< Jeremiah 25 >

1 Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
Dette er det ord som kom til Jeremias om hele Judas folk i Judas konge Jojakims, Josias' sønns fjerde år, det er Babels konge Nebukadnesars første år,
2 Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
og som profeten Jeremias talte til hele Judas folk og til alle Jerusalems innbyggere:
3 Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Fra Judas konge Josias', Amons sønns trettende år og like til denne dag, nu i tre og tyve år, er Herrens ord kommet til mig, og jeg har talt til eder tidlig og sent, men I hørte ikke.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Og Herren sendte til eder alle sine tjenere, profetene, tidlig og sent; men I hørte ikke, og I bøide ikke eders øre til å høre.
5 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
Han sa: Vend om, hver fra sin onde vei, og fra eders onde gjerninger! Så skal I få bo i det land Herren gav eder og eders fedre, fra evighet og til evighet.
6 Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
Følg ikke andre guder, så I dyrker dem og tilbeder dem, og vekk ikke min harme ved eders henders verk, forat jeg ikke skal gjøre eder noget ondt!
7 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
Men I hørte ikke på mig, sier Herren, I vakte min harme ved eders henders verk, til ulykke for eder selv.
8 Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
Derfor sier Herren, hærskarenes Gud, så: Fordi I ikke har hørt på mine ord,
9 Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
se, så sender jeg bud og henter alle Nordens folkeslag, sier Herren, og jeg sender bud til Babels konge Nebukadnesar, min tjener, og jeg lar dem komme over dette land og over dets innbyggere og over alle folkeslagene her rundt omkring, og jeg slår dem med bann og gjør dem til en forferdelse og til en spott og deres land til evige ørkener,
10 Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
og jeg lar fryds røst og gledes røst, brudgoms røst og bruds røst, lyd av kvern og lys av lampe bli borte hos dem.
11 Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
Og hele dette land skal bli til en ørken, til en ødemark, og disse folkeslag skal tjene Babels konge i sytti år.
12 “Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
Men når sytti år er til ende, da vil jeg hjemsøke kongen i Babel og folket der, sier Herren, for deres misgjernings skyld, og jeg vil hjemsøke kaldeernes land og gjøre det til evige ørkener.
13 Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
Og jeg vil la komme over det land alle de ord som jeg har talt om det, alt det som er skrevet i denne bok, det som Jeremias har profetert om alle folkeslagene.
14 Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
For mange folkeslag og store konger skal gjøre også dem til træler, og jeg vil gjengjelde dem efter deres gjerning og efter deres henders verk.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
For så sa Herren, Israels Gud, til mig: Ta dette beger med vredesvin av min hånd og gi alle de folk jeg sender dig til, å drikke av det!
16 Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
Og de skal drikke og rave og te sig som rasende for det sverd jeg sender iblandt dem.
17 Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
Og jeg tok begeret av Herrens hånd, og jeg gav alle de folk å drikke som Herren hadde sendt mig til:
18 Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
Jerusalem og Judas byer og dets konger og dets høvdinger, for å gjøre dem til en ørken, til en ødemark, til en spott og til en forbannelse, således som det er på denne dag,
19 Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Egyptens konge Farao og hans tjenere og hans høvdinger og hele hans folk
20 Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
og alle hans fremmede undersåtter og alle kongene i landet Us og alle kongene i filistrenes land, i Askalon og Gasa og Ekron og det som er tilbake av Asdod,
21 Edomu, Moabu àti Ammoni;
Edom og Moab og Ammons barn
22 gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
og alle Tyrus' konger og alle Sidons konger og kongene over kystlandet på hin side havet,
23 Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
Dedan og Tema og Bus og alle med rundklippet hår
24 Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
og alle Arabias konger og alle kongene over de fremmede folk som bor i ørkenen,
25 Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
og alle Simris konger og alle Elams konger og alle Medias konger
26 Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
og alle Nordens konger, nær og fjern, den ene med den andre, og alle verdens riker utover hele jorden; og Sesaks konge skal drikke efter dem.
27 “Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
Og du skal si til dem: Så sier Herren, hærskarenes Gud, Israels Gud: Drikk og bli drukne og spy og fall og reis eder ikke mere - for det sverd jeg sender iblandt eder!
28 Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
Men dersom de ikke vil ta begeret av din hånd og drikke, da skal du si til dem: Så sier Herren, hærskarenes Gud: Drikke skal I.
29 Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
For se, den by som er kalt med mitt navn, lar jeg ulykken ramme først, og så skulde I bli ustraffede? Nei, I skal ikke bli ustraffede; for sverd kaller jeg hit over alle dem som bor på jorden, sier Herren, hærskarenes Gud.
30 “Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
Og du skal profetere for dem alt dette og si til dem: Herren skal brøle fra det høie og la sin røst høre fra sin hellige bolig; ja, brøle skal han over sin beitemark, et skrik lik deres som treder vinpersen, skal han opløfte over alle dem som bor på jorden.
31 Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
Bulderet når til jordens ende, for Herren har strid med folkene, han går i rette med alt kjød; de ugudelige overgir han til sverdet, sier Herren.
32 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
Så sier Herren, hærskarenes Gud: Se, ulykke går ut fra folk til folk, og en svær storm reiser sig fra jordens ytterste ende.
33 Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
Og de som Herren har drept, skal på den dag ligge fra jordens ene ende til den andre; ingen skal gråte over dem, ingen skal samle dem op og begrave dem; til gjødsel utover jorden skal de bli.
34 Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
Hyl, I hyrder, og skrik og velt eder i støvet, I som er de gjeveste i hjorden! For tiden er kommet da I skal slaktes, og jeg vil adsprede eder, og I skal falle som et kostelig kar,
35 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
og hyrdene skal ikke mere ha noget tilfluktssted, og de gjeveste i hjorden skal ikke finne redning.
36 Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
Hør hvorledes hyrdene skriker og de gjeveste i hjorden hyler! For Herren ødelegger deres beite,
37 Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
og de fredelige enger blir øde for Herrens brennende vrede.
38 Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
Som en ung løve går han frem fra sitt skjul; ja, deres land blir til en ødemark for det herjende sverd og for hans brennende vrede.

< Jeremiah 25 >