< Jeremiah 26 >

1 Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìjọba ọba Jehoiakimu ọmọ Josiah tí ń ṣe ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa:
In the bigynnyng of the rewme of Joachym, the sone of Josie, kyng of Juda, this word was maad of the Lord, and seide,
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Dúró ní àgbàlá ilé Olúwa, kí o sì sọ fún gbogbo ènìyàn ilẹ̀ Juda tí ó ti wá láti wá jọ́sìn ní ilé Olúwa, sọ fún gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ; má ṣaláìsọ gbogbo ọ̀rọ̀ náà.
The Lord seide these thingis, Stonde thou in the porche of the hous of the Lord, and thou schalt speke to alle the citees of Juda, fro whiche thei comen for to worschipe in the hous of the Lord, alle the wordis whiche Y comaundide to thee, that thou speke to hem; nyle thou withdrawe a word;
3 Bóyá gbogbo wọn máa gbọ́ ọ̀rọ̀ náà tí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn yóò kúrò nínú ìwà búburú wọn. Èmi ó yí ọkàn padà, n kò sì ní fi ibi tí mo ti rò sí wọn ṣe wọ́n.
if perauenture thei heren, and ben conuertid, ech man fro his yuele weie, and it repente me of the yuel which Y thouyte to do to hem for the malices of her studies.
4 Sọ fún wọn wí pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Tí ẹ kò bá fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, tí ẹ kò sì gbọ́ òfin mi, ti mo gbé kalẹ̀ níwájú yín,
And thou schalt seie to hem, The Lord seith these thingis, If ye heren not me, that ye go in my lawe which Y yaf to you,
5 àti tí ẹ kò bá gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì tí mo rán sí i yín léraléra (ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́),
that ye here the wordis of my seruauntis, profetis, whiche Y risynge bi niyte, and dressynge, sente to you, and ye herden not;
6 nígbà náà ni èmi yóò ṣe ilé yìí bí Ṣilo, èmi yóò sì ṣe ìlú yìí ní ìfibú sí gbogbo orílẹ̀-èdè ayé.’”
Y schal yyue this hous as Silo, and Y schal yyue this citee in to cursyng to alle folkis of erthe.
7 Àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo ènìyàn ni ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Jeremiah tí ó sọ ní ilé Olúwa.
And the prestis, and profetis, and al the puple herden Jeremye spekynge these wordis in the hous of the Lord.
8 Ṣùgbọ́n ní kété tí Jeremiah ti parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ tí Olúwa pàṣẹ láti sọ; àwọn àlùfáà, àti gbogbo ènìyàn dìímú, wọ́n sì wí pé, “Kíkú ni ìwọ yóò kú!
And whanne Jeremye hadde fillid spekynge alle thingis, whiche the Lord hadde comaundid to hym, that he schulde speke to al the puple, the prestis, and profetis, and al the puple token hym, and seiden, Die he bi deeth;
9 Kí ló dé tí ìwọ ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa pé, ilé yìí yóò dàbí Ṣilo, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro tí kì yóò ní olùgbé.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì kójọpọ̀ pẹ̀lú Jeremiah nínú ilé Olúwa.
whi profesiede he in the name of the Lord, and seide, This hous schal be as Silo, and this citee schal be desolat, for no dwellere is? And al the puple was gaderid togidere ayens Jeremye, in the hous of the Lord.
10 Nígbà tí àwọn aláṣẹ Juda gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, wọ́n lọ láti ààfin ọba sí ilé Olúwa, wọ́n sì mú ààyè wọn, wọ́n jókòó ní ẹnu-ọ̀nà tuntun ilé Olúwa.
And the princes of Juda herden alle these wordis; and thei stieden fro the kyngis hous in to the hous of the Lord, and saten in the entryng of the newe yate of the hous of the Lord.
11 Àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì sọ fún àwọn aláṣẹ àti gbogbo ènìyàn pé, “Arákùnrin yìí gbọdọ̀ gba ìdájọ́ ikú nítorí pé ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórí ìlú yìí: bí ẹ̀yin ti fi etí yín gbọ́!”
And the prestis and profetis spaken to the princes, and to al the puple, and seiden, Doom of deth is to this man, for he profesiede ayens this citee, as ye herden with youre eeris.
12 Nígbà náà ni Jeremiah sọ fún gbogbo àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn wí pé: “Olúwa rán mi láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ilé yìí àti ìlú yìí, gbogbo ohun tí ẹ ti gbọ́.
And Jeremye seide to alle the princes, and to al the puple, `and seide, The Lord sente me, that Y schulde prophesie to this hous, and to this citee, alle the wordis whiche ye herden.
13 Nísinsin yìí, tún ọ̀nà rẹ ṣe àti ìṣe rẹ, kí ẹ sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run yín. Olúwa yóò yí ọkàn rẹ̀ padà, kò sì ní mú ohun gbogbo tí ó ti sọ jáde ní búburú ṣẹ lórí yín.
