< Jeremiah 25 >
1 Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
Det Ord, som kom til Jeremias over alt Judas Folk, i Jojakims, Josias's Søns, Judas Konges fjerde Aar; det er Nebukadnezar, Kongen af Babels første Aar;
2 Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
hvilket Profeten Jeremias talte til alt Judas Folk og til alle Indbyggere i Jerusalem, sigende:
3 Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Fra Josias's, Amons Søns, Judas Konges trettende Aar og indtil denne Dag, hvilket nu er tre og tyve Aar, er Herrens Ord kommet til mig; og jeg talte til eder tidligt og ideligt, og I have ikke hørt.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Og Herren har sendt til eder alle sine Tjenere, Profeterne, tidligt og ideligt, og I have ikke hørt og ikke bøjet eders Øre til at høre;
5 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
idet de sagde: Omvender eder dog, hver fra sin onde Vej og fra sine Idrætters Ondskab, saa skulle I bo i Landet, som Herren gav eders Fædre, fra Evighed indtil Evighed;
6 Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
og vandrer ikke efter andre Guder for at tjene dem og for at tilbede dem; og I skulle ikke opirre mig med eders Hænders Gerning, at jeg ikke skal gøre eder ondt.
7 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
Men I hørte mig ikke, siger Herren, for at opirre mig med eders Hænders Gerning, til eders Ulykke.
8 Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
Derfor siger den Herre Zebaoth saaledes: Efterdi I ikke have hørt mine Ord,
9 Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
se, saa sender jeg Bud og henter alle Nordens Slægter, siger Herren, ogsaa til Nebukadnezar, Kongen af Babel, min Tjener, og jeg vil lade dem komme over dette Land og over dets Indbyggere og over alle disse Folk trindt omkring; og jeg vil ødelægge dem og gøre dem til en Forfærdelse og til en Spot og til evige Ørkener.
10 Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
Og jeg vil bringe Fryds Røst og Glædes Røst, Brudgoms Røst og Bruds Røst, Møllens Lyd og Lampens Skin til at høre op hos dem.
11 Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
Og hele dette Land skal blive til en Ørk og til Forfærdelse; og disse Folk skulle tjene Kongen af Babel halvfjerdsindstyve Aar.
12 “Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
Og det skal ske, naar halvfjerdsindstyve Aar ere omme, da vil jeg hjemsøge Kongen af Babel og dette Folk, siger Herren, for deres Misgerning, samt Kaldæernes Land, og jeg vil gøre det til evige Ødelæggelser.
13 Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
Og over dette Land vil jeg lade alle mine Ord komme, som jeg har talt imod det: Alt det, som er skrevet i denne Bog, det, som Jeremias har spaaet over alle Folkene.
14 Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
Thi ogsaa dem skulle mange Folkeslag og store Konger gøre til Trælle; og jeg vil betale dem efter deres Fortjeneste og efter deres Hænders Gerning.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
Thi saa sagde Herren, Israels Gud, til mig: Tag Bægeret med denne Vredens Vin af min Haand, og giv alle Folkene, til hvilke jeg sender dig, at drikke af den.
16 Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
Og de skulle drikke og tumle og rase over Sværdet, som jeg sender iblandt dem.
17 Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
Og jeg tog Bægeret af Herrens Haand, og jeg gav alle Folkene, til hvilke Herren sendte mig, at drikke:
18 Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
Jerusalem og Judas Stæder og dens Konger og dens Fyrster for at gøre dem til en Ørk, til Forfærdelse, til Spot og til Forbandelse, som det ses paa denne Dag;
19 Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Farao, Kongen i Ægypten, og hans Tjenere og hans Fyrster og alt hans Folk
20 Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
og den hele Hob af alle Haande Folk og alle Konger i Landet Uz og alle Konger i Filisternes Land, Askalon og Gaza og Ekron og de overblevne af Asdod,
21 Edomu, Moabu àti Ammoni;
Edom og Moab og Ammons Børn,
22 gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
og alle Konger i Tyrus og alle Konger i Sidon og Kongerne paa Kysten, som er paa hin Side Havet,
23 Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
Dedan og Thema og Bus og alle dem med rundklippet Haar
24 Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
og alle Konger i Arabien og alle Konger over den hele Hob af alle Haande Folk, dem, som bo i Ørken,
25 Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
og alle Konger i Zimri og alle Konger i Elam og alle Konger i Medien,
26 Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
og alle Konger imod Norden, baade dem, som ere nær, og dem, som ere fjern, den ene efter den anden, og alle Jordens Riger, som ere paa Jorderiges Kreds; og Kongen af Sesak skal drikke efter dem.
27 “Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
Og du skal sige til dem: Saa siger den Herre Zebaoth, Israels Gud: Drikker og bliver drukne, og spyer og falder, saa at I ikke kunne staa op igen; for Sværdet, som jeg sender iblandt eder.
28 Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
Og det skal ske, naar de vægre sig ved at tage Bægeret af din Haand til at drikke, da skal du sige til dem: Saa siger den Herre Zebaoth: Drikke skulle I!
29 Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
Thi se, i den Stad, som er kaldet efter mit Navn, begynder jeg med at lade Ulykken komme; og skulde I gaa fri? I skulle ikke gaa fri! thi jeg kalder et Sværd hid over alle Jordens Beboere, siger den Herre Zebaoth.
30 “Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
Og du skal spaa over dem og forkynde alle disse Ord og sige til dem: Herren skal lade et Brøl lyde fra det høje og hæve sin Røst fra sin hellige Bolig: Et Brøl skal han lade lyde imod sin Bolig, han skal opløfte et Frydeskrig som de, der træde Vinpersen, imod alle Jordens Beboere.
31 Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
Der kommer et Bulder lige indtil Jordens Ende, thi Herren har Trætte med Hedningerne, han holder Dom over alt Kød; de ugudelige giver han til Sværdet, siger Herren.
32 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
Saa siger den Herre Zebaoth: Se, der udgaar Ulykke fra et Folk til et andet Folk, og en vældig Storm skal rejse sig fra det yderste af Jorden.
33 Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
Og de, som ere ihjelslagne af Herren, skulle paa den Dag ligge fra den ene Ende af Jorden og indtil den anden Ende af Jorden; de skulle ej beklages og ej sankes op og ej begraves, de skulle vorde til Møg oven paa Marken.
34 Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
Hyler, I Hyrder! og raaber og vælter eder i Støv, I herlige iblandt Hjorden! thi eders Dage ere komne til at slagtes; og jeg skal sønderslaa eder, og I skulle falde som et kosteligt Kar.
35 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
Og der skal ingen Tilflugt være for Hyrderne, og de herlige iblandt Hjorden skulle ikke undkomme.
36 Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
Der lyder Skrig af Hyrderne og Hylen af de herlige iblandt Hjorden; thi Herren ødelægger deres Græsgang.
37 Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
Og de fredelige Hytter ere blevne stille, for Herrens brændende Vredes Skyld.
38 Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
Han har som den unge Løve forladt sin Hule; thi deres Land er blevet en Forfærdelse for den ødelæggende Magts Grumhed og for hans brændende Vredes Skyld.