< Jeremiah 25 >

1 Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
Az ige, mely Jirmejáhúhoz lett, Jehúda egész népe felől, Jehójákim, Jósijáhú fiának, Jehúda királyának negyedik évében, első éve az Nebúkadnecczárnak, Bábel királyának,
2 Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
melyet szólt Jirmejáhú próféta Jehúda egész népéhez és mind a Jeruzsálem lakóihoz, mondván:
3 Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Jósijáhú, Ámón fiának, Jehúda királyának tizenharmadik évétől mind e mai napig, immár huszonhárom éve lett hozzám az Örökkévaló igéje és én beszéltem hozzátok, reggelenként beszélve, de ti nem hallottátok.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Küldte az Örökkévaló hozzátok mind az ő szolgáit, a prófétákat, reggelenként küldve – de ti nem hallottátok és nem hajlítottátok fületeket a hallásra –
5 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
mondván: térjetek csak meg kiki rossz útjáról és cselekedeteitek rosszaságától, hogy lakhassatok a földön, melyet az Örökkévaló adott nektek és őseiteknek, öröktől örökké;
6 Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
és ne járjatok más istenek után, szolgálva őket és leborulva előttük, és ne bosszantsatok engem kezeitek művével, hogy rosszat ne tegyek veletek.
7 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
De nem hallgattatok rám, úgymond az Örökkévaló, azért hogy bosszantsatok engem kezeitek művével, hogy rosszul járjatok.
8 Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
Azért így szól az Örökkévaló, a seregek ura: Mivelhogy nem hallgattatok szavaimra,
9 Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
íme én küldök és veszem mind az észak nemzetségeit, úgymond az Örökkévaló, meg Nebúkadnecczárhoz, Bábel királyához, az én szolgámhoz, és elhozom őket ez ország ellen és lakói ellen és mind a nemzetek ellen köröskörül; kipusztítom őket és teszem őket iszonyodássá és pisszegéssé és örök romokká.
10 Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
És eltüntetem tőlük a vígság hangját és öröm hangját, vőlegény hangját és menyasszony hangját, malomnak hangját és mécsesnek világát.
11 Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
És ez egész ország rommá és pusztulássá lesz és szolgálni fogják e nemzetek Bábel királyát hetven évig.
12 “Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
És lesz, amint eltelt hetven év, megbüntetem Bábel királyán és ama nemzeten, úgymond az Örökkévaló, az ő bűnüket, meg Kaszdím országán, és teszem azt örök pusztasággá.
13 Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
És elhozom amaz országra mind a szavaimat, melyeket szóltam felőle, mindazt, ami írva van a könyvben, amit prófétált Jirmejáhú mind a nemzetek felől.
14 Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
Mert leigázzák őket is számos nemzetek és nagy királyok; és fizetek nekik tettük szerint és kezeik műve szerint.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
Mert így szólt hozzám az Örökkévaló, Izrael Istene: Vedd kezemből a harag borának a serlegét és itasd azt meg mind a nemzetekkel, melyekhez téged küldlek;
16 Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
igyanak és inogjanak meg és tomboljanak a kard miatt, amelyet közéjük küldök.
17 Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
Vettem a serleget az Örökkévaló kezéből és megitattam mind a nemzetekkel, amelyekhez az Örökkévaló engem küldött:
18 Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
Jeruzsálemmel és Jehúda varosaival, királyaival és nagyjaival, hogy tegyem őket rommá, iszonyodássá, pisszegéssé és átokká, mint az e mai napon van;
19 Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Fáraóval, Egyiptom királyával, meg szolgáival és nagyjaival és egész népével;
20 Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
és az egész Érebbel és Úcz országának mind a királyaival és a filiszteusok országának mind a királyaival: Askalónnal, Azzával, Ekrónnal és Asdód maradékával;
21 Edomu, Moabu àti Ammoni;
Edómmal, Móábbal és Ammón fiaival;
22 gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
Czór minden királyaival és Czídón minden királyaival, meg a sziget királyaival, mely a tengeren túl van;
23 Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
Dedánnal, Témával, Búzzal és mind a levágott hajszélűekkel;
24 Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
Arábia minden királyaival és az Éreb minden királyaival, akik a pusztában laknak;
25 Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
Zimri minden királyaival, Élám minden királyaival és Média minden királyaival;
26 Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
meg mind az észak királyaival, a közel levőkkel és távol levőkkel egymás után és mind a föld királyságaival, melyek a föld színén vannak – Sésák királya pedig azok után fog inni.
27 “Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
És szólj hozzájuk: Így szól az Örökkévaló, a seregek ura, Izrael Istene: igyatok, részegedjetek és okádjatok, essetek el és ne keljetek föl a kard miatt, melyet közitekbe küldök.
28 Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
És lesz, midőn vonakodnak elfogadni kezedből a serleget, hogy igyanak, akkor szólj hozzájuk: Így szól az Örökkévaló, a seregek ura, meg kell innotok!
29 Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
Mert íme azon városnál, mely nevemről neveztetik, megkezdem a veszedelmet, és ti büntetlenül maradnátok? Nem maradtok büntetlenül, mert kardot szólítok mind a föld lakóira, úgymond az Örökkévaló, a seregek ura.
30 “Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
Te pedig prófétáld nekik mind e szavakat és szólj hozzájuk: az Örökkévaló a magasból ordít és szent hajlékából hallatja hangját; ordítva ordít tanyájára, kurjantást, mint a sajtolók, hangoztat mind a föld lakói ellen.
31 Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
Eljut a zajongás, a föld végéig ér, mert pöre van az Örökkévalónak a nemzetekkel, ítéletre száll minden halandóval; a gonoszokat a kardnak adta át, úgymond az Örökkévaló.
32 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
Így szól az Örökkévaló, a seregek ura: Íme veszedelem indul nemzettől nemzethez és nagy szélvész kel a föld hátuljáról.
33 Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
És lesznek az Örökkévaló megöltjei azon napon föld végétől föld végéig, nem siratják őket, nem szedik össze és nem temetik el, trágyává lesznek a föld színén.
34 Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
Jajgassatok, pásztorok és kiáltsatok, porban fetrengjetek ti hatalmasai a juhoknak, mert leteltek napjaitok a vágásra; elszórlak benneteket és elhulltok, miként drága edény.
35 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
És elvész menedék a pásztorok számára és menekülés a juhok hatalmasai számára.
36 Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
Hallik a pásztorok kiáltása és a juhok hatalmasainak jajgatása, mert pusztítja az Örökkévaló legelőjüket.
37 Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
És megsemmisülnek a béke tanyái az Örökkévaló fellobbant haragja miatt.
38 Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
Elhagyta mint a fiatal oroszlán bozótját, mert pusztulássá lett országuk az elnyomó kard heve miatt és az ő fellobbant haragja miatt.

< Jeremiah 25 >