< Jeremiah 25 >

1 Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
This is the word that came to Jeremiah about all the people of Judah. It came in the fourth year of Jehoiakim son of Josiah, king of Judah. That was the first year of Nebuchadnezzar, king of Babylon.
2 Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
Jeremiah the prophet proclaimed this to all the people of Judah and all the inhabitants of Jerusalem.
3 Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
He said, “For twenty-three years, from the thirteenth year of Josiah son of Amon, king of Judah until this day, Yahweh's words have been coming to me and I have spoken to you again and again, but you have not listened.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Yahweh sent out all his servants the prophets to you again and again, but you have not listened or paid any attention.
5 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
These prophets said, 'Let each man turn from his wicked way and the corruption of his practices and return to the land that Yahweh gave in ancient times to your ancestors and to you, as a permanent gift.
6 Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
So do not walk after other gods to worship them or bow down to them, and do not provoke him with the work of your hands so that he does you harm.'
7 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
But you have not listened to me—this is Yahweh's declaration—so you have provoked me with the work of your hands to do harm to you.
8 Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
So Yahweh of hosts says this, 'Because you did not listen to my words,
9 Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
see, I am about to send out a command to gather all the peoples of the north—this is Yahweh's declaration—with Nebuchadnezzar my servant, king of Babylon, and bring them against this land and its inhabitants, and against all the nations around you. For I will set them apart for destruction. I will turn them into a horror, an object for hissing, and an unending desolation.
10 Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
I will put an end to the sound of joy and sound of gladness, the sound of the groom and the sound of the bride, the sound of the millstones and the light of the lamp.
11 Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
Then all of this land will become a desolation and a horror, and these nations will serve the king of Babylon for seventy years.
12 “Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
Then it will happen when seventy years have been completed, that I will punish the king of Babylon and that nation, the land of the Chaldeans—this is Yahweh's declaration—for their iniquity and make it an unending desolation.
13 Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
Then I will carry out against that land all the words that I had spoken, and everything written in this book that Jeremiah has prophesied against all the nations.
14 Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
For also many other nations and great kings will make slaves out of these nations. I will repay them for their deeds and the works of their hands.'”
15 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
For Yahweh, God of Israel, said this to me, “Take this cup of the wine of fury from my hand and make all the nations to which I am sending you drink it.
16 Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
For they will drink and then stagger about and rant madly before the sword that I am sending out among them.”
17 Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
So I took the cup from Yahweh's hand, and I made all the nations to which Yahweh had sent me drink it:
18 Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
Jerusalem, the cities of Judah and her kings and officials—to turn them into ruins and something terrifying, and into an object for hissing and cursing, as they are at this present day.
19 Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Other nations also had to drink it: Pharaoh king of Egypt and his servants; his officials and all his people;
20 Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
all people of mixed heritage and all the kings of the land of Uz; all the kings of the land of Philistia—Ashkelon, Gaza, Ekron, and the remnant of Ashdod;
21 Edomu, Moabu àti Ammoni;
Edom and Moab and the people of Ammon.
22 gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
The kings of Tyre and Sidon, the kings of the coasts on the other side of the sea,
23 Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
Dedan, Tema, and Buz with all the ones who cut the hair on the sides of their heads, they also had to drink it.
24 Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
All the kings of Arabia and all the kings of people of mixed heritage who live in the wilderness;
25 Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
all the kings of Zimri, all the kings of Elam, and all the kings of the Medes;
26 Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
all the kings of the north, the ones close by and the ones far away—everyone with his brother and all the kingdoms of the world that are on the surface of the earth, all of them had to drink the cup from Yahweh's hand. Finally, the king of Babylon will also drink from that cup.
27 “Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
Yahweh said to me, “Now you must say to them, 'Yahweh of hosts, God of Israel, says this: Drink and become drunk, then vomit, fall down, and do not rise before the sword that I am sending among you.'
28 Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
Then it will happen that if they refuse to take the cup from your hand to drink, you will say to them, 'Yahweh of hosts says this: You must certainly drink it.
29 Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
For see, I am about to bring disaster on the city that is called by my name, and should you yourselves be free from punishment? You will not be free, for I am calling a sword against all the inhabitants of the land!—this is the declaration of Yahweh of hosts.'
30 “Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
You must prophesy all these words against them, and say to them, 'Yahweh will roar from the heights and he will shout with his voice from his holy dwelling, and he will roar mightily against his fold; and he will shout, like those who tread the grapes against all those who live on the earth.
31 Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
The sound of battle will resound to the ends of the earth, for Yahweh brings charges against the nations, and he brings judgment on all flesh, and the wicked ones he will put to the sword—this is Yahweh's declaration.'
32 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
Yahweh of hosts says this, 'See, disaster is going out from nation to nation, and a great storm is beginning from the farthest parts of the earth.
33 Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
Then those killed by Yahweh will on that day extend from one end of the earth to the other; they will not be mourned, gathered, or buried. They will be like dung on the ground.
34 Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
Wail, shepherds, and shout for help! Roll about in the dust, you leaders of the flock, for the days of your slaughter have come; you will be scattered when you fall like fine pottery.
35 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
There is no refuge for the shepherds, there will be no escape for the leaders of the flock.
36 Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
Hear the cries of the shepherds and the wails of the leaders of the flock, for Yahweh is destroying their pastures.
37 Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
So the peaceful pastures will be devastated because of Yahweh's fierce anger.
38 Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
Like a young lion, he has left his den, for their land will become a horror because of the oppressor's anger, because of his angry wrath.'”

< Jeremiah 25 >