Now therfor make ye good youre weies, and youre studies, and here ye the vois of youre Lord God; and it schal repente the Lord of the yuel which he spak ayens you.
14 Bí ó bá ṣe tèmi ni, èmi wà ní ọwọ́ yín, ẹ ṣe ohun tí ẹ̀yin bá rò pé ó dára, tí ó sì tọ́ lójú yín fún mi.
Lo! forsothe Y am in youre hondis; do ye to me, as it is good and riytful bifore youre iyen.
15 Ẹ mọ̀ dájú pé tí ẹ bá pa mí, ẹ ó mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ wá sórí ara yín, sórí ìlú yìí àti àwọn olùgbé inú rẹ̀; nítorí pé nítòótọ́ ni Olúwa ti rán mi láti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún un yín.”
Netheles wite ye, and knowe, that if ye sleen me, ye schulen bitraie innocent blood ayens you silf, and ayens this citee, and the dwelleris therof; for in trewthe the Lord sente me to you, that Y schulde speke in youre eeris alle these wordis.
16 Nígbà náà ni àwọn aláṣẹ àti gbogbo àwọn ènìyàn sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì pé, “Ẹ má ṣe pa ọkùnrin yìí nítorí ó ti bá wa sọ̀rọ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.”
And the princes and al the puple seiden to the preestis and profetis, Doom of deth is not to this man; for he spak to vs in the name of oure Lord God.
17 Lára àwọn àgbàgbà ilẹ̀ náà sì sún síwájú, wọ́n sì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé,
Therfor men of the eldere men of the lond rysiden vp, and seiden to al the cumpanye of the puple,
18 “Mika ti Moreṣeti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní ọjọ́ Hesekiah ọba Juda. Ó sọ fún gbogbo ènìyàn Juda pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘A ó sì fa Sioni tu bí oko Jerusalẹmu yóò di òkìtì àlàpà àti òkè ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ibi gíga igbó.’
and spaken, Mychee of Morasten was a profete in the daies of Ezechie, king of Juda; and he seide to al the puple of Juda, and seide, The Lord of oostis seith these thingis, Sion schal be erid as a feeld, and Jerusalem schal be in to an heep of stoonys, and the hil of the hous of the Lord schal be in to hiy thingis of woodis.
19 Ǹjẹ́ Hesekiah ọba Juda tàbí ẹnikẹ́ni ní Juda pa á bí? Ǹjẹ́ Hesekiah kò bẹ̀rù Olúwa tí ó sì wá ojúrere rẹ̀? Ǹjẹ́ Olúwa kò ha a sì yí ìpinnu rẹ̀ padà, tí kò sì mú ibi tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ yẹ̀ kúrò lórí wọn? Ibi ni a fẹ́ mú wá sórí ara wa yìí.”
Whether Ezechie, kyng of Juda, and al Juda condempnede hym bi deth? Whether thei dredden not the Lord, and bisouyten the face of the Lord? and it repentide the Lord of the yuel which he spak ayens hem. Therfor do we not greet yuel ayens oure soulis.
20 (Bákan náà Uriah ọmọ Ṣemaiah láti Kiriati-Jearimu jẹ́ ọkùnrin mìíràn tí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà ní orúkọ Olúwa. Ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ kan náà sí ìlú náà àti ilẹ̀ yín bí Jeremiah ti ṣe.
Also Vrye, the sone of Semey, of Cariathiarym, was a man profesiynge in the name of the Lord; and he profesiede ayens this citee, and ayens this lond, bi alle the wordis of Jeremye.
21 Nígbà tí ọba Jehoiakimu àti gbogbo àwọn aláṣẹ gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀, ọba ń wá láti pa á: ṣùgbọ́n Uriah gbọ́ èyí, ẹ̀rù bà á, ó sì sálọ sí Ejibiti.
And kyng Joachym, and alle the myyti men, and princes of hem, herden these wordis; and the kyng souyte to sle hym; and Vrye herde, and dredde, and he fledde, and entride in to Egipt.
22 Ọba Jehoiakimu rán Elnatani ọmọ Akbori lọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ọkùnrin mìíràn.
And kyng Joachym sente men in to Egipt, Elnathan, the sone of Achobor, and men with hym, in to Egipt;
23 Wọ́n sì mú Uriah láti Ejibiti lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Jehoiakimu; ẹni tí ó fi idà pa, ó sì sọ òkú rẹ̀ sí inú isà òkú àwọn ènìyàn lásán.)
and thei ledden Vrye out of Egipt, and brouyten hym to kyng Joachym; and the kyng killide hym bi swerd, and castide forth his careyn in the sepulcris of the comyn puple vnnoble.
24 Ahikamu ọmọ Ṣafani ń bẹ pẹ̀lú Jeremiah, wọn kò sì fi í lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́ láti pa á.
Therfor the hond of Aicham, sone of Saphan, was with Jeremye, that he was not bitakun in to the hondis of the puple, and that it killide not hym.

< Jeremiah 26 >