en fut informé, il prit peur, s’enfuit et se rendit en Egypte.
22 Ọba Jehoiakimu rán Elnatani ọmọ Akbori lọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mìíràn.
Alors le roi Joïakim envoya des gens en Egypte: c’était Elnathan, fils d’Akhbor, et quelques autres avec lui pour l’accompagner en Egypte.
23 Wọ́n sì mú Uriah láti Ejibiti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Jehoiakimu; ẹni tí ó fi idà pa, ó sì sọ òkú rẹ̀ sí inú isà òkú àwọn ènìyàn lásán.)
Ils firent sortir Ouria hors d’Egypte et l’amenèrent au roi Joïakim, qui le fit périr par le glaive et ordonna de jeter son cadavre parmi les tombes du bas peuple.
24 Ahikamu ọmọ Ṣafani ń bẹ pẹ̀lú Jeremiah, wọn kò sì fi í lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti pa á.
Toutefois, Ahi’kam, fils de Chafan, protégea Jérémie et empêcha qu’il ne fût livré au pouvoir du peuple et mis à mort.