< Jeremiah 23 >
1 “Ègbé ni fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń tú agbo ẹran mi ká tí ó sì ń pa wọ́n run!” ni Olúwa wí.
Ve över de herdar som fördärva och förskingra fåren i min hjord! säger HERREN.
2 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ ní ti àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń darí àwọn ènìyàn mi: “Nítorí tí ẹ̀yin tú agbo ẹran mi ká, tí ẹ lé wọn dànù tí ẹ̀yin kò sì bẹ̀ wọ́n wò. Èmi yóò jẹ yín ní yà nítorí nǹkan búburú tí ẹ ti ṣe,” ni Olúwa wí.
Därför säger HERREN, Israels Gud, så om de herdar som föra mitt folk i bet: Det är I som haven förskingrat mina får och drivit bort dem och underlåtit att söka deras bästa. Men se, nu skall jag hemsöka eder för edert onda väsendes skull, säger HERREN.
3 “Èmi Olúwa tìkára mi yóò kó ìyókù agbo ẹran mi jọ láti inú gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo ti lé wọn, Èmi yóò mú wọn padà sínú pápá oko wọn, níbẹ̀ ni wọn ó ti bí sí i, tí wọn ó sì pọ̀ sí i.
Och jag skall själv församla kvarlevan av mina får ur alla de länder till vilka jag har drivit dem bort, och skall föra dem tillbaka till deras betesmarker, och de skola bliva fruktsamma och föröka sig.
4 Èmi ó wá olùṣọ́-àgùntàn fún wọn, tí yóò darí wọn, wọn kì yóò bẹ̀rù tàbí dààmú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan kì yóò sọnù,” ni Olúwa wí.
Och jag skall låta herdar uppstå åt dem, vilka skola föra dem i bet; och de skola icke mer behöva frukta eller förskräckas och skola icke mer drabbas av hemsökelse, säger HERREN.
5 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò gbé ẹ̀ka òdodo dìde fún Dafidi, ọba tí yóò lo ìjọba pẹ̀lú ọgbọ́n tí yóò sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ lórí ilẹ̀ náà.
Se, dagar skola komma, säger HERREN, då jag skall låta en rättfärdig telning uppstå åt David. Han skall regera såsom konung och hava framgång, och han skall skaffa rätt och rättfärdighet på jorden.
6 Ní ọjọ́ rẹ̀ ni a ó gba Juda là, Israẹli yóò sì máa gbé ní aláìléwu. Èyí ni orúkọ tí a ó fi máa pè é: Olúwa Òdodo wa.
I hans dagar skall Juda varda frälst och Israel bo i trygghet; och detta skall vara det namn han skall få: HERREN vår rättfärdighet.
7 Nítorí náà, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí ènìyàn kì yóò tún wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.’
Se, därför skola dagar komma, säger HERREN, då man icke mer skall säga: "Så sant HERREN lever, han som har fört Israels barn upp ur Egyptens land",
8 Ṣùgbọ́n wọn yóò máa wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa ń bẹ tí ó mú irú-ọmọ ilé Israẹli wá láti ilẹ̀ àríwá àti láti àwọn ilẹ̀ ibi tí mo tí lé wọn lọ,’ wọn ó sì gbé inú ilẹ̀ wọn.”
utan: "Så sant HERREN lever, han som har fört upp Israels hus släkt och hämtat dem ut ur nordlandet och ur alla andra länder till vilka jag hade drivit dem bort." Och så skola de få bo i sitt land.
9 Nípa ti àwọn wòlíì èké. Ọkàn mi ti bàjẹ́ nínú mi, gbogbo egungun mi ni ó wárìrì. Èmi dàbí ọ̀mùtí ènìyàn, bí ọkùnrin tí ọtí wáìnì ń pa; nítorí Olúwa àti àwọn ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.
Om profeterna. Mitt hjärta vill brista i mitt bröst, alla ben i min kropp äro vanmäktiga. Jag är såsom en drucken man, en man överväldigad av vin, inför HERREN och inför hans heliga ord.
