< Jeremiah 23 >

1 “Ègbé ni fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń tú agbo ẹran mi ká tí ó sì ń pa wọ́n run!” ni Olúwa wí.
Malheur aux bergers qui détruisent et dispersent les brebis de mon pâturage, dit l'Éternel.
2 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ ní ti àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń darí àwọn ènìyàn mi: “Nítorí tí ẹ̀yin tú agbo ẹran mi ká, tí ẹ lé wọn dànù tí ẹ̀yin kò sì bẹ̀ wọ́n wò. Èmi yóò jẹ yín ní yà nítorí nǹkan búburú tí ẹ ti ṣe,” ni Olúwa wí.
C'est pourquoi Yahvé, le Dieu d'Israël, dit contre les bergers qui font paître mon peuple: « Vous avez dispersé mes brebis, vous les avez chassées, et vous ne les avez pas visitées. Voici, je vais faire retomber sur vous la méchanceté de vos actions, dit Yahvé.
3 “Èmi Olúwa tìkára mi yóò kó ìyókù agbo ẹran mi jọ láti inú gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo ti lé wọn, Èmi yóò mú wọn padà sínú pápá oko wọn, níbẹ̀ ni wọn ó ti bí sí i, tí wọn ó sì pọ̀ sí i.
Je rassemblerai le reste de mon troupeau de tous les pays où je l'ai chassé, je le ramènerai dans ses replis, et il sera fécond et multipliera.
4 Èmi ó wá olùṣọ́-àgùntàn fún wọn, tí yóò darí wọn, wọn kì yóò bẹ̀rù tàbí dààmú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan kì yóò sọnù,” ni Olúwa wí.
J'établirai sur eux des bergers qui les paîtront. Ils n'auront plus peur, ils ne seront plus effrayés, ils ne manqueront de rien, dit Yahvé.
5 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò gbé ẹ̀ka òdodo dìde fún Dafidi, ọba tí yóò lo ìjọba pẹ̀lú ọgbọ́n tí yóò sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ lórí ilẹ̀ náà.
« Voici, les jours viennent, dit Yahvé, « que je susciterai à David un rameau de justice; et il régnera en tant que roi et fera preuve de sagesse, et fera régner la justice et la droiture dans le pays.
6 Ní ọjọ́ rẹ̀ ni a ó gba Juda là, Israẹli yóò sì máa gbé ní aláìléwu. Èyí ni orúkọ tí a ó fi máa pè é: Olúwa Òdodo wa.
En ses jours, Juda sera sauvé, et Israël habitera en sécurité. C'est le nom par lequel il sera appelé: Yahvé notre justice.
7 Nítorí náà, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí ènìyàn kì yóò tún wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.’
« C'est pourquoi voici que les jours viennent, dit Yahvé, où l'on ne dira plus: « Yahvé est vivant, lui qui a fait monter les enfants d'Israël du pays d'Égypte »,
8 Ṣùgbọ́n wọn yóò máa wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa ń bẹ tí ó mú irú-ọmọ ilé Israẹli wá láti ilẹ̀ àríwá àti láti àwọn ilẹ̀ ibi tí mo tí lé wọn lọ,’ wọn ó sì gbé inú ilẹ̀ wọn.”
mais: « Yahvé est vivant, lui qui a fait monter et qui a conduit les rejetons de la maison d'Israël du pays du Nord et de tous les pays où je les avais chassés ». Alors ils habiteront dans leur pays. »
9 Nípa ti àwọn wòlíì èké. Ọkàn mi ti bàjẹ́ nínú mi, gbogbo egungun mi ni ó wárìrì. Èmi dàbí ọ̀mùtí ènìyàn, bí ọkùnrin tí ọtí wáìnì ń pa; nítorí Olúwa àti àwọn ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.
Concernant les prophètes: Mon cœur en moi est brisé. Tous mes os tremblent. Je suis comme un homme ivre, et comme un homme que le vin a vaincu, à cause de Yahvé, et à cause de ses paroles saintes.
10 Ilẹ̀ náà kún fún panṣágà ènìyàn; nítorí ègún, ilẹ̀ náà gbẹ, àwọn koríko orí aṣálẹ̀ ilẹ̀ náà rọ. Àwọn wòlíì tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọ́n sì ń lo agbára wọn lọ́nà àìtọ́.
