< Jeremiah 25 >

1 Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
Detta är det ord som kom till Jeremia angående hela Juda folk, i Jojakims, Josias sons, Juda konungs, fjärde regeringsår, vilket var Nebukadressars, den babyloniske konungens, första regeringsår.
2 Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
Och detta ord talade profeten Jeremia till hela Juda folk och till alla Jerusalems invånare; han sade:
3 Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Allt ifrån Josias, Amons sons, Juda konungs, trettonde regeringsår ända till denna dag, eller nu under tjugutre år, har HERRENS ord kommit till mig; men fastän jag titt och ofta har talat till eder, haven I icke velat höra.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Och fastän HERREN titt och ofta har sänt till eder alla sina tjänare profeterna, haven I icke velat höra. I böjden icke edra öron till att höra,
5 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
när de sade: "Vänden om, var och en från sin onda väg och sitt onda väsende, så skolen I för evärdliga tider få bo kvar i det land som HERREN har givit åt eder och edra fäder.
6 Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
Och följen icke efter andra gudar, så att I tjänen och tillbedjen dem; och förtörnen mig icke genom edra händers verk, på det att jag icke må låta olycka komma över eder.
7 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
I villen icke höra på mig, säger HERREN, och så förtörnaden I mig genom edra händers verk, eder själva till olycka.
8 Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
Därför säger HERREN Sebaot så: Eftersom I icke villen höra mina ord,
9 Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
därför skall jag sända åstad och hämta alla nordens folkstammar, säger HERREN, och skall sända bud till min tjänare Nebukadressar, konungen i Babel; och jag skall låta dem komma över detta land och dess inbyggare, så ock över alla folken här runt omkring. Och dem skall jag giva till spillo, och skall göra dem till ett föremål för häpnad och begabberi, och låta deras land bliva ödemarker för evärdlig tid.
10 Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
Och jag skall i dem göra slut på fröjderop och glädjerop, på rop för brudgum och rop för brud, på buller av kvarn och ljus från lampa.
11 Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
Ja, hela detta land skall bliva ödelagt och förött, och dessa folk skola vara Babels konung underdåniga i sjuttio år.
12 “Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
Men när sjuttio år äro till ända skall jag hemsöka konungen i Babel och folket där för deras missgärning, säger HERREN, och hemsöka kaldéernas land och göra det till en ödemark för evärdlig tid.
13 Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
Och jag skall på det landet låta alla de ord fullbordas, som jag har talat mot det, allt vad som är skrivet i denna bok, och vad Jeremia har profeterat mot alla dessa folk.
14 Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
Ty också dem skola mäktiga folk och stora konungar göra sig underdåniga, och jag skall vedergälla dem efter deras gärningar och deras händers verk.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
Ty så sade HERREN, Israels Gud, till mig: "Tag denna kalk med vredesvin ur min hand, och giv alla de folk till vilka jag sänder dig att dricka därur.
16 Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
Må de dricka, så att de ragla och mista sansen, när det svärd kommer, som jag skall sända ibland dem."
17 Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
Och jag tog kalken ur HERRENS hand och gav alla de folk att dricka, till vilka HERREN sände mig,
18 Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
nämligen Jerusalem med Juda städer och med dess konungar och furstar, för att så göra dem till en ödemark, och till ett föremål för häpnad och begabberi, och till ett exempel som man nämner, när man förbannar, såsom ock nu har skett;
19 Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
vidare Farao, konungen i Egypten, med hans tjänare, hans furstar och allt hans folk,
20 Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
så ock allt Erebs folk med alla konungar i Us' land och alla konungar i filistéernas land, både Askelon och Gasa och Ekron och kvarlevan i Asdod;
21 Edomu, Moabu àti Ammoni;
vidare Edom, Moab och Ammons barn;
22 gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
vidare alla konungar i Tyrus, alla konungar i Sidon och konungarna i kustländerna på andra sidan havet;
23 Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
vidare Dedan, Tema, Bus och alla dem som hava kantklippt hår;
24 Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
vidare alla konungar i Arabien och alla konungar över Erebs folk, som bo i öknen,
25 Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
så ock alla konungar i Simri, alla konungar i Elam och alla konungar i Medien,
26 Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
slutligen alla konungar i nordlandet -- både dem som bo nära och dem som bo fjärran, den ene såväl som den andre -- och alla övriga riken i världen, utöver jordens yta. Och Sesaks konung skall dricka efter dem.
27 “Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
Och du skall säga till dem: Så säger HERREN Sebaot, Israels Gud: Dricken, så att I bliven druckna, och spyn, och fallen omkull utan att kunna stå upp; ja, fallen, när det svärd kommer, som jag skall sända bland eder. --
28 Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
Men om de icke vilja taga emot kalken ur din hand och dricka, så säg till dem: Så säger HERREN Sebaot: I måsten dricka.
29 Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
Ty se, med den stad som är uppkallad efter mitt namn skall jag begynna hemsökelsen. Skullen då I bliva ostraffade? Nej, I skolen icke bliva ostraffade, utan jag skall båda upp ett svärd mot jordens alla inbyggare, säger HERREN Sebaot.
30 “Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
Och du skall profetera för dem allt detta och säga till dem: HERREN upphäver ett rytande från höjden och från sin heliga boning låter han höra sin röst; ja, han upphäver ett högt rytande över sin ängd och höjer skördeskri, såsom en vintrampare, över alla jordens inbyggare.
31 Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
Dånet höres intill jordens ända, ty HERREN har sak med folken, han går till rätta med allt kött; de ogudaktiga giver han till pris åt svärdet, säger HERREN.
32 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
Så säger HERREN Sebaot: Se, en olycka går fram ifrån det ena folket till det andra, och ett stort oväder stiger upp från jordens yttersta ända.
33 Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
Och de som bliva slagna av HERREN på den tiden skola ligga strödda från jordens ena ända till den andra; man skall icke hålla dödsklagan efter dem eller samla dem tillhopa och begrava dem, utan de skola bliva gödsel på marken.
34 Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
Jämren eder, I herdar, och klagen; vältren eder på marken, I väldige i hjorden; ty tiden är inne, att I skolen slaktas. I skolen bliva förskingrade, I skolen komma på fall, såsom det händer jämväl ett dyrbart kärl.
35 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
Då finnes icke mer någon undflykt för herdarna, icke mer någon räddning för de väldige i hjorden.
36 Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
Hör huru herdarna ropa, huru de väldige i hjorden jämra sig! Ty HERREN ödelägger deras betesmark,
37 Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
och de fredliga ängderna förgöras genom HERRENS vredes glöd.
38 Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
Han drager ut såsom ett lejon ur sitt snår. Ja, deras land bliver en ödemark under förhärjelsens glöd, under hans vredes glöd.

< Jeremiah 25 >