< Jeremiah 22 >
1 Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀:
Так говорить Господь: Зійди в дім Юдиного царя, і будеш казати там оце слово,
2 ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí.
та й промовиш: Послухай Господнього слова, о ца́рю юдейський, що сидиш на Давидовім троні, ти й раби твої та наро́д твій, що входите в бра́ми оці.
3 Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí.
Так говорить Господь: Чиніть правосу́ддя та правду, і рятуйте грабо́ваного від руки гноби́теля, чужинця́ ж, сироту та вдову́ не гнобі́ть, не грабу́йте, і крови невинної не проливайте на місці цьому́!
4 Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
Бо коли оце слово наспра́вді ви ви́конаєте, то ходитимуть бра́мами дому оцьо́го царі, що будуть сидіти на троні Давида, що їздити бу́дуть колесни́цями й кіньми, він і раб його та наро́д його.
5 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’”
А якщо не послухаєтесь оцих слів, то клянуся Собою — говорить Госпо́дь: руїною ста́неться дім цей!
6 Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi, gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni, dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀, àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.
Бо так промовляє Госпо́дь про дім царя Юди: Ти для Мене Ґілеа́д, щит Ліва́ну, та поправді кажу́ Я, — тебе оберну́ на пустиню, на міста́ незасе́лені!
7 Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀, wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀, wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.
І приготу́ю на тебе отих, що руйнують люди́ну та збро́ю її, і вони твої ке́дри добі́рні зітну́ть і їх повкида́ють в огонь!
8 “Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’
І люди числе́нні ходитимуть містом оцим і будуть казати один до одно́го: За́що Господь зробив так цьому місту великому?
9 Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’”
І відкажуть: За те, що вони поки́нули заповіта Господа, Бога Свого, і вклонялися іншим богам, і служили їм.
10 Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú nítorí kì yóò padà wá mọ́ tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.
Не плачте за вмерлим, і не жалку́йте за ним, — але плакати — плачте за тим, хто відходить в поло́н, бо вже не пове́рнеться, і не побачить землі, де він народився.
11 Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́.
Бо так промовляє Господь до Шаллу́ма, сина Йосіїного, царя Юдиного, що царював замість Йосі́ї, свого ба́тька, що вийшов із місця цього́: Він сюди вже не ве́рнеться!
12 Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”
Бо помре він у місці, куди його полони́ли, Кра́ю ж цього́ не побачить уже.
13 “Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo, àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́ tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.
Горе тому́, хто несправедливістю дім свій будує, а верхні кімна́ти — безпра́в'ям, хто каже своєму ближньому працювати даре́мно, і платні́ його йому не дає,
14 Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀, ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’ A ó sì fi igi kedari bò ó, a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
що говорить: Збудую собі дім великий, і верхні кімна́ти широкі!“І ві́кна собі повиру́бує, й криє кедри́ною, і малю́є червоною фарбою.
15 “Ìwọ ó ha jẹ ọba kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari? Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu? Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo, nítorí náà ó dára fún un.
Чи ти зацарюєш тому́, що в ке́драх ти ме́шкаєш? Чи ж твій ба́тько не їв та не пив? І коли правосу́ддя та правду чинив він, тоді було добре йому́, —
16 Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní, ohun gbogbo sì dára fún un. Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?” ni Olúwa wí.
він розсу́джував справу нужде́нного й бідного, й тоді добре було́! Чи не це — Мене знати? говорить Госпо́дь.
17 “Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ wà lára èrè àìṣòótọ́ láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”
Хіба твої очі та серце твоє не обе́рнені тільки на ко́ристь свою́, та щоб пролива́ти кров невинну, і щоб гніт та насилля чинити?
18 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda: “Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’ Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’
Тому так промовляє Госпо́дь про Єгояки́ма, Йосіїного сина, царя Юдиного: Не будуть за ним голосити: „О мій брате!“й „О се́стро!“Не будуть за ним голосити: „О пане" й „О вели́чносте його!“
19 A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.”
Поховають його, немов того осла, воло́чачи та викидаючи геть за брами Єрусалиму.
20 “Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta, kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani, kí o kígbe sókè láti Abarimu, nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.
Зійди на Лива́н та й кричи, і в Баша́ні свій голос подай, і кричи з Аварі́му, бо пони́щені всі твої дру́зі.
21 Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu, ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’ Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ, ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.
Говорив Я тобі в час гара́зду твого́, але ти каза́ла: „Не слу́хатиму!“Це доро́га твоя від юна́цтва твого́, бо не слухалась ти Мого голосу.
22 Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ, gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn, nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́ nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.
Усіх твоїх па́стирів буря розки́дає, а коха́нці твої підуть до полону, — справді, тоді посоро́млена та побенте́жена будеш за все своє зло!
23 Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’ tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari, ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ, ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!
О ти, що сидиш на Ливані, що ку́блишся в ке́драх, — як ти бу́деш стогна́ти, як бо́лі й дрижа́ння на тебе спаду́ть, мов на ту породі́ллю!
24 “Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀.
Як живий Я, — говорить Госпо́дь, — коли б був Коні́я, син Єгоякимів, цар Юдин, печа́ткою-пе́рснем на правій руці Моїй, — справді Я й звідти тебе зірву́!
25 Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli.
І дам Я тебе в руку тих, хто шукає твоєї душі, і в руку тих, що боїшся ти їх, і в руку Навуходоно́сора, царя вавилонського, і в руку халде́їв.
26 Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí.
І кину тебе й твою матір, яка породила тебе́, до іншого кра́ю, де ви не зроди́лись, — і там — ви повмира́єте!
27 Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”
А до Кра́ю, куди вони пра́гнуть душею своєю верну́тись, — туди не пове́рнуться!
28 Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo, ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́? Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.
Чи муж цей, Коні́я, — це гли́няний по́суд, пого́рджений та розпоро́шений? Хіба він посу́дина та непотрі́бна? Чом відкинені він та насі́ння його́, та й закинені в землю, якої не знають?
29 Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
О Кра́ю, мій Кра́ю, о Кра́ю, — послухай Господнього сло́ва:
30 Báyìí ni Olúwa wí: “Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ, ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀; nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere, èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”
Так говорить Госпо́дь: Запишіть люди́ну оцю самі́тною, мужем, якому не буде щасти́тись у днях його, бо ніко́му з насіння його не пощасти́ться сидіти на троні Давидовім та панувати ще в Юді!