10 Ilẹ̀ náà kún fún panṣágà ènìyàn; nítorí ègún, ilẹ̀ náà gbẹ, àwọn koríko orí aṣálẹ̀ ilẹ̀ náà rọ. Àwọn wòlíì tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọ́n sì ń lo agbára wọn lọ́nà àìtọ́.
Ty landet är fullt av äktenskapsbrytare, under förbannelse ligger landet sörjande, och betesmarkerna i öknen äro förtorkade; man hastar till vad ont är och har sin styrka i orättrådighet.
11 “Wòlíì àti àlùfáà kò gbé ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run; kódà nínú tẹmpili mi ni mo rí ìwà búburú wọn,” ni Olúwa wí.
Ty både profeter och präster äro gudlösa; ända inne i mitt hus har jag mött deras ondska, säger HERREN.
12 “Nítorí náà, ọ̀nà wọn yóò di yíyọ́, a ó lé wọn jáde sínú òkùnkùn; níbẹ̀ ni wọn yóò ṣubú. Èmi yóò mú ìdààmú wá sórí wọn, ní ọdún tí a jẹ wọ́n ní ìyà,” ni Olúwa wí.
Därför skall deras väg bliva för dem såsom en slipprig stig i mörkret, de skola på den stöta emot och falla. Ty jag vill låta olycka drabba dem, när deras hemsökelses är kommer, säger HERREN.
13 “Láàrín àwọn wòlíì Samaria, Èmi rí ohun tí ń lé ni sá. Wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ Baali wọ́n sì mú Israẹli ènìyàn mi ṣìnà.
Väl såg jag ock hos Samarias profeter vad förvänt var; de profeterade i Baals namn och förde mitt folk Israel vilse.
14 Àti láàrín àwọn wòlíì Jerusalẹmu, èmi ti rí ohun búburú. Wọ́n ṣe panṣágà, wọ́n sì ń ṣèké. Wọ́n fún àwọn olùṣe búburú ní agbára, tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí ó yípadà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀. Gbogbo wọn dàbí Sodomu níwájú mi, àti àwọn ènìyàn olùgbé rẹ̀ bí Gomorra.”
Men hos Jerusalems profeter har jag sett de gruvligaste ting: de leva i äktenskapsbrott och fara med lögn; de styrka modet hos dem som göra ont, så att ingen vill omvända sig från sin ondska. De äro alla för mig såsom Sodom, och stadens invånare såsom Gomorras.
15 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí ní ti àwọn wòlíì: “Èmi yóò mú wọn jẹ oúnjẹ kíkorò, wọn yóò mu omi májèlé nítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jerusalẹmu ni àìwà-bí-Ọlọ́run ti tàn ká gbogbo ilẹ̀.”
Därför säger HERREN Sebaot så om profeterna: Se, jag skall giva dem malört att äta och gift att dricka, ty från profeterna i Jerusalem har gudlöshet gått ut över hela landet.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ má ṣe fi etí sí àsọtẹ́lẹ̀ tí àwọn wòlíì èké ń sọ fún un yín. Wọ́n ń kún inú ọkàn yín pẹ̀lú ìrètí asán. Wọ́n ń sọ ìran láti ọkàn ara wọn, kì í ṣe láti ẹnu Olúwa.
Så säger HERREN Sebaot: Hören icke på de profeters ord, som profetera för eder, ty de bedraga eder; sina egna hjärtans syner tala de, icke vad som kommer från HERRENS mun.
17 Wọ́n ń sọ fún àwọn tí ó ń gàn mí pé, ‘Olúwa ti wí pé, ẹ̀yin ó ní àlàáfíà.’ Wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn tí ó rìn nípa agídí ọkàn rẹ̀ pé, ‘Kò sí ìpalára kan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí yín.’
De säga alltjämt till dem som förakta mig: "HERREN har så talat: Det skall gå eder väl." Och till var och en som vandrar i sitt hjärtas hårdhet säga de: "Ingen olycka skall komna över eder."
18 Ṣùgbọ́n èwo nínú wọn ni ó dúró nínú ìgbìmọ̀ Olúwa láti rí i tàbí gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀? Ta ni ó gbọ́ tí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ náà?