« Car le pays est rempli d'adultères; car à cause de la malédiction, le pays est en deuil. Les pâturages du désert se sont asséchés. Leur parcours est mauvais, et leur pouvoir n'est pas juste;
11 “Wòlíì àti àlùfáà kò gbé ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run; kódà nínú tẹmpili mi ni mo rí ìwà búburú wọn,” ni Olúwa wí.
car le prophète et le prêtre sont tous deux profanes. Oui, dans ma maison, j'ai trouvé leur méchanceté, dit Yahvé.
12 “Nítorí náà, ọ̀nà wọn yóò di yíyọ́, a ó lé wọn jáde sínú òkùnkùn; níbẹ̀ ni wọn yóò ṣubú. Èmi yóò mú ìdààmú wá sórí wọn, ní ọdún tí a jẹ wọ́n ní ìyà,” ni Olúwa wí.
C'est pourquoi leur chemin sera pour eux comme des lieux glissants dans les ténèbres. Ils seront conduits sur, et y tomber; car je vais faire venir le malheur sur eux, même l'année de leur visite, dit Yahvé.
13 “Láàrín àwọn wòlíì Samaria, Èmi rí ohun tí ń lé ni sá. Wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ Baali wọ́n sì mú Israẹli ènìyàn mi ṣìnà.
« J'ai vu la folie des prophètes de Samarie. Ils ont prophétisé par Baal, et fait errer mon peuple Israël.
14 Àti láàrín àwọn wòlíì Jerusalẹmu, èmi ti rí ohun búburú. Wọ́n ṣe panṣágà, wọ́n sì ń ṣèké. Wọ́n fún àwọn olùṣe búburú ní agbára, tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí ó yípadà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀. Gbogbo wọn dàbí Sodomu níwájú mi, àti àwọn ènìyàn olùgbé rẹ̀ bí Gomorra.”
Dans les prophètes de Jérusalem, j'ai aussi vu une chose horrible: ils commettent des adultères et marchent dans le mensonge. Ils renforcent les mains des malfaiteurs, afin que personne ne revienne de sa méchanceté. Ils sont tous devenus pour moi comme Sodome, et ses habitants comme Gomorrhe. »
15 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí ní ti àwọn wòlíì: “Èmi yóò mú wọn jẹ oúnjẹ kíkorò, wọn yóò mu omi májèlé nítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jerusalẹmu ni àìwà-bí-Ọlọ́run ti tàn ká gbogbo ilẹ̀.”
C'est pourquoi Yahvé des Armées dit à propos des prophètes: « Voici, je vais les nourrir d'absinthe, et leur faire boire de l'eau empoisonnée; car les prophètes de Jérusalem ont répandu l'impiété dans tout le pays. »
16 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ má ṣe fi etí sí àsọtẹ́lẹ̀ tí àwọn wòlíì èké ń sọ fún un yín. Wọ́n ń kún inú ọkàn yín pẹ̀lú ìrètí asán. Wọ́n ń sọ ìran láti ọkàn ara wọn, kì í ṣe láti ẹnu Olúwa.
Yahvé des Armées dit, « N'écoutez pas les paroles des prophètes qui vous prophétisent. Ils vous apprennent la vanité. Ils parlent d'une vision de leur propre cœur, et non de la bouche de Yahvé.
17 Wọ́n ń sọ fún àwọn tí ó ń gàn mí pé, ‘Olúwa ti wí pé, ẹ̀yin ó ní àlàáfíà.’ Wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn tí ó rìn nípa agídí ọkàn rẹ̀ pé, ‘Kò sí ìpalára kan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí yín.’
Ils disent continuellement à ceux qui me méprisent, Yahvé a dit: « Vous aurez la paix ». et à tous ceux qui marchent dans l'obstination de leur propre cœur, ils disent, « Aucun malheur ne viendra sur vous.
18 Ṣùgbọ́n èwo nínú wọn ni ó dúró nínú ìgbìmọ̀ Olúwa láti rí i tàbí gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀? Ta ni ó gbọ́ tí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ náà?
