< Jeremiah 23 >

1 “Ègbé ni fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń tú agbo ẹran mi ká tí ó sì ń pa wọ́n run!” ni Olúwa wí.
Ve de Hyrder, som ødelægge og adsprede min Græsgangs Faar! siger Herren.
2 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ ní ti àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń darí àwọn ènìyàn mi: “Nítorí tí ẹ̀yin tú agbo ẹran mi ká, tí ẹ lé wọn dànù tí ẹ̀yin kò sì bẹ̀ wọ́n wò. Èmi yóò jẹ yín ní yà nítorí nǹkan búburú tí ẹ ti ṣe,” ni Olúwa wí.
Derfor, saa siger Herren, Israels Gud, imod Hyrderne, som vogte mit Folk: I have adspredt mine Faar og fordrevet dem og ikke set til dem; se, jeg vil hjemsøge eder for eders Idrætters Ondskabs Skyld, siger Herren.
3 “Èmi Olúwa tìkára mi yóò kó ìyókù agbo ẹran mi jọ láti inú gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo ti lé wọn, Èmi yóò mú wọn padà sínú pápá oko wọn, níbẹ̀ ni wọn ó ti bí sí i, tí wọn ó sì pọ̀ sí i.
Og jeg vil samle de overblevne af mine Faar fra alle de Lande, hvorhen jeg har fordrevet dem; og jeg vil føre dem tilbage til deres Græsgange, og de skulle vorde frugtbare og mangfoldige.
4 Èmi ó wá olùṣọ́-àgùntàn fún wọn, tí yóò darí wọn, wọn kì yóò bẹ̀rù tàbí dààmú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan kì yóò sọnù,” ni Olúwa wí.
Og over dem vil jeg sætte Hyrder, som skulle vogte dem; og de skulle ikke mere frygte og ikke forskrækkes og ikke savnes, siger Herren.
5 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò gbé ẹ̀ka òdodo dìde fún Dafidi, ọba tí yóò lo ìjọba pẹ̀lú ọgbọ́n tí yóò sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ lórí ilẹ̀ náà.
Se, de Dage komme, siger Herren, da jeg vil oprejse David en retfærdig Vækst; og han skal regere som en Konge og handle viselig og øve Ret og Retfærdighed paa Jorden.
6 Ní ọjọ́ rẹ̀ ni a ó gba Juda là, Israẹli yóò sì máa gbé ní aláìléwu. Èyí ni orúkọ tí a ó fi máa pè é: Olúwa Òdodo wa.
I hans Dage skal Juda frelses og Israel bo tryggelig; og dette er hans Navn, som man skal kalde ham med: \x{201c}Herren vor Retfærdighed\x{201d}.
7 Nítorí náà, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí ènìyàn kì yóò tún wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.’
Derfor se, de Dage komme, siger Herren, da de ikke mere skulle sige: Saa sandt Herren lever, som førte Israels Børn op fra Ægyptens Land!
8 Ṣùgbọ́n wọn yóò máa wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa ń bẹ tí ó mú irú-ọmọ ilé Israẹli wá láti ilẹ̀ àríwá àti láti àwọn ilẹ̀ ibi tí mo tí lé wọn lọ,’ wọn ó sì gbé inú ilẹ̀ wọn.”
men derimod: Saa sandt Herren lever, som førte og bragte Israels Hus's Sæd op fra Nordenlandet og fra alle de Lande, hvorhen jeg har fordrevet dem! Og de skulle bo i deres eget Land.
9 Nípa ti àwọn wòlíì èké. Ọkàn mi ti bàjẹ́ nínú mi, gbogbo egungun mi ni ó wárìrì. Èmi dàbí ọ̀mùtí ènìyàn, bí ọkùnrin tí ọtí wáìnì ń pa; nítorí Olúwa àti àwọn ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.
Over Profeterne er mit Hjerte knust inden i mig, alle mine Ben bæve, jeg er bleven som en drukken Mand og som en Mand, over hvem Vinen har faaet Overhaand, for Herrens Skyld og for hans hellige Ords Skyld.
10 Ilẹ̀ náà kún fún panṣágà ènìyàn; nítorí ègún, ilẹ̀ náà gbẹ, àwọn koríko orí aṣálẹ̀ ilẹ̀ náà rọ. Àwọn wòlíì tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọ́n sì ń lo agbára wọn lọ́nà àìtọ́.