Vilken av dem har då fått tillträde till HERRENS råd, så att han kan förnimma och höra hans ord? Och vilken har aktat på hans ord och lyssnat därtill?
19 Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jáde pẹ̀lú ìbínú à fẹ́ yíká ìjì yóò fẹ́ sí orí àwọn olùṣe búburú.
Se, en stormvind från HERREN är här, hans förtörnelse bryter fram, en virvlande storm! Över de ogudaktigas huvuden virvlar den ned.
20 Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀ títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ, ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.
Och HERRENS vrede skall icke upphöra, förrän han har utfört och fullbordat sitt hjärtas tankar; i kommande dagar skolen I förvisso förnimma det.
21 Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyí síbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn. Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀, síbẹ̀ wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Jag sände icke dessa profeter, utan själva lupo de åstad; jag talade icke till dem, utan själva profeterade de.
22 Ṣùgbọ́n ì bà ṣe pé wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi, wọn ìbá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi. Wọn ìbá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi fun àwọn ènìyàn wọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nà àti ìṣe búburú wọn.
Om de verkligen hade tillträde till mitt råd, så borde de förkunna mina ord för mitt folk och förmå dem att vända om från sin onda väg och sitt onda väsende.
23 “Ǹjẹ́ Ọlọ́run tòsí nìkan ni Èmi bí?” ni Olúwa wí, “kì í sì í ṣe Ọlọ́run ọ̀nà jíjìn.
Ar jag väl en Gud allenast på nära håll, säger HERREN, och icke en Gud också i fjärran?
24 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè sá pamọ́ sí ibi kọ́lọ́fín kan, kí èmi má ba a rí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi kò ha a kún ọ̀run àti ayé bí?” ni Olúwa wí.
Eller skulle någon kunna gömma sig på ett så lönnligt ställe att jag icke skulle se honom? säger HERREN. Är jag icke den som uppfyller himmel och jord? säger HERREN.
25 “Mo ti gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn wòlíì èké tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ mi ń sọ. Wọ́n sọ wí pé, ‘Mo lá àlá! Mo lá àlá!’
Jag har hört vad profeterna säga, de som profetera lögn i mitt namn; de säga: "Jag har haft en dröm, jag har haft en dröm."
26 Títí di ìgbà wo ni èyí yóò fi máa tẹ̀síwájú ni ọkàn àwọn wòlíì èké wọ̀nyí tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìtànjẹ ọkàn wọn?
Huru länge skall detta vara? Hava de något i sinnet, dessa profeter som profetera lögn, och som äro profeter genom sina egna hjärtans svek,
27 Wọ́n rò wí pé àlá tí wọ́n ń sọ fún ara wọn yóò mú kí àwọn ènìyàn mi gbàgbé orúkọ mi, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe gbàgbé orúkọ mi nípa sí sin òrìṣà Baali.
dessa som tänka att de genom sina drömmar; dem som de förtälja för varandra, skola komma mitt folk att förgäta mitt namn, likasom deras fäder glömde mitt namn för Baal?
28 Jẹ́ kí wòlíì tí ó bá lá àlá sọ àlá rẹ̀, ṣùgbọ́n jẹ́ kí ẹni tí ó ní ọ̀rọ̀ mí sọ ọ́ ní òtítọ́. Kí ni koríko gbígbẹ ní í ṣe nínú ọkà?” ni Olúwa wí.
Den profet som har haft en dröm, han må förtälja sin dröm; men den som bar undfått mitt ord, han må tala mitt ord i sanning. Vad har halmen att skaffa med säden? säger HERREN.
29 “Ọ̀rọ̀ mi kò ha a dàbí iná?” ni Olúwa wí, “àti bí òòlù irin tí ń fọ́ àpáta túútúú?
Är icke mitt ord såsom en eld, säger HERREN, och likt en hammare som krossar sönder klippor?
30 “Nítorí náà, èmi lòdì sí àwọn wòlíì ni,” Olúwa wí, “Tí ń jí ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí ó ti ọ̀dọ̀ mi wá lò lọ́dọ̀ ara wọn.
