< Jeremiah 22 >

1 Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀:
Näin sanoo Herra: "Mene alas Juudan kuninkaan linnaan ja puhu siellä tämä sana;
2 ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí.
sano: Kuule Herran sana, sinä Juudan kuningas, joka istut Daavidin valtaistuimella, sinä ja sinun palvelijasi ja kansasi, jotka käytte sisälle näistä porteista.
3 Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí.
Näin sanoo Herra: Tehkää oikeus ja vanhurskaus ja pelastakaa ryöstetty sortajan kädestä; muukalaiselle, orvolle ja leskelle älkää tehkö vääryyttä ja väkivaltaa älkääkä vuodattako viatonta verta tässä paikassa.
4 Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
Sillä jos te teette tämän sanan mukaan, niin tulee tämän linnan porteista sisälle, ajaen vaunuilla ja hevosilla, kuninkaita, jotka istuvat Daavidin valtaistuimella, tulee kuningas ynnä hänen palvelijansa ja kansansa.
5 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’”
Mutta jos te ette kuule näitä sanoja, niin minä vannon itse kauttani, sanoo Herra, että tämä linna on tuleva raunioiksi.
6 Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi, gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni, dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀, àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.
Sillä näin sanoo Herra Juudan kuninkaan linnasta: Sinä olet minulle Gilead, olet Libanonin huippu; mutta totisesti, minä teen sinut erämaaksi, asumattomiksi kaupungeiksi.
7 Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀, wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀, wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.
Minä vihin hävittäjät sinua vastaan, kunkin aseinensa, ja he hakkaavat maahan sinun valiosetrisi ja heittävät ne tuleen.
8 “Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’
Monet kansat kulkevat tämän kaupungin ohitse ja kysyvät toinen toiseltansa: 'Miksi