Car qui s'est tenu dans le conseil de Yahvé, pour qu'il perçoive et entende sa parole? Qui a écouté ma parole, et l'a entendue?
19 Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jáde pẹ̀lú ìbínú à fẹ́ yíká ìjì yóò fẹ́ sí orí àwọn olùṣe búburú.
Voici que l'orage de Yahvé, sa colère, a éclaté. Oui, une tempête tourbillonnante! Elle éclatera sur la tête des méchants.
20 Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀ títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ, ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.
La colère de Yahvé ne reviendra pas avant qu'il ait exécuté et a réalisé les intentions de son cœur. Dans les derniers jours, vous le comprendrez parfaitement.
21 Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyí síbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn. Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀, síbẹ̀ wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Je n'ai pas envoyé ces prophètes, et pourtant ils ont couru. Je ne leur ai pas parlé, mais ils ont prophétisé.
22 Ṣùgbọ́n ì bà ṣe pé wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi, wọn ìbá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi. Wọn ìbá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi fun àwọn ènìyàn wọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nà àti ìṣe búburú wọn.
Mais s'ils s'étaient tenus dans mon conseil, alors ils auraient fait en sorte que mon peuple entende mes paroles, et les aurait détournés de leur mauvaise voie, et de la méchanceté de leurs actes.
23 “Ǹjẹ́ Ọlọ́run tòsí nìkan ni Èmi bí?” ni Olúwa wí, “kì í sì í ṣe Ọlọ́run ọ̀nà jíjìn.
« Je suis un Dieu à portée de main », dit Yahvé, « et non un Dieu lointain?
24 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè sá pamọ́ sí ibi kọ́lọ́fín kan, kí èmi má ba a rí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi kò ha a kún ọ̀run àti ayé bí?” ni Olúwa wí.
Quelqu'un peut-il se cacher dans des lieux secrets pour que je ne puisse pas le voir? » dit Yahvé. « Ne remplis-je pas le ciel et la terre? » dit Yahvé.
25 “Mo ti gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn wòlíì èké tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ mi ń sọ. Wọ́n sọ wí pé, ‘Mo lá àlá! Mo lá àlá!’
« J'ai entendu ce qu'ont dit les prophètes, qui prophétisent des mensonges en mon nom, disant: 'J'ai eu un rêve! J'ai eu un songe!
26 Títí di ìgbà wo ni èyí yóò fi máa tẹ̀síwájú ni ọkàn àwọn wòlíì èké wọ̀nyí tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìtànjẹ ọkàn wọn?
Jusqu'à quand cela sera-t-il dans le cœur des prophètes qui prophétisent le mensonge, même les prophètes de la tromperie de leur propre cœur?
27 Wọ́n rò wí pé àlá tí wọ́n ń sọ fún ara wọn yóò mú kí àwọn ènìyàn mi gbàgbé orúkọ mi, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe gbàgbé orúkọ mi nípa sí sin òrìṣà Baali.
Ils ont l'intention de faire oublier mon nom à mon peuple par les rêves qu'ils racontent chacun à son prochain, comme leurs pères ont oublié mon nom à cause de Baal.
28 Jẹ́ kí wòlíì tí ó bá lá àlá sọ àlá rẹ̀, ṣùgbọ́n jẹ́ kí ẹni tí ó ní ọ̀rọ̀ mí sọ ọ́ ní òtítọ́. Kí ni koríko gbígbẹ ní í ṣe nínú ọkà?” ni Olúwa wí.
Que le prophète qui a un rêve raconte un rêve, et que celui qui a ma parole dise fidèlement ma parole. Qu'est-ce que la paille pour le blé? dit Yahvé.
29 “Ọ̀rọ̀ mi kò ha a dàbí iná?” ni Olúwa wí, “àti bí òòlù irin tí ń fọ́ àpáta túútúú?
« Ma parole n'est-elle pas comme un feu, dit Yahvé, et comme un marteau qui brise le rocher?
30 “Nítorí náà, èmi lòdì sí àwọn wòlíì ni,” Olúwa wí, “Tí ń jí ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí ó ti ọ̀dọ̀ mi wá lò lọ́dọ̀ ara wọn.