Thi Landet er fuldt af Horkarle, og Landet sørger for Forbandelsens Skyld, Græsgangene i Ørken ere hentørrede; og deres Løb var ondt, og deres Magt brugtes ikke ret.
11 “Wòlíì àti àlùfáà kò gbé ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run; kódà nínú tẹmpili mi ni mo rí ìwà búburú wọn,” ni Olúwa wí.
Thi baade Profet og Præst ere vanhellige; endog i mit Hus har jeg fundet deres Ondskab, siger Herren.
12 “Nítorí náà, ọ̀nà wọn yóò di yíyọ́, a ó lé wọn jáde sínú òkùnkùn; níbẹ̀ ni wọn yóò ṣubú. Èmi yóò mú ìdààmú wá sórí wọn, ní ọdún tí a jẹ wọ́n ní ìyà,” ni Olúwa wí.
Derfor skal deres Vej blive for dem som slibrige Stier i Mørke, de skulle stødes frem og falde paa den; thi jeg vil lade Ulykke komme over dem, deres Hjemsøgelses Aar, siger Herren.
13 “Láàrín àwọn wòlíì Samaria, Èmi rí ohun tí ń lé ni sá. Wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ Baali wọ́n sì mú Israẹli ènìyàn mi ṣìnà.
Og hos Profeterne i Samaria har jeg set Daarlighed, de spaaede ved Baal og forvildede mit Folk Israel;
14 Àti láàrín àwọn wòlíì Jerusalẹmu, èmi ti rí ohun búburú. Wọ́n ṣe panṣágà, wọ́n sì ń ṣèké. Wọ́n fún àwọn olùṣe búburú ní agbára, tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí ó yípadà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀. Gbogbo wọn dàbí Sodomu níwájú mi, àti àwọn ènìyàn olùgbé rẹ̀ bí Gomorra.”
men hos Profeterne i Jerusalem har jeg set en gruelig Ting, at de bedrive Hor og gaa om med Løgn, saa at de styrke de ondes Hænder, at de ikke skulle omvende sig hver fra sin Ondskab, de ere alle blevne for mig som Sodoma og dens Indbyggere som Gomorra.
15 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí ní ti àwọn wòlíì: “Èmi yóò mú wọn jẹ oúnjẹ kíkorò, wọn yóò mu omi májèlé nítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jerusalẹmu ni àìwà-bí-Ọlọ́run ti tàn ká gbogbo ilẹ̀.”
Derfor siger den Herre Zebaoth saaledes om Profeterne: Se, jeg vil give dem Malurt at æde og give dem besk Vand at drikke; thi fra Profeterne i Jerusalem er Vanhellighed kommen ud i det ganske Land.
16 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ má ṣe fi etí sí àsọtẹ́lẹ̀ tí àwọn wòlíì èké ń sọ fún un yín. Wọ́n ń kún inú ọkàn yín pẹ̀lú ìrètí asán. Wọ́n ń sọ ìran láti ọkàn ara wọn, kì í ṣe láti ẹnu Olúwa.
Saa siger den Herre Zebaoth: Hører ikke paa Profeternes Ord, som spaa for eder, de bedrage eder, de tale efter deres Hjertes Syn, ikke af Herrens Mund.
17 Wọ́n ń sọ fún àwọn tí ó ń gàn mí pé, ‘Olúwa ti wí pé, ẹ̀yin ó ní àlàáfíà.’ Wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn tí ó rìn nípa agídí ọkàn rẹ̀ pé, ‘Kò sí ìpalára kan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí yín.’
De sige og sige til dem, som foragte mig: Herren har talt, I skulle have Fred; og de sige til hver, som vandrer i sit Hjertes Stivhed: Der skal ingen Ulykke komme over eder.
18 Ṣùgbọ́n èwo nínú wọn ni ó dúró nínú ìgbìmọ̀ Olúwa láti rí i tàbí gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀? Ta ni ó gbọ́ tí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ náà?
Thi hvo har staaet i Herrens hemmelige Raad og ser og hører hans Ord? hvo har lyttet til hans Ord, saa han hørte det?
