< Jeremiah 23 >

1 “Ègbé ni fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń tú agbo ẹran mi ká tí ó sì ń pa wọ́n run!” ni Olúwa wí.
Malheur aux pasteurs qui perdent et dispersent les brebis de mon pâturage, — oracle de Yahweh!
2 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ ní ti àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń darí àwọn ènìyàn mi: “Nítorí tí ẹ̀yin tú agbo ẹran mi ká, tí ẹ lé wọn dànù tí ẹ̀yin kò sì bẹ̀ wọ́n wò. Èmi yóò jẹ yín ní yà nítorí nǹkan búburú tí ẹ ti ṣe,” ni Olúwa wí.
C’est pourquoi ainsi parle Yahweh, Dieu d’Israël, touchant les pasteurs qui paissent mon peuple: Vous avez dispersé mes brebis, vous les avez chassées, vous n’en avez pas pris soin; voici que je vais prendre soin, contre vous, de la méchanceté de vos actions, — oracle de Yahweh.
3 “Èmi Olúwa tìkára mi yóò kó ìyókù agbo ẹran mi jọ láti inú gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo ti lé wọn, Èmi yóò mú wọn padà sínú pápá oko wọn, níbẹ̀ ni wọn ó ti bí sí i, tí wọn ó sì pọ̀ sí i.
Et moi je rassemblerai le reste de mes brebis, de tous les pays où je les aurai chassées, et je les ramènerai dans leur pâturage; elles croîtront et se multiplieront.
4 Èmi ó wá olùṣọ́-àgùntàn fún wọn, tí yóò darí wọn, wọn kì yóò bẹ̀rù tàbí dààmú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan kì yóò sọnù,” ni Olúwa wí.
Et je susciterai sur elles des pasteurs qui les paîtront; elles n’auront plus ni crainte ni terreur, et il n’en manquera plus aucune, — oracle de Yahweh!
5 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò gbé ẹ̀ka òdodo dìde fún Dafidi, ọba tí yóò lo ìjọba pẹ̀lú ọgbọ́n tí yóò sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ lórí ilẹ̀ náà.
Voici que des jours viennent, — oracle de Yahweh, où je susciterai à David un germe juste; il régnera en roi et il sera sage, et il fera droit et justice dans le pays.
6 Ní ọjọ́ rẹ̀ ni a ó gba Juda là, Israẹli yóò sì máa gbé ní aláìléwu. Èyí ni orúkọ tí a ó fi máa pè é: Olúwa Òdodo wa.
Dans ses jours, Juda sera sauvé, Israël habitera en assurance, et voici le nom dont on l’appellera: Yahweh-notre-justice.
7 Nítorí náà, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí ènìyàn kì yóò tún wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.’
C’est pourquoi voici que des jours viennent, — oracle de Yahweh, où l’on ne dira plus: « Yahweh est vivant, lui qui a fait monter les enfants d’Israël du pays d’Égypte, » —
8 Ṣùgbọ́n wọn yóò máa wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa ń bẹ tí ó mú irú-ọmọ ilé Israẹli wá láti ilẹ̀ àríwá àti láti àwọn ilẹ̀ ibi tí mo tí lé wọn lọ,’ wọn ó sì gbé inú ilẹ̀ wọn.”
mais « Yahweh est vivant, lui qui a fait monter et fait revenir la race de la maison d’Israël du pays du septentrion et de tous les pays où je les avais chassés; » et ils habiteront sur leur sol.
9 Nípa ti àwọn wòlíì èké. Ọkàn mi ti bàjẹ́ nínú mi, gbogbo egungun mi ni ó wárìrì. Èmi dàbí ọ̀mùtí ènìyàn, bí ọkùnrin tí ọtí wáìnì ń pa; nítorí Olúwa àti àwọn ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.
Aux prophètes. Mon cœur est brisé au-dedans de moi, tous mes os tremblent; je suis comme un homme ivre, comme un homme pris de vin, en présence de Yahweh et en présence de sa parole sainte,
10 Ilẹ̀ náà kún fún panṣágà ènìyàn; nítorí ègún, ilẹ̀ náà gbẹ, àwọn koríko orí aṣálẹ̀ ilẹ̀ náà rọ. Àwọn wòlíì tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọ́n sì ń lo agbára wọn lọ́nà àìtọ́.
