< Jeremiah 22 >

1 Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀:
Tā saka Tas Kungs: noej Jūda ķēniņa namā un runā tur šo vārdu
2 ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí.
Un saki: klausi Tā Kunga vārdu, Jūda ķēniņ, kas sēdi Dāvida goda krēslā, tu un tavi kalpi un tavi ļaudis, visi, kas ieejat pa šiem vārtiem.
3 Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí.
Tā saka Tas Kungs: nesiet tiesu un taisnību un izglābiet aplaupīto no spaidītāja rokas, un neplēšat svešinieku, bāriņu, atraitni, nedariet varas darbu un neizlejat šai vietā nenoziedzīgas asinis.
4 Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
Jo kad jūs tā darīsiet, tad pa šā nama vārtiem ieies ķēniņi, kas sēdēs uz Dāvida goda krēsla, un brauks ar ratiem un zirgiem, pats un viņa kalpi un viņa ļaudis.
5 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’”
Bet ja jūs šos vārdus neklausīsiet, tad Es pie Sevis esmu zvērējis, saka Tas Kungs, ka šim namam būs palikt par posta vietu.
6 Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi, gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni, dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀, àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.
Jo tā saka Tas Kungs par Jūda ķēniņa namu: tu Man esi kā Gileāda, kā Lībanus galva, bet tiešām, Es tevi darīšu par tuksnesi un tās pilsētas bez iedzīvotājiem.
7 Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀, wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀, wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.
Jo Es pret tevi iecelšu postītājus, ikvienu ar saviem ieročiem; tie nocirtīs tavus labākos ciedru kokus un tos metīs ugunī.
8 “Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’
Tad daudz pagānu šai pilsētai ies garām un sacīs cits uz citu: kādēļ Tas Kungs šai lielai pilsētai tā darījis?
9 Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’”
Un tie sacīs: tādēļ ka tie atstājuši Tā Kunga, sava Dieva, derību un zemē metušies priekš citiem dieviem un tiem kalpojuši.
10 Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú nítorí kì yóò padà wá mọ́ tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.
Neraudiet par nomirušo un nežēlojiet viņu; raudiet raudādami par to, kas aiziet, jo tas neatgriezīsies atpakaļ, redzēt savas dzimtenes zemi.
11 Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́.
Jo tā saka Tas Kungs par Šallumu, Josijas dēlu, Jūda ķēniņu, kas valda sava tēva Josijas vietā, kas no šās vietas aizgājis: viņš vairs negriezīsies atpakaļ,
12 Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”
Bet tai vietā, kurp tie viņu aizveduši, viņš mirs un šo zemi viņš vairs neredzēs.
13 “Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo, àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́ tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.
Vai tam, kas savu namu uztaisa ar netaisnību un savas istabas ar viltu, kas savam tuvākam liek velti strādāt, un tam nedod savu algu,
14 Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀, ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’ A ó sì fi igi kedari bò ó, a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
Kas domā: es sev uztaisīšu augstu namu un plašas istabas, un liek sev logus izcirst un ar ciedru kokiem apsegt un ar sarkanumu apsvaidīt.
15 “Ìwọ ó ha jẹ ọba kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari? Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu? Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo, nítorí náà ó dára fún un.
Vai tu domā valdīt, tādēļ ka tu ar ciedru kokiem greznojies? Vai tavs tēvs neēda un nedzēra un darīja tiesu un taisnību? Tad viņam labi klājās.
16 Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní, ohun gbogbo sì dára fún un. Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?” ni Olúwa wí.
Viņš izdeva tiesu nabagam un bēdīgam, tad viņam labi klājās. Vai tas nav mani atzīt? saka Tas Kungs.
17 “Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ wà lára èrè àìṣòótọ́ láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”
Bet tavas acis un tava sirds uz citu neskatās kā vien mantu krāt un nenoziedzīgas asinis izliet, apspiest un darīt varas darbu.
18 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda: “Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’ Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’
Tādēļ, tā saka Tas Kungs par Jojaķimu, Josijas, Jūda ķēniņa dēlu: par to nevaidēs: vai, mans brāli! Vai, mana māsa! par to nevaidēs: vai, kungs! Vai, cienīgais.
19 A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.”
Bet kā ēzeli aprok, tā viņu apraks, un viņš taps rauts un izmests tālu no Jeruzālemes vārtiem.
20 “Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta, kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani, kí o kígbe sókè láti Abarimu, nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.
Kāp uz Lībanu un sauc un pacel savu balsi Basanā un brēc no Abarima, jo visi tavi mīluļi ir satriekti.
21 Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu, ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’ Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ, ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.
Es runāju uz tevi, kad tev vēl labi klājās, bet tu sacīji: es neklausīšu. Tas ir tavs ceļš no pašas jaunības, ka tu Manu balsi neesi klausījis
22 Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ, gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn, nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́ nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.
Vējš aizraus visus tavus ganus, un tavi mīluļi ies cietumā; tad tu tiešām tapsi kaunā un par apsmieklu visas savas blēdības dēļ.
23 Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’ tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari, ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ, ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!
Tu uz Lībanus dzīvo un ciedru kokos taisi ligzdas, kā tev klāsies, kad tev sāpes uzies, mokas, kā dzemdētājai?
24 “Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀.
Tik tiešām kā Es dzīvoju, saka Tas Kungs: kaut arī Kanija, Jojaķima dēls, Jūda ķēniņš, būtu pie Manas labās rokas spiežamais gredzens, tomēr Es tevi no tejienes aizraušu.
25 Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli.
Un Es tevi nodošu rokā tiem, kas tavu dvēseli meklē, un tiem rokā, priekš kā vaiga tu bīsties, proti Nebukadnecera, Bābeles ķēniņa, un Kaldeju rokā.
26 Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí.
Un Es izmetīšu tevi un tavu māti, kas tevi dzemdējusi, uz citu zemi, kur jūs neesiet dzimuši, un tur jums būs jāmirst.
27 Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”
Un tai zemē, kurp viņu dvēselei gribēsies atpakaļ griezties, turp tie neatgriezīsies.
28 Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo, ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́? Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.
Vai šis vīrs Kanija ir viens nieka sadauzāms pods, jeb vai viņš trauks, kas nevienam nepatīk? Kāpēc viņš un viņa dzimums atmesti uz to zemi, ko tie nepazīst?
29 Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Ak zeme, zeme, zeme! Klausi Tā Kunga vārdu!
30 Báyìí ni Olúwa wí: “Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ, ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀; nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere, èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”
Tā saka Tas Kungs: pieraksti šo vīru par neauglīgu, par vīru, kam savu mūžu labi neizdosies. Jo nevienam no viņa dzimuma labi neklāsies, kas varētu sēdēt uz Dāvida goda krēsla un turpmāk valdīt pār Jūdu.

< Jeremiah 22 >