19 Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jáde pẹ̀lú ìbínú à fẹ́ yíká ìjì yóò fẹ́ sí orí àwọn olùṣe búburú.
Se, Herrens Storm, Fortørnelse, farer ud, og en hvirvlende Storm! den skal hvirvle over de ugudeliges Hoved.
20 Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀ títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ, ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.
Herrens Vrede skal ikke vende om, inden han har udført, og inden han har fuldkommet sit Hjertes Tanker; i de sidste Dage skulle I ret faa Forstand derpaa.
21 Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyí síbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn. Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀, síbẹ̀ wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
Jeg sendte ikke Profeterne, dog løb de; jeg talte ikke til dem, dog spaaede de.
22 Ṣùgbọ́n ì bà ṣe pé wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi, wọn ìbá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi. Wọn ìbá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi fun àwọn ènìyàn wọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nà àti ìṣe búburú wọn.
Men dersom de havde staaet i mit hemmelige Raad, da vilde de lade mit Folk høre mine Ord, og de vilde føre dem tilbage fra deres onde Vej og fra deres Idrætters Ondskab.
23 “Ǹjẹ́ Ọlọ́run tòsí nìkan ni Èmi bí?” ni Olúwa wí, “kì í sì í ṣe Ọlọ́run ọ̀nà jíjìn.
Er jeg kun en Gud nær hos? siger Herren, og ikke en Gud langt borte fra?
24 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè sá pamọ́ sí ibi kọ́lọ́fín kan, kí èmi má ba a rí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi kò ha a kún ọ̀run àti ayé bí?” ni Olúwa wí.
Mon nogen kan skjule sig paa lønlige Steder, saa at jeg ikke kan se ham? siger Herren; er jeg ikke den, som opfylder Himlene og Jorden? siger Herren.
25 “Mo ti gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn wòlíì èké tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ mi ń sọ. Wọ́n sọ wí pé, ‘Mo lá àlá! Mo lá àlá!’
Jeg har hørt, hvad Profeterne have sagt, de, som spaa Løgn i mit Navn og sige: Jeg drømte, jeg drømte.
26 Títí di ìgbà wo ni èyí yóò fi máa tẹ̀síwájú ni ọkàn àwọn wòlíì èké wọ̀nyí tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìtànjẹ ọkàn wọn?
Hvor længe dog! mon Profeterne, som spaa Løgn, og som ere Profeter ved deres Hjertes Bedrageri, have i Sinde,
27 Wọ́n rò wí pé àlá tí wọ́n ń sọ fún ara wọn yóò mú kí àwọn ènìyàn mi gbàgbé orúkọ mi, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe gbàgbé orúkọ mi nípa sí sin òrìṣà Baali.
og mon de tænke paa at bringe mit Folk til at glemme mit Navn ved deres Drømme, som de fortælle hver sin Næste? ligesom deres Fædre glemte mit Navn for Baals Skyld.
28 Jẹ́ kí wòlíì tí ó bá lá àlá sọ àlá rẹ̀, ṣùgbọ́n jẹ́ kí ẹni tí ó ní ọ̀rọ̀ mí sọ ọ́ ní òtítọ́. Kí ni koríko gbígbẹ ní í ṣe nínú ọkà?” ni Olúwa wí.
Den Profet, som har en Drøm, fortælle en Drøm, men den, hos hvem mit Ord er, tale mit Ord i Sandhed; hvad har Halm at gøre med Kornet? siger Herren.
29 “Ọ̀rọ̀ mi kò ha a dàbí iná?” ni Olúwa wí, “àti bí òòlù irin tí ń fọ́ àpáta túútúú?
Er mit Ord ikke saaledes som Ild? siger Herren, og som en Hammer, der sønderslaar en Klippe?
30 “Nítorí náà, èmi lòdì sí àwọn wòlíì ni,” Olúwa wí, “Tí ń jí ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí ó ti ọ̀dọ̀ mi wá lò lọ́dọ̀ ara wọn.
Derfor se, jeg er imod de Profeter, siger Herren, som stjæle mine Ord, den ene fra den anden.