Car le pays est rempli d’adultères; car, à cause de la malédiction, le pays est en deuil; les pâturages du désert sont desséchés. L’objet de leur course est le mal; leur force est l’injustice,
11 “Wòlíì àti àlùfáà kò gbé ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run; kódà nínú tẹmpili mi ni mo rí ìwà búburú wọn,” ni Olúwa wí.
Prophètes et prêtres eux-mêmes sont des profanes, et dans ma maison même j’ai trouvé leur méchanceté, — oracle de Yahweh.
12 “Nítorí náà, ọ̀nà wọn yóò di yíyọ́, a ó lé wọn jáde sínú òkùnkùn; níbẹ̀ ni wọn yóò ṣubú. Èmi yóò mú ìdààmú wá sórí wọn, ní ọdún tí a jẹ wọ́n ní ìyà,” ni Olúwa wí.
Aussi leur chemin sera pour eux comme des lieux glissants dans les ténèbres; ils seront poussés, ils y tomberont; car j’amènerai sur eux le malheur l’année où je les visiterai, — oracle de Yahweh.
13 “Láàrín àwọn wòlíì Samaria, Èmi rí ohun tí ń lé ni sá. Wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ Baali wọ́n sì mú Israẹli ènìyàn mi ṣìnà.
Dans les prophètes de Samarie, j’ai vu de la sottise: ils prophétisaient par Baal, et ils égaraient mon peuple d’Israël;
14 Àti láàrín àwọn wòlíì Jerusalẹmu, èmi ti rí ohun búburú. Wọ́n ṣe panṣágà, wọ́n sì ń ṣèké. Wọ́n fún àwọn olùṣe búburú ní agbára, tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí ó yípadà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀. Gbogbo wọn dàbí Sodomu níwájú mi, àti àwọn ènìyàn olùgbé rẹ̀ bí Gomorra.”
et dans les prophètes de Jérusalem, j’ai vu l’horreur: ils commettent l’adultère et marchent dans le mensonge; ils affermissent les mains des méchants, afin qu’aucun d’eux ne revienne de sa méchanceté. Ils sont tous pour moi comme Sodome, et les habitants de Jérusalem comme Gomorrhe.
15 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí ní ti àwọn wòlíì: “Èmi yóò mú wọn jẹ oúnjẹ kíkorò, wọn yóò mu omi májèlé nítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jerusalẹmu ni àìwà-bí-Ọlọ́run ti tàn ká gbogbo ilẹ̀.”
C’est pourquoi ainsi parle Yahweh des armées touchant les prophètes: Je vais leur faire manger de l’absinthe et leur faire boire des eaux empoisonnées! car c’est des prophètes de Jérusalem que la profanation est venue dans tout le pays.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ má ṣe fi etí sí àsọtẹ́lẹ̀ tí àwọn wòlíì èké ń sọ fún un yín. Wọ́n ń kún inú ọkàn yín pẹ̀lú ìrètí asán. Wọ́n ń sọ ìran láti ọkàn ara wọn, kì í ṣe láti ẹnu Olúwa.
Ainsi parle Yahweh des armées: N’écoutez pas les paroles des prophètes qui vous prophétisent. Ils vous entraînent à la vanité, ils disent les visions de leur propre cœur, et non ce qui sort de la bouche de Yahweh.
17 Wọ́n ń sọ fún àwọn tí ó ń gàn mí pé, ‘Olúwa ti wí pé, ẹ̀yin ó ní àlàáfíà.’ Wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn tí ó rìn nípa agídí ọkàn rẹ̀ pé, ‘Kò sí ìpalára kan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí yín.’
Ils disent à ceux qui me méprisent: « Yahweh a dit: Vous aurez la paix; » et à tous ceux qui marchent dans la perversité de leur cœur ils disent: « Il ne vous arrivera aucun mal. »
18 Ṣùgbọ́n èwo nínú wọn ni ó dúró nínú ìgbìmọ̀ Olúwa láti rí i tàbí gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀? Ta ni ó gbọ́ tí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ náà?
