< Jeremiah 24 >

1 Lẹ́yìn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn oníṣọ̀nà àti oníṣẹ́ ọwọ́ ti Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli tán. Olúwa fi agbọ̀n èso ọ̀pọ̀tọ́ méjì hàn mí tí a gbé sí iwájú pẹpẹ Olúwa.
The Lord caused me to see, and, behold, there were two baskets of figs placed before the temple of the Lord, after Nebuchadrezzar the king of Babylon had carried away into exile Yechonyahu the son of Yehoyakim the king of Judah, and the princes of Judah, with the carpenters and the locksmiths, from Jerusalem, and had brought them to Babylon.
2 Agbọ̀n kan ni èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó dára bí èyí tí ó tètè pọ́n; èkejì sì ní èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó burú rékọjá tí kò sì le è ṣe é jẹ.
The one basket [had] very good figs, like the figs that are first ripe: and the other basket [had] very bad figs, which could not be eaten, from being so bad.
3 Nígbà náà ni Olúwa bi mí pé, “Kí ni ìwọ rí Jeremiah?” Mo dáhùn pe, “Èso ọ̀pọ̀tọ́.” Mo dáhùn. “Èyí tí ó dáradára púpọ̀, ṣùgbọ́n èyí tí ó burú burú rékọjá tí kò sì ṣe é jẹ.”
Then said the Lord unto me, What seest thou, Jeremiah? And I said, Figs: the good figs, are very good; and the bad ones, are very bad, which cannot be eaten, from being so bad.
4 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
And the word of the Lord came unto me, saying,
5 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára yìí ni Èmi yóò ka àwọn tí wọ́n lọ sí ilẹ̀ àjèjì láti Juda sí tí èmi rán jáde kúrò ní ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kaldea.
Thus hath said the Lord, the God of Israel, Like these good figs, so will I acknowledge the exiles of Judah, whom I have sent away from this place into the land of the Chaldeans, for good.
6 Ojú mi yóò máa ṣọ́ wọn lọ fún rere, Èmi yóò gbé wọn ró, n kò ní já wọn lulẹ̀. Èmi yóò gbìn wọ́n, n kò sì ní fà wọ́n tu.
And I will set my eye upon them for good, and I will cause them to return again to this land; and I will build them up, and not pull them down; and I will plant them, and not pluck them up.
7 Èmi yóò fún wọn ní ọkàn láti mọ̀ mí pé, “Èmi ni Olúwa.” Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi; Èmi ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn; nítorí pé wọn yóò padà sọ́dọ̀ mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
And I will give them a heart to know me, that I am the Lord: and they shall be unto me for a people, and I will be unto them for God! for they will return unto me with all their heart.
8 “‘Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí kò dára, tí ó burú tí kò ṣe é jẹ,’ ni Olúwa wí, ‘bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe pẹ̀lú Sedekiah ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn tí ó yẹ ní Jerusalẹmu, yálà wọ́n wà lórí ilẹ̀ yìí tàbí wọ́n ń gbé Ejibiti.
And like the bad figs, which cannot be eaten, from being so bad, surely thus hath said the Lord, So I will render Zedekiah the king of Judah, and his princes, and the residue of Jerusalem, that remain in this land, and those that dwell in the land of Egypt;
9 Èmi yóò sọ wọ́n di ìwọ̀sí àti ẹni ibi nínú gbogbo ìjọba ayé, láti di ẹni ìfibú àti ẹni òwe, ẹni ẹ̀sín, àti ẹni ẹ̀gàn ní ibi gbogbo tí Èmi ó lé wọn sí.
And I will make them a horror because of [their] mishaps unto all the kingdoms of the earth, a disgrace and a proverb, a byword and a curse, in all the places whither I will drive them.
10 Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí wọn, títí tí gbogbo wọn yóò parun lórí ilẹ̀ tí a fún wọn àti fún àwọn baba wọn.’”
And I will send out against them the sword, the famine, and the pestilence, till they be destroyed from off the land that I had given unto them and to their fathers.

< Jeremiah 24 >