< Jeremiah 25 >

1 Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
Babylon siangpahrang Nebuchadnezzar angraeng ah ohhaih saningto haih, Josiah capa Judah siangpahrang Jehoiakim angraenghaih saning palito haih naah, Judah kaminawk boih kawng pongah Jeremiah khaeah lok to angzoh,
2 Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
to pongah tahmaa Jeremiah mah Judah kaminawk boih hoi Jerusalem ah kaom kaminawk boih khaeah;
3 Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Judah siangpahrang Amon capa Josiah angraenghaih saning hathlai thumto nathuem hoi vaihni ni khoek to, saning pumphae thumto thung, Angraeng ih lok kai khaeah angzoh, to lok to khawnthaw ah kang thawk moe, kang thuih o boeh, toe na tahngai o ai.
4 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
Angraeng loe khawnthaw ah angthawk moe, a tamna tahmaanawk to nangcae khaeah ang patoeh; toe lok na tahngai pae o ai, thaih han ih naa doeh na patueng o ai.
5 Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
Nihcae mah, nangcae boih, vaihi na caeh o ih kasae loklam hoiah na sak o ih kasae hmuennawk hoiah amlaem oh ah loe, Angraeng mah nangmacae khae hoi nam panawk khaeah dungzan ah paek ih prae thungah om oh;
6 Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
kalah sithawnawk hnukah bang o hmah, a tok doeh sah pae o hmah, bok doeh bok o hmah; na ban hoiah sak ih hmuennawk hoiah kai palung na phui o sak hmah, to tih nahaeloe nganbawh kana kang paek o mak ai, tiah ang thuih o.
7 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
Toe ka lok na tahngai o ai, nam ro o hanah, nangmacae ban hoi sak ih hmuen hoiah palung nang phui o sak, tiah Angraeng mah thuih.
8 Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
To pongah misatuh kaminawk ih Angraeng mah, Ka lok na tahngai o ai pongah,
9 Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
khenah, aluek bang ih kaminawk boih hoi ka tamna Babylon siangpahrang Nebuchadnezzar to ka kawk moe, hae prae hoi a thungah kaom kaminawk boih, hae kami taengah kaom kaminawk to laksak boih hanah ka patoeh han; anih mah nihcae to amrosak tih, nihcae to dawnraisak tih, hanghaih hoiah dungzan ah kang hmatsak zuep han.
10 Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
Nihcae khae hoi anghoehaih lok, oephaih lok, zu la kami ih lok, sava sah kami ih lok, cang kaehhaih lok hoi hmaithawk paanghaih to ka lak pae ving han boeh.
11 Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
Hae prae boih loe pong sut ueloe, dawnraihaih hoiah om o tih; hae kaminawk mah Babylon siangpahrang ih tok to saning qui sarihto thung sah pae o tih, tiah thuih.
12 “Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
Toe saning qui sarihto koep pacoengah loe, hae kaminawk nuiah sakpazae ih hmuen pongah, Babylon siangpahrang hoi anih ih kaminawk to ka thuitaek moe, dungzan khoek to ka pongsak han, tiah Angraeng mah thuih.
13 Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
Kaimah ka thuih ih nihcae misatukhaih loknawk boih, hae cabu thungah tahmaa Jeremiah mah tarik moe, thuih ih prae kaminawk misatukhaih loknawk to hae prae thungah ka phaksak boih han.
14 Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
Babylon kaminawk loe pop parai, kalen parai kalah acaeng siangpahrangnawk ih misong ah om o tih; a sak o ih hmuen baktih, ban mah sak ih hmuen baktih toengah, nihcae nuiah ka sak pathok han, tiah thuih.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
Hae ka ban pong ih palungphuihaih misurtui boengloeng hae la ah loe, naek han kang patoeh ih prae kaminawk boih to, naesak ah.
16 Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
Nihcae salakah sumsen to ka patoeh han boeh pongah, nihcae mah naek o naah paqui o ueloe, amthu o boih tih, tiah Israel Angraeng Sithaw mah ang thuih.
