< Jeremiah 24 >
1 Lẹ́yìn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn oníṣọ̀nà àti oníṣẹ́ ọwọ́ ti Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli tán. Olúwa fi agbọ̀n èso ọ̀pọ̀tọ́ méjì hàn mí tí a gbé sí iwájú pẹpẹ Olúwa.
Le Seigneur me montra deux corbeilles de figues posées devant la façade du temple du Seigneur, après que Nabuchodonosor eut enlevé Jéchonias, fils de Joakim, roi de Juda, et les princes, et les artisans, et les prisonniers, et les riches de Jérusalem, et qu'il les eut emmenés à Babylone.
2 Agbọ̀n kan ni èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó dára bí èyí tí ó tètè pọ́n; èkejì sì ní èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó burú rékọjá tí kò sì le è ṣe é jẹ.
L'une de ces corbeilles contenait de très bonnes figues, comme celles de la primeur; et l'autre de très mauvaises figues qu'on ne pouvait manger, tant elles étaient mauvaises.
3 Nígbà náà ni Olúwa bi mí pé, “Kí ni ìwọ rí Jeremiah?” Mo dáhùn pe, “Èso ọ̀pọ̀tọ́.” Mo dáhùn. “Èyí tí ó dáradára púpọ̀, ṣùgbọ́n èyí tí ó burú burú rékọjá tí kò sì ṣe é jẹ.”
Et le Seigneur me dit: Jérémie, que vois-tu? Et je répondis: Des figues; des figues bonnes, très bonnes, et d'autres mauvaises, très mauvaises, qu'on ne peut manger, tant elles sont mauvaises.
4 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Et la parole du Seigneur vint à moi, disant:
5 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára yìí ni Èmi yóò ka àwọn tí wọ́n lọ sí ilẹ̀ àjèjì láti Juda sí tí èmi rán jáde kúrò ní ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kaldea.
Voici ce que dit le Seigneur Dieu d'Israël: Comme les bonnes figues, je reconnaîtrai les Juifs emmenés en captivité, que j'ai expulsés de ce lieu et envoyés en Chaldée, je les traiterai bien.
6 Ojú mi yóò máa ṣọ́ wọn lọ fún rere, Èmi yóò gbé wọn ró, n kò ní já wọn lulẹ̀. Èmi yóò gbìn wọ́n, n kò sì ní fà wọ́n tu.
Et j'attacherai sur eux mes regards pour leur bien, et je les rétablirai pour leur bien dans cette terre, et je les réédifierai pour ne plus les abattre, et je les replanterai pour ne plus les arracher.
7 Èmi yóò fún wọn ní ọkàn láti mọ̀ mí pé, “Èmi ni Olúwa.” Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi; Èmi ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn; nítorí pé wọn yóò padà sọ́dọ̀ mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Et je leur donnerai un cœur pour qu'ils me connaissent, pour qu'ils sachent que je suis le Seigneur; et ils seront mon peuple, et je serai leur Dieu, parce qu'ils se seront convertis à moi de toute leur âme.
8 “‘Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí kò dára, tí ó burú tí kò ṣe é jẹ,’ ni Olúwa wí, ‘bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe pẹ̀lú Sedekiah ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn tí ó yẹ ní Jerusalẹmu, yálà wọ́n wà lórí ilẹ̀ yìí tàbí wọ́n ń gbé Ejibiti.
Et comme les mauvaises figues qu'on ne peut manger, tant elles sont mauvaises, dit le Seigneur, je livrerai Sédécias, roi de Juda, et ses grands, et le reste de Jérusalem qui est demeuré en cette terre, et ceux qui habitent l'Égypte.
9 Èmi yóò sọ wọ́n di ìwọ̀sí àti ẹni ibi nínú gbogbo ìjọba ayé, láti di ẹni ìfibú àti ẹni òwe, ẹni ẹ̀sín, àti ẹni ẹ̀gàn ní ibi gbogbo tí Èmi ó lé wọn sí.
Et je les livrerai à la dispersion dans tous les royaumes de la terre, et dans les lieux où je les aurai bannis, et ils seront un sujet d'outrages et de railleries, de haine et de malédiction;
10 Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí wọn, títí tí gbogbo wọn yóò parun lórí ilẹ̀ tí a fún wọn àti fún àwọn baba wọn.’”
Et je leur enverrai la famine, et la peste, et le glaive, jusqu'à ce qu'il n'y en n'ait plus sur cette terre que je leur ai donnée.