Mais qui a assisté au conseil de Yahweh pour voir et entendre sa parole? Qui a été attentif à sa parole et l’a entendue?
19 Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jáde pẹ̀lú ìbínú à fẹ́ yíká ìjì yóò fẹ́ sí orí àwọn olùṣe búburú.
Voici que la tempête de Yahweh, la fureur, va éclater; l’orage tourbillonne, il fond sur la tête des impies.
20 Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀ títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ, ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.
La colère de Yahweh ne retournera pas en arrière qu’elle n’ait agi et réalisé les desseins de son cœur; à la fin des temps vous en aurez la pleine intelligence.
21 Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyí síbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn. Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀, síbẹ̀ wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Je n’ai pas envoyé ces prophètes, et ils courent! Je ne leur ai point parlé, et ils prophétisent!
22 Ṣùgbọ́n ì bà ṣe pé wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi, wọn ìbá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi. Wọn ìbá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi fun àwọn ènìyàn wọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nà àti ìṣe búburú wọn.
S’ils avaient assisté à mon conseil, ils auraient fait entendre mes paroles à mon peuple; ils les auraient ramenés de leur voie mauvaise, de la méchanceté de leurs actions.
23 “Ǹjẹ́ Ọlọ́run tòsí nìkan ni Èmi bí?” ni Olúwa wí, “kì í sì í ṣe Ọlọ́run ọ̀nà jíjìn.
Ne suis-je un Dieu que de près, — oracle de Yahweh, et ne suis-je pas aussi un Dieu de loin?
24 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè sá pamọ́ sí ibi kọ́lọ́fín kan, kí èmi má ba a rí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi kò ha a kún ọ̀run àti ayé bí?” ni Olúwa wí.
Un homme peut-il se cacher dans des cachettes sans que je le voie — oracle de Yahweh? Est-ce que le ciel et la terre je ne les remplis pas, moi — oracle de Yahweh?
25 “Mo ti gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn wòlíì èké tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ mi ń sọ. Wọ́n sọ wí pé, ‘Mo lá àlá! Mo lá àlá!’
J’ai entendu ce que disent ces prophètes qui prophétisent en mon nom des mensonges, en disant: « J’ai eu un songe; j’ai eu un songe! »
26 Títí di ìgbà wo ni èyí yóò fi máa tẹ̀síwájú ni ọkàn àwọn wòlíì èké wọ̀nyí tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìtànjẹ ọkàn wọn?
Jusques à quand?… Veulent-ils, ces prophètes, qui prophétisent le mensonge, ces prophètes de l’imposture de leur cœur,
27 Wọ́n rò wí pé àlá tí wọ́n ń sọ fún ara wọn yóò mú kí àwọn ènìyàn mi gbàgbé orúkọ mi, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe gbàgbé orúkọ mi nípa sí sin òrìṣà Baali.
pensent-ils faire oublier mon nom à mon peuple, pour les rêves qu’ils se racontent les uns aux autres, comme leurs pères ont oublié mon nom pour Baal?
28 Jẹ́ kí wòlíì tí ó bá lá àlá sọ àlá rẹ̀, ṣùgbọ́n jẹ́ kí ẹni tí ó ní ọ̀rọ̀ mí sọ ọ́ ní òtítọ́. Kí ni koríko gbígbẹ ní í ṣe nínú ọkà?” ni Olúwa wí.
Que le prophète qui a eu un songe raconte ce songe; que celui qui a ma parole rapporte fidèlement ma parole. Qu’a de commun la paille avec le froment, — oracle de Yahweh?
29 “Ọ̀rọ̀ mi kò ha a dàbí iná?” ni Olúwa wí, “àti bí òòlù irin tí ń fọ́ àpáta túútúú?
Ma parole n’est-elle pas comme un feu, — oracle de Yahweh, comme un marteau qui brise le roc?
30 “Nítorí náà, èmi lòdì sí àwọn wòlíì ni,” Olúwa wí, “Tí ń jí ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí ó ti ọ̀dọ̀ mi wá lò lọ́dọ̀ ara wọn.
C’est pourquoi, voici que je viens à ces prophètes qui se dérobent mes paroles les uns aux autres.