31 Bẹ́ẹ̀,” ni Olúwa wí, “Èmi lòdì sí àwọn wòlíì tí wọ́n lo ahọ́n wọn káàkiri, síbẹ̀ tí wọ́n ń sọ wí pé, ‘Olúwa wí.’
Se, jeg er imod Profeter, siger Herren, som tage deres Tunge og varsle: \x{201c}Han har sagt det\x{201d}.
32 Nítòótọ́, mo lòdì sí àwọn tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa àlá èké,” ni Olúwa wí. “Wọ́n ń sọ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà nípa onírúurú èké wọn, síbẹ̀ èmi kò rán wọn tàbí yàn wọ́n. Wọn kò sì ran àwọn ènìyàn wọ̀nyí lọ́wọ́ bí ó ti wù kí ó kéré mọ,” ni Olúwa wí.
Se, jeg er imod dem, som spaa løgnagtige Drømme, siger Herren, og som fortælle dem og forvilde mit Folk med deres Løgne og med deres Letfærdighed; og jeg har dog ikke sendt dem og ikke givet dem Befaling, og de gavne slet ikke dette Folk, siger Herren.
33 “Nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, tàbí wòlíì tàbí àlùfáà bá bi ọ́ léèrè wí pé, ‘Kí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa?’ Sọ fún wọn wí pé, ‘Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ wo? Èmi yóò pa yín tì ni Olúwa wí.’
Og naar dette Folk eller Profeten eller en Præst spørger dig og siger: Hvad er Herrens Byrde? da skal du sige til dem: \x{201c}Hvad, Byrde!\x{201d} og: \x{201c}Jeg vil bortkaste eder!\x{201d} siger Herren.
34 Bí wòlíì tàbí àlùfáà tàbí ẹnikẹ́ni bá sì gbà wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’ Èmi yóò fi ìyà jẹ ọkùnrin náà àti gbogbo agbo ilé rẹ̀.
Og naar Profeten eller Præsten eller Folket siger: \x{201c}Herrens Byrde!\x{201d} da vil jeg hjemsøge den Mand og hans Hus.
35 Èyí ni ohun tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín ń sọ fún ọ̀rẹ́ àti ará ilé rẹ̀: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa sọ?’
Saaledes skulle I sige, hver til sin Næste og hver til sin Broder: \x{201c}Hvad har Herren svaret?\x{201d} og: \x{201c}Hvad har Herren talt?\x{201d}
36 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dárúkọ ọ̀rọ̀ ‘ìjìnlẹ̀ Olúwa’ mọ́, nítorí pé ọ̀rọ̀ oníkálùkù ènìyàn di ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ rẹ̀. Nítorí náà, ẹ̀yin ń yí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run alààyè, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run wa padà.
Men \x{201c}Herrens Byrde\x{201d} skulle I ikke nævne; thi \x{201c}Byrden\x{201d} vil for Manden blive hans eget Ord, efterdi I have forvendt den levende Guds, den Herre Zebaoths, vor Guds Ord.
37 Èyí ni ohun tí ẹ̀yin ń sọ fún wòlíì: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa sí ọ́?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa bá ọ sọ?’
Saaledes skal du sige til Profeten: Hvad har Herren svaret dig? og hvad har Herren talt?
38 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ń sọ wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ èyí ni ohun tí Olúwa sọ, Ẹ̀yin ń lo ọ̀rọ̀ yìí, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo sọ fún un yín láti má ṣe lò ó mọ́, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’
Men dersom I sige: \x{201c}Herrens Byrde!\x{201d} saa siger Herren derfor saaledes: Fordi I have sagt dette Ord: \x{201c}Herrens Byrde!\x{201d} skønt jeg sendte til eder og lod sige: I skulle ikke sige: Herrens Byrde!
39 Nítorí náà, Èmi yóò gbàgbé yín, bẹ́ẹ̀ ni n ó lé e yín kúrò níwájú mi pẹ̀lú àwọn ìlú tí mo fi fún un yín àti àwọn baba yín.
derfor se, jeg er der, og jeg vil glemme eder og kaste eder og Staden, som jeg gav eder og eders Fædre, bort fra mit Ansigt;
40 Èmi yóò sì mú ìtìjú ayérayé wá sí orí yín, ìtìjú tí kò ní ní ìgbàgbé.”
og jeg vil lægge paa eder evig Forhaanelse og evig Forsmædelse, som ikke skal glemmes.

< Jeremiah 23 >