C'est pourquoi voici, j'en veux aux prophètes, dit l'Éternel, qui volent chacun mes paroles à leur prochain.
31 Bẹ́ẹ̀,” ni Olúwa wí, “Èmi lòdì sí àwọn wòlíì tí wọ́n lo ahọ́n wọn káàkiri, síbẹ̀ tí wọ́n ń sọ wí pé, ‘Olúwa wí.’
Voici, j'en veux aux prophètes, dit l'Éternel, qui se servent de leur langue et disent: « Il dit ».
32 Nítòótọ́, mo lòdì sí àwọn tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa àlá èké,” ni Olúwa wí. “Wọ́n ń sọ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà nípa onírúurú èké wọn, síbẹ̀ èmi kò rán wọn tàbí yàn wọ́n. Wọn kò sì ran àwọn ènìyàn wọ̀nyí lọ́wọ́ bí ó ti wù kí ó kéré mọ,” ni Olúwa wí.
Voici, j'en veux à ceux qui prophétisent des songes mensongers, dit Yahvé, qui les racontent et égarent mon peuple par leurs mensonges et par leur vaine vantardise; pourtant je ne les ai ni envoyés ni commandés. Ils ne profitent pas du tout à ce peuple », dit Yahvé.
33 “Nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, tàbí wòlíì tàbí àlùfáà bá bi ọ́ léèrè wí pé, ‘Kí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa?’ Sọ fún wọn wí pé, ‘Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ wo? Èmi yóò pa yín tì ni Olúwa wí.’
« Lorsque ce peuple, ou le prophète, ou un prêtre, t'interrogera en disant: « Quel est le message de Yahvé? Tu leur répondras: « Quel message? Je vous rejetterai, dit Yahvé ».
34 Bí wòlíì tàbí àlùfáà tàbí ẹnikẹ́ni bá sì gbà wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’ Èmi yóò fi ìyà jẹ ọkùnrin náà àti gbogbo agbo ilé rẹ̀.
Quant au prophète, au prêtre et au peuple qui diront: « Le message de Yahvé », je punirai même cet homme et sa famille.
35 Èyí ni ohun tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín ń sọ fún ọ̀rẹ́ àti ará ilé rẹ̀: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa sọ?’
Vous direz chacun à son voisin, chacun à son frère: « Qu'est-ce que l'Éternel a répondu? » et « Qu'est-ce que l'Éternel a dit? »
36 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dárúkọ ọ̀rọ̀ ‘ìjìnlẹ̀ Olúwa’ mọ́, nítorí pé ọ̀rọ̀ oníkálùkù ènìyàn di ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ rẹ̀. Nítorí náà, ẹ̀yin ń yí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run alààyè, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run wa padà.
Vous ne parlerez plus du message de l'Éternel, car la parole de chacun est devenue son message, car vous avez perverti les paroles du Dieu vivant, de l'Éternel des armées, notre Dieu.
37 Èyí ni ohun tí ẹ̀yin ń sọ fún wòlíì: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa sí ọ́?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa bá ọ sọ?’
Vous direz au prophète: « Que t'a répondu Yahvé? » et « Qu'a dit Yahvé?
38 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ń sọ wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ èyí ni ohun tí Olúwa sọ, Ẹ̀yin ń lo ọ̀rọ̀ yìí, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo sọ fún un yín láti má ṣe lò ó mọ́, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’
Si vous dites: « Le message de l'Éternel », l'Éternel dit: « Parce que vous dites cette parole: « Le message de l'Éternel », et que je vous ai envoyé dire de ne pas dire: « Le message de l'Éternel »,
39 Nítorí náà, Èmi yóò gbàgbé yín, bẹ́ẹ̀ ni n ó lé e yín kúrò níwájú mi pẹ̀lú àwọn ìlú tí mo fi fún un yín àti àwọn baba yín.
voici, je vous oublierai, et je vous rejetterai avec la ville que j'ai donnée à vous et à vos pères, loin de ma présence.
40 Èmi yóò sì mú ìtìjú ayérayé wá sí orí yín, ìtìjú tí kò ní ní ìgbàgbé.”
Je mettrai sur toi un opprobre éternel et une honte perpétuelle, qui ne s'oubliera pas.'"

< Jeremiah 23 >