31 Bẹ́ẹ̀,” ni Olúwa wí, “Èmi lòdì sí àwọn wòlíì tí wọ́n lo ahọ́n wọn káàkiri, síbẹ̀ tí wọ́n ń sọ wí pé, ‘Olúwa wí.’
Voici que je viens à ces prophètes, — oracle de Yahweh, qui agitent leur langue et qui disent: « Oracle de Yahweh! »
32 Nítòótọ́, mo lòdì sí àwọn tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa àlá èké,” ni Olúwa wí. “Wọ́n ń sọ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà nípa onírúurú èké wọn, síbẹ̀ èmi kò rán wọn tàbí yàn wọ́n. Wọn kò sì ran àwọn ènìyàn wọ̀nyí lọ́wọ́ bí ó ti wù kí ó kéré mọ,” ni Olúwa wí.
Voici que je viens à ceux qui prophétisent des songes menteurs, — oracle de Yahweh, qui les racontent, qui égarent mon peuple par leurs mensonges et par leur extravagance. Je ne les ai point envoyés, et je ne leur ai rien commandé; ils ne servent de rien à ce peuple, — oracle de Yahweh.
33 “Nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, tàbí wòlíì tàbí àlùfáà bá bi ọ́ léèrè wí pé, ‘Kí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa?’ Sọ fún wọn wí pé, ‘Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ wo? Èmi yóò pa yín tì ni Olúwa wí.’
Quand ce peuple, ou des prophètes, ou un prêtre t’interrogent en ces termes: « Quel est le fardeau de Yahweh? » tu leur répondras: « C’est vous qui êtes le fardeau, et je vous rejetterai, » — oracle de Yahweh.
34 Bí wòlíì tàbí àlùfáà tàbí ẹnikẹ́ni bá sì gbà wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’ Èmi yóò fi ìyà jẹ ọkùnrin náà àti gbogbo agbo ilé rẹ̀.
Et le prophète, le prêtre ou l’homme du peuple qui dira: « Fardeau de Yahweh, » je visiterai cet homme et sa maison.
35 Èyí ni ohun tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín ń sọ fún ọ̀rẹ́ àti ará ilé rẹ̀: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa sọ?’
Voici comment vous parlerez l’un à l’autre et chacun à son frère: « Qu’a répondu Yahweh? » et « Qu’a dit Yahweh? »
36 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dárúkọ ọ̀rọ̀ ‘ìjìnlẹ̀ Olúwa’ mọ́, nítorí pé ọ̀rọ̀ oníkálùkù ènìyàn di ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ rẹ̀. Nítorí náà, ẹ̀yin ń yí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run alààyè, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run wa padà.
Mais vous ne répéterez plus: « Fardeau de Yahweh! » Car le fardeau de chacun sera sa parole, parce que vous tordez les paroles du Dieu vivant, de Yahweh des armées, notre Dieu.
37 Èyí ni ohun tí ẹ̀yin ń sọ fún wòlíì: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa sí ọ́?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa bá ọ sọ?’
Tu parleras ainsi au prophète: « Que t’a répondu Yahweh? qu’a dit Yahweh? »
38 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ń sọ wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ èyí ni ohun tí Olúwa sọ, Ẹ̀yin ń lo ọ̀rọ̀ yìí, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo sọ fún un yín láti má ṣe lò ó mọ́, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’
Mais si vous dites: « Fardeau de Yahweh, » alors Yahweh parle ainsi: Parce que vous dites ce mot: « Fardeau de Yahweh, » après que j’ai envoyé vers vous pour vous dire: « Ne dites plus: Fardeau de Yahweh, »
39 Nítorí náà, Èmi yóò gbàgbé yín, bẹ́ẹ̀ ni n ó lé e yín kúrò níwájú mi pẹ̀lú àwọn ìlú tí mo fi fún un yín àti àwọn baba yín.
à cause de cela, voici que je vous oublierai entièrement et que je vous rejetterai de devant ma face, vous et la ville que j’avais donnée à vous et à vos pères;
40 Èmi yóò sì mú ìtìjú ayérayé wá sí orí yín, ìtìjú tí kò ní ní ìgbàgbé.”
et je ferai venir sur vous un opprobre éternel, une honte éternelle, qui ne s’oublieront jamais.

< Jeremiah 23 >