< Jeremiah 25 >

1 Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
The word of the Lord, that was maad to Jeremye, of al the puple of Juda, in the fourthe yeer of Joachym, the sone of Josie, the king of Juda, aftir that Jeconye was translatid in to Babiloyne; thilke is the firste yeer of Nabugodonosor, kyng of Babiloyne; which word Jeremy,
2 Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
the prophete, spak to al the puple of Juda, and to alle the dwelleris of Jerusalem, and seide,
3 Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Fro the threttenthe yeer of the rewme of Josie, the sone of Amon, the kyng of Juda, `til to this dai, this is the three and twentithe yeer, the word of the Lord was maad to me; and Y spak to you, and Y roos bi niyt and spak, and ye herden not.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
And the Lord sente to you alle hise seruauntis profetis, and roos ful eerli, and sente, and ye herden not, nether ye bowiden youre eeris, for to here;
5 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
whanne he seide, Turne ye ayen, ech man fro his yuel weie, and fro youre worste thouytis, and ye schulen dwelle in the lond whiche the Lord yaf to you, and to youre fadris, fro the world and til in to the world.
6 Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
And nyle ye go aftir alien goddis, that ye serue hem, and worschipe hem, nether terre ye me to wrathfulnesse, in the werkis of youre hondis, and Y schal not turmente you.
7 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
And ye herden not me, seith the Lord, that ye terreden me to wrathfulnesse in the werkis of youre hondis, in to youre yuel.
8 Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
Therfor the Lord of oostis seith these thingis, For that that ye herden not my wordis, lo!
9 Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
Y schal sende, and take alle the kynredis of the north, seith the Lord, and Nabugodonosor, my seruaunt, the kyng of Babiloyne; and Y schal bringe hem on this lond, and on the dwelleris therof, and on alle naciouns, that ben in the cumpas therof; and Y schal sle hem, and Y schal sette hem in to wondryng, and in to hissyng, and in to euerlastynge wildirnessis.
10 Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
And Y schal leese of hem the vois of ioye, and the vois of gladnesse, the vois of spouse, and the vois of spousesse, the vois of queerne, and the liyt of the lanterne.
11 Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
And al the lond therof schal be in to wildirnesse, and in to wondring; and alle these folkis schulen serue the king of Babiloyne seuenti yeer.
12 “Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
And whanne seuenti yeer ben fillid, Y schal visite on the kyng of Babiloyne, and on that folc the wickidnesse of hem, seith the Lord, and on the lond of Caldeis, and Y schal set it in to euerlastynge wildirnesses.
13 Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
And Y schal brynge on that lond alle my wordis whiche Y spak ayens it, al thing that is writun in this book; what euer thingis Jeremye profeside ayens alle folkis;
14 Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
for thei serueden to hem, whanne thei weren many folkis, and grete kingis; and Y schal yelde to hem aftir the werkis of hem, and aftir the dedis of her hondis.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
For the Lord of oostis, God of Israel, seith thus, Take thou the cuppe of wyn of this woodnesse fro myn hond, and thou schal birle therof to alle hethene men, to whiche Y schal sende thee.
16 Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
And thei schulen drynke, and schulen be disturblid, and schulen be woode of the face of swerd, which Y schal sende among hem.
17 Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
And Y took the cuppe fro the hond of the Lord, and Y birlide to alle folkis, to whiche the Lord sente me;
18 Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
to Jerusalem, and to alle the citees of Juda, and to the kyngis therof, and to the princes therof; that Y schulde yyue hem in to wildirnesse, and in to wondring, and in to hissyng, and in to cursing, as this dai is; to Farao,
19 Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
the king of Egipt, and to hise seruauntis, and to hise princes, and to al hise puple;
20 Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
and to alle men generali, to alle the kyngis of the lond Ansitidis, and to alle the kyngis of the lond of Filistiym, and to Ascalon, and to Gaza, and to Acoron, and to the residues of Azotus;
21 Edomu, Moabu àti Ammoni;
to Idumee, and to Moab, and to the sones of Amon;
22 gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
and to alle the kyngis of Tirus, and to alle the kingis of Sidon, and to the kingis of the lond of ilis that ben biyendis the see;
23 Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
and to Dedan, and Theman, and Buz, and to alle men that ben clippid on the long heer;
24 Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
and to alle the kingis of Arabie, and to alle the kingis of the west, that dwellen in desert;
25 Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
and to alle the kingis of Zambri, and to alle the kingis of Elam, and to alle the kyngis of Medeis; and to alle the kingis of the north,
26 Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
of niy and of fer, to ech man ayens his brothir; and to alle the rewmes of erthe, that ben on the face therof; and kyng Sesac schal drynke after hem.
27 “Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
And thou schalt seie to hem, The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Drynke ye, and be ye drunkun, and spue ye, and falle ye doun, and nyle ye rise fro the face of swerd which Y schal sende among you.
28 Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
And whanne thei nylen take the cuppe fro thin hond, that thei drynke, thou schalt seie to hem, The Lord of oostis seith these thingis, Ye drynkynge schulen drynke;
29 Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
for lo! in the citee in which my name is clepid to help, Y bigynne to turmente, and schulen ye as innocentis be with out peyne? ye schulen not be with out peyne, for Y clepe swerd on alle the dwelleris of erthe, seith the Lord of oostis.
30 “Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
And thou schalt profesie to hem alle these wordis, and thou schalt seie to hem, The Lord schal rore fro an hiy, and fro his hooli dwellyng place he schal yyue his vois; he rorynge schal rore on his fairnesse; a myry song, as of men tredynge in pressouris, schal be sungun ayens alle dwelleris of erthe.
31 Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
Sown is comun til to the laste partis of erthe, for whi doom is to the Lord with folkis, he is demed with ech fleisch; the Lord seith, Y haue youe wickid men to the swerd.
32 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
The Lord of oostis seith these thingis, Lo! turment schal go out fro folk in to folk, and a greet whirlwynd schal go out fro the endis of erthe.
33 Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
And the slayn men of the Lord schulen be in that dai fro the ende of the erthe `til to the ende therof; thei schulen not be biweilid, nether schulen be gaderid togidere, nether schulen be biried; thei schulen ligge in to a dunghil on the face of erthe.
34 Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
Yelle, ye scheepherdis, and crye, and, ye princypals of the floc, bispreynge you with aische; for youre daies ben fillid, that ye be slayn, and youre scateryngis ben fillid, and ye schulen falle as precious vessels.
35 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
And fleyng schal perische fro scheepherdis, and sauyng schal perische fro the principals of the floc.
36 Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
The vois of the crye of scheepherdis, and the yellyng of the principals of the floc, for the Lord hath wastid the lesewis of hem.
37 Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
And the feeldis of pees weren stille, for the face of wraththe of the strong veniaunce of the Lord.
38 Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
He as a lion hath forsake his tabernacle, for the lond of hem is maad in to desolacioun, of the face of wraththe of the culuer, and of the face of wraththe of the strong veniaunce of the Lord.

< Jeremiah 25 >