Se, därför skall jag komma över profeterna, säger HERREN, dessa som stjäla mina ord, den ene från den andre;
31 Bẹ́ẹ̀,” ni Olúwa wí, “Èmi lòdì sí àwọn wòlíì tí wọ́n lo ahọ́n wọn káàkiri, síbẹ̀ tí wọ́n ń sọ wí pé, ‘Olúwa wí.’
ja, jag skall komma över profeterna, säger HERREN, dessa som frambära sin egen tungas ord, men säga: "Så säger HERREN."
32 Nítòótọ́, mo lòdì sí àwọn tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa àlá èké,” ni Olúwa wí. “Wọ́n ń sọ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà nípa onírúurú èké wọn, síbẹ̀ èmi kò rán wọn tàbí yàn wọ́n. Wọn kò sì ran àwọn ènìyàn wọ̀nyí lọ́wọ́ bí ó ti wù kí ó kéré mọ,” ni Olúwa wí.
Ja, jag skall komma över dem som profetera lögndrömmar, säger HERREN, och som, när de förtälja dem, föra mitt folk vilse med sina lögner och sin stortalighet, fastän jag icke har sänt dem eller givit dem något uppdrag, och fastän de alls icke kunna hjälpa detta folk, säger HERREN.
33 “Nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, tàbí wòlíì tàbí àlùfáà bá bi ọ́ léèrè wí pé, ‘Kí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa?’ Sọ fún wọn wí pé, ‘Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ wo? Èmi yóò pa yín tì ni Olúwa wí.’
Om nu detta folk eller en profet eller en präst gör dig denna fråga: "Vad förkunnar HERRENS tunga?", så skall du säga till dem vad som är den verkliga "tungan", och att jag därför skall kasta eder bort, säger HERREN.
34 Bí wòlíì tàbí àlùfáà tàbí ẹnikẹ́ni bá sì gbà wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’ Èmi yóò fi ìyà jẹ ọkùnrin náà àti gbogbo agbo ilé rẹ̀.
Och den profet eller den präst eller den av folket, som säger "HERRENS tunga", den mannen och hans hus skall jag hemsöka.
35 Èyí ni ohun tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín ń sọ fún ọ̀rẹ́ àti ará ilé rẹ̀: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa sọ?’
Nej, så skolen I fråga varandra och säga eder emellan: "Vad har HERREN svarat?", eller: "Vad har HERREN talat?"
36 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dárúkọ ọ̀rọ̀ ‘ìjìnlẹ̀ Olúwa’ mọ́, nítorí pé ọ̀rọ̀ oníkálùkù ènìyàn di ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ rẹ̀. Nítorí náà, ẹ̀yin ń yí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run alààyè, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run wa padà.
Men Om HERRENS "tunga" mån I icke mer orda; ty en tunga skall då vars och ens eget ord bliva för honom, eftersom I förvänden den levande Gudens, HERRENS Sebaots, vår Guds, ord.
37 Èyí ni ohun tí ẹ̀yin ń sọ fún wòlíì: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa sí ọ́?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa bá ọ sọ?’
Så skall du säga till profeten: "Vad har HERREN svarat dig?", eller: vad har HERREN talat?"
38 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ń sọ wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ èyí ni ohun tí Olúwa sọ, Ẹ̀yin ń lo ọ̀rọ̀ yìí, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo sọ fún un yín láti má ṣe lò ó mọ́, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’
Men om I sägen "HERRENS tunga", då säger HERREN så: "Eftersom I sägen detta ord 'HERRENS tunga', fastän jag har sänt bud till eder och låtit säga: I skolen icke säga 'HERRENS tunga',
39 Nítorí náà, Èmi yóò gbàgbé yín, bẹ́ẹ̀ ni n ó lé e yín kúrò níwájú mi pẹ̀lú àwọn ìlú tí mo fi fún un yín àti àwọn baba yín.
därför skall jag nu alldeles förgäta eder och kasta eder bort ifrån mitt ansikte, med den stad som jag har givit åt eder och edra fäder.
40 Èmi yóò sì mú ìtìjú ayérayé wá sí orí yín, ìtìjú tí kò ní ní ìgbàgbé.”
Och jag skall låta en evig smälek komma över eder, och en evig blygd, som icke skall varda förgäten."