17 Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
To pacoengah Angraeng ban pong ih boengloeng to ka lak moe, Angraeng mah kai khaeah patoeh ih prae kaminawk to ka naeksak boih:
18 Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
ka naeksak ih kaminawk loe Jerusalem hoi Judah vangpuinawk hoiah kamtong, vaihniah kaom hmuen baktiah, Judah siangpahrangnawk hoi ukkung angraengnawk loe palungsethaih, dawnraihaih, paciip paaahaih, tangoenghaih hoiah ohsak;
19 Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
to pacoengah Izip siangpahrang Faro hoi a tamnanawk, anih ih angraengnawk hoi anih ih kaminawk boih;
20 Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
to ah kaom congca kaminawk boih; Uz prae ih siangpahrangnawk boih; Philistin prae ih siangpahrangnawk boih, Ashkelon, Gaza, Ekron hoi Ashdod ih kanghmat kaminawk,
21 Edomu, Moabu àti Ammoni;
Edom, Moab hoi Ammon kaminawk,
22 gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
Tura hoi Sidon ih siangpahrangnawk boih; tuipui thung ih prae ukkung siangpahrangnawk boih,
23 Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
Dedan, Tema, Buz hoi kangthla koek ahmuen ah kaom kaminawk boih,
24 Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
Arabia siangpahrangnawk boih, praezaek ah kaom congca kaminawk ih siangpahrangnawk boih,
25 Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
Zimri, Elam hoi Median ih siangpahrang boih,
26 Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
Maeto hoi maeto kangthla maw, kanghnai maw tih ai ah, aluek bang ih siangpahrangnawk boih; long nuiah kaom long pum ih praenawk to athum o boih; nihcae naek o pacoengah, Sheshak siangpahrang doeh nae toeng tih.
27 “Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
Nihcae khaeah, misatuh kaminawk ih Angraeng Israel Sithaw mah, Nae oh, paqui oh loe, palok oh, angthawk let han ai ah, nangcae khaeah ka patoeh han ih sumsen pongah, amtim oh, tiah thui paeh.
28 Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
Toe naek hanah na ban pong ih boengloeng lak han koeh o ai nahaeloe, nihcae khaeah, Na naek o han oh! tiah misatuh kaminawk ih Angraeng mah thuih, tiah thui pae ah.
29 Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
Khenah, Ka hmin hoi kawk ih vangpui nuiah amrohaih ka phaksak han, thuitaek ai ah na om o tih maw? Thuitaek ai ah na om o mak ai; long nuiah kaom kaminawk boih nuiah sumsen to ka patoeh han boeh, tiah misatuh kaminawk ih Angraeng mah thuih.
30 “Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
Vaihi nihcae misa haih loknawk boih to thui paeh; nihcae khaeah, Angraeng loe hmuensang hoiah hang ueloe, a ohhaih hmuenciim hoiah lok to tacawt tih; a ohhaih ahmuen to hang thui tih, kaeh ih misurtui baktiah, long nui ih kaminawk to hang thui tih.
31 Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
Long boeng khoek to a lok to amsong tih; Angraeng mah prae kaminawk to lokcaek boih tih, kaminawk boih lokcaek tih; kasae kaminawk to sumsen hoi hum hanah paek tih, tiah Angraeng mah thuih.
32 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
Misatuh kaminawk ih Angraeng mah, Khenah, prae maeto hoi maeto ah amrohaih angcen tih; long boenghaih ahmuen hoiah kamhae takhi to song tih boeh, tiah thuih.
33 Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
To naah Angraeng mah hum ih kaminawk loe, long boenghaih maeto hoi kalah maeto bang khoek to om tih; nihcae to qah o haih mak ai, la o mak ai, aphum doeh aphum o mak ai; maiphu baktiah ni long ah om o tih.
34 Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
Nangcae tuutoep kaminawk, qah oh loe, hang oh; kalen koek tuu zaehoikungnawk, long ah maiphu angnok oh loe asawt oh; nangcae humhaih atue hoi ampraek phanghaih atue to phak boeh; nangcae loe atho kana laom baktiah na krah o tih.
35 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
Tuutoep kaminawk loe cawnhaih ahmuen tawn o mak ai, kalen koek tuutoep kaminawk doeh loih o mak ai.
36 Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
Angraeng mah nihcae prathaih ahmuen to phraek pae pongah, tuutoep kaminawk hoi kalen koek tuu zaehoikungnawk ih hanghaih lok to thaih o tih.
37 Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
Kanung parai Angraeng palungphuihaih pongah, kamongah ohhaih ahmuen to phraek o boeh.
38 Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
Kaipui mah a ohhaih ahmuen to caehtaak baktih toengah, anih mah a ohhaih ahmuen to caehtaak boeh; kana parai ah pacaekthlaek ih kami hoi kanung parai anih palungphuihaih pongah prae loe pong sut boeh.

< Jeremiah 25 >