< Jeremiah 22 >

1 Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀:
Tako govori Gospod: »Pojdi dol k hiši Judovega kralja in tam spregovori to besedo
2 ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí.
in reci: ›Poslušaj besedo od Gospoda, oh Judov kralj, ki sediš na Davidovem prestolu, ti in tvoji služabniki in tvoje ljudstvo, ki vstopate pri teh velikih vratih.
3 Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí.
Tako govori Gospod: ›Izvršujte sodbo in pravičnost ter oplenjenega osvobodite iz roke zatiralca. Ne delajte napačno, ne delajte nasilja tujcu [niti] osirotelemu niti vdovi niti ne prelivajte nedolžne krvi na tem kraju.
4 Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
Kajti če zares storite to stvar, potem bodo tam, pri velikih vratih te hiše, vstopali kralji, sedeči na Davidovem prestolu, jahajoči na bojnih vozovih in na konjih, on, njegovi služabniki in njegovo ljudstvo.
5 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’”
Toda če ne boste poslušali teh besed, prisežem pri sebi, ‹ govori Gospod, ›da bo ta hiša postala opustošenje.‹
6 Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi, gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni, dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀, àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.
Kajti tako govori Gospod kraljevi hiši Juda: ›Ti si mi Gileád in glava Libanona, vendar te bom zagotovo spremenil [v] divjino in mesta, ki niso naseljena.
7 Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀, wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀, wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.
Zoper tebe bom pripravil uničevalce, vsakogar s svojimi orožji. Posekali bodo tvoje izbrane cedre in jih vrgli v ogenj.
8 “Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’
Številni narodi bodo šli mimo tega mesta in vsak človek bo rekel svojemu sosedu: ›Zakaj je Gospod tako storil temu velikemu mestu?‹
9 Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’”
Potem bodo odgovorili: ›Ker so zapustili zavezo Gospoda, svojega Boga in oboževali druge bogove ter jim služili.‹
10 Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú nítorí kì yóò padà wá mọ́ tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.
Ne jokajte za mrtvim niti ga ne objokujte, temveč boleče jokajte za tistim, ki gre proč, kajti ne bo se več vrnil niti ne bo videl svoje domače dežele.
11 Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́.
Kajti tako govori Gospod glede Jošíjevega sina Šalúma, Judovega kralja, ki je zakraljeval namesto svojega očeta Jošíja, ki je odšel iz tega kraja: ›Tja se ne bo več vrnil, ‹
12 Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”
temveč bo umrl na kraju, kamor so ga odvedli v ujetništvo in ne bo več videl te dežele.
13 “Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo, àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́ tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.
Gorje tistemu, ki svojo hišo gradi z nepravičnostjo in svoje sobe s krivico; ki brez plačil uporablja pomoč svojega soseda in mu ne daje za njegovo delo;
14 Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀, ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’ A ó sì fi igi kedari bò ó, a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
ki pravi: ›Zgradil si bom široko hišo in velike sobe‹ in si izreže okna; in ta je obložena s cedrovino in pobarvana z živo rdečo.
15 “Ìwọ ó ha jẹ ọba kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari? Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu? Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo, nítorí náà ó dára fún un.
Mar boš kraljeval, ker se zapiraš s cedrovino? Mar ni tvoj oče jedel, pil, izvajal sodbo in pravico in je bilo potem dobro z njim?
16 Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní, ohun gbogbo sì dára fún un. Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?” ni Olúwa wí.
Sodil je primer revnega in pomoči potrebnega; tedaj je bilo dobro z njim. Ali ni bilo to poznati mene?‹ govori Gospod.
17 “Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ wà lára èrè àìṣòótọ́ láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”
Toda tvoje oči in tvoje srce sta zgolj za tvojo pohlepnost, za prelivanje nedolžne krvi, za zatiranje in za nasilje, da ga počneš.
18 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda: “Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’ Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’
Zato tako govori Gospod glede Jojakíma, Jošíjevega sina, Judovega kralja: ›Ne bodo žalovali za njim, rekoč: ›Ah, moj brat!‹ ali ›Ah, sestra.‹ Ne bodo žalovali za njim, rekoč: ›Ah, gospod!‹ ali ›Ah, njegova slava!‹
19 A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.”
Pokopan bo s pokopom osla, povlečen in vržen bo naprej onkraj velikih vrat [prestolnice] Jeruzalem.
20 “Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta, kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani, kí o kígbe sókè láti Abarimu, nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.
Pojdi gor na Libanon in jokaj; povzdigni svoj glas v Bašánu in jokaj iz prehodov, kajti vsi tvoji ljubimci so uničeni.
21 Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu, ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’ Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ, ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.
Govoril sem ti v tvojem uspevanju, toda praviš: ›Ne bom poslušala.‹ To je bil tvoj način od tvoje mladosti, da ne ubogaš mojega glasu.
22 Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ, gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn, nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́ nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.
Veter bo pojedel vse tvoje pastirje in tvoji ljubimci bodo šli v ujetništvo. Potem boš zagotovo osramočena in zbegana zaradi vse svoje zlobnosti.
23 Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’ tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari, ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ, ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!
Oh prebivalec Libanona, ki delaš svoje gnezdo na cedrah, kako pomilovanja vreden boš, ko pridejo nadte ostre bolečine, bolečina kakor ženski v porodnih mukah!
24 “Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀.
Kakor jaz živim, ‹ govori Gospod ›čeprav bi bil Konija, sin Jojahína, Judovega kralja, za pečat na moji desnici, bi te vendar od tam izruval
25 Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli.
in te izročil v roko tistih, ki ti strežejo po življenju in v roko tistih, katerih obraza se bojiš, celo v roko babilonskega kralja Nebukadnezarja in v roko Kaldejcev.
26 Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí.
Vrgel te bom ven in tvojo mater, ki te je nosila, v drugo deželo, kjer nista bila rojena, in tam bosta umrla.
27 Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”
Toda v deželo, kamor se želita vrniti, tja se ne bosta vrnila.
28 Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo, ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́? Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.
Ali je ta mož Konija preziran, polomljen malik? Ali je on posoda, v kateri ni zadovoljstva? Zakaj so izvrženi, on in njegovo seme in so vrženi v deželo, ki je ne poznajo?‹
29 Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Oh zemlja, zemlja, zemlja, poslušaj Gospodovo besedo.
30 Báyìí ni Olúwa wí: “Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ, ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀; nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere, èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”
Tako govori Gospod: ›Zapiši tega moža brez otrok, moža, ki ne bo uspeval v svojih dneh, kajti noben mož iz njegovega semena ne bo uspeval, sedeč na Davidovem prestolu in ne bo več vladal v Judu.‹«

< Jeremiah 22 >