< Jeremiah 22 >
1 Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀:
Аша ворбеште Домнул: „Кобоарэ-те ын каса ымпэратулуй луй Иуда ши аколо ростеште кувинтеле ачестя.
2 ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí.
Сэ спуй: ‘Аскултэ Кувынтул Домнулуй, ымпэрат ал луй Иуда, каре стай пе скаунул де домние ал луй Давид, ту, служиторий тэй ши тот попорул каре интраць пе порциле ачестя!
3 Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí.
Аша ворбеште Домнул: «Фачець дрептате ши жудекатэ; скоатець пе чел асуприт дин мыниле асуприторулуй; ну кинуиць пе стрэин, пе орфан ши пе вэдувэ; ну апэсаць ши ну вэрсаць сынӂе невиноват ын локул ачеста!
4 Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
Кэч, дакэ лукраць дупэ кувынтул ачеста, вор интра пе порциле касей ачестея ымпэраць каре стау пе скаунул де домние ал луй Давид, суиць ын каре ши кэлэрь пе кай, ей, служиторий лор ши попорул лор.
5 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’”
Дар, дакэ ну вець аскулта кувинтеле ачестя, пе Мине Ынсумь жур», зиче Домнул, «кэ ачастэ касэ ва ажунӂе о дэрымэтурэ!»’”
6 Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi, gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni, dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀, àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.
Кэч аша ворбеште Домнул асупра касей ымпэратулуй луй Иуда: „Ту ешть пентру Мине прекум Галаадул, ка вырфул Либанулуй, дар, ку адевэрат, вой фаче дин тине ун пустиу, о четате фэрэ локуиторь!
7 Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀, wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀, wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.
Прегэтеск ымпотрива та ниште нимичиторь, фиекаре ку армеле луй: ей вор тэя чей май фрумошь чедри ай тэй ши-й вор арунка ын фок.
8 “Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’
Мулте нямурь вор трече пе лынгэ четатя ачаста ши вор зиче унул алтуя: ‘Пентру че а фэкут Домнул аша ачестей четэць марь?’
9 Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’”
Ши се ва рэспунде: ‘Пентру кэ ау пэрэсит легэмынтул Домнулуй Думнезеулуй лор, пентру кэ с-ау ынкинат ынаинтя алтор думнезей ши ле-ау служит!’”
10 Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú nítorí kì yóò padà wá mọ́ tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.
Ну плынӂець пе чел морт ши ну вэ бочиць пентру ел, чи плынӂець май деграбэ пе чел че се дуче, каре ну се ва май ынтоарче ши ну-шь ва май ведя цара де наштере!
11 Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́.
Кэч аша ворбеште Домнул деспре Шалум, фиул луй Иосия, ымпэратул луй Иуда, каре домня ын локул татэлуй сэу Иосия ши каре а ешит дин локул ачеста: „Ну се ва май ынтоарче ын ел,
12 Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”
чи ва мури ын локул унде есте дус роб ши ну ва май ведя цара ачаста.
13 “Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo, àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́ tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.
Вай де чел че ышь зидеште каса ку недрептате ши одэиле, ку нелеӂюире; каре пуне пе апроапеле сэу сэ лукрезе деӂяба, фэрэ сэ-й дя плата;
14 Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀, ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’ A ó sì fi igi kedari bò ó, a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
каре зиче: ‘Ымь вой зиди о касэ маре ши одэй ынкэпэтоаре’ ши-й фаче ферестре мулте, о кэптушеште ку чедру ши о вопсеште ку рошу!
15 “Ìwọ ó ha jẹ ọba kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari? Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu? Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo, nítorí náà ó dára fún un.
Ымпэрат ешть ту оаре, де те ынтречь ын чедри? Ну мынка татэл тэу ши ну бя ши ел? Ши тотушь ел фэчя дрептате ши жудекатэ, ши ера феричит!
16 Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní, ohun gbogbo sì dára fún un. Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?” ni Olúwa wí.
Жудека причина сэракулуй ши а челуй липсит ши ера феричит. Ну ынсямнэ лукрул ачеста а Мэ куноаште?”, зиче Домнул.
17 “Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ wà lára èrè àìṣòótọ́ láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”
„Дар ту н-ай окь ши инимэ декыт ка сэ те дедай ла лэкомие, ка сэ вершь сынӂе невиноват ши сэ ынтребуинцезь асуприре ши силничие.”
18 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda: “Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’ Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’
Де ачея, аша ворбеште Домнул деспре Иоаким, фиул луй Иосия, ымпэратул луй Иуда: „Ну-л вор плынӂе зикынд: ‘Вай, фрателе меу! Вай, сора мя!’ Нич ну-л вор плынӂе зикынд: ‘Вай, доамне! Вай, Мэрия Са!’
19 A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.”
Чи ва фи ынмормынтат ка ун мэгар, ва фи тырыт ши арункат афарэ дин порциле Иерусалимулуй!
20 “Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta, kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani, kí o kígbe sókè láti Abarimu, nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.
Суе-те пе Либан ши стригэ! Ыналцэ-ць гласул де пе Басан! Ши стригэ де пе ынэлцимя Абарим! Кэч тоць чей че те юбяу сунт здробиць!
21 Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu, ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’ Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ, ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.
Ць-ам ворбит кынд ыць мерӂя бине, дар ту зичяй: ‘Ну пот с-аскулт!’ Аша ай лукрат дин тинереця та ши н-ай аскултат гласул Меу.
22 Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ, gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn, nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́ nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.
Пе тоць пэсторий тэй ый ва паште вынтул ши чей че те юбеск вор мерӂе ын робие. Атунч вей фи акоперит де рушине ши вей роши дин причина ынтреӂий тале рэутэць.
23 Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’ tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari, ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ, ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!
Ту, каре локуешть пе Либан акум, каре ыць ай куйбул ын чедри, кум вей ӂеме кынд те вор ажунӂе дурериле, дурерь ка але уней фемей ын мунчь!
24 “Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀.
Пе вяца Мя”, зиче Домнул, „кэ, ши кяр дакэ Иекония, фиул луй Иоиаким, ымпэратул луй Иуда, ар фи ун инел де печетлуит ын мына Мя чя дряптэ, те-аш скоате ши де аколо.
25 Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli.
Те вой да ын мыниле челор че вор сэ-ць я вяца, ын мыниле ачелора ынаинтя кэрора тремурь, ын мыниле луй Небукаднецар, ымпэратул Бабилонулуй, ын мыниле халдеенилор.
26 Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí.
Те вой арунка, пе тине ши пе мамэ-та каре те-а нэскут, ынтр-о алтэ царэ, унде ну в-аць нэскут ши аколо вець мури!
27 Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”
Дар, ын цара ын каре вор дори сэ се ынтоаркэ, ну се вор май ынтоарче!
28 Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo, ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́? Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.
Есте ун вас диспрецуит, сфэрымат, ачест Иекония? Есте ел ун лукру кэруя ну-й дай ничун прец? Пентру че сунт арункаць оаре, ел ши сэмынца луй, ши азвырлиць ынтр-о царэ пе каре н-о куноск?
29 Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Царэ, царэ, царэ, аскултэ гласул Домнулуй!
30 Báyìí ni Olúwa wí: “Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ, ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀; nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere, èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”
Аша ворбеште Домнул: ‘Скриець пе омул ачеста ка липсит де копий, ка ун ом кэруя ну-й ва мерӂе бине тоатэ вяца луй, кэч ничунул дин урмаший луй ну ва избути сэ шадэ пе скаунул де домние ал луй Давид ши сэ домняскэ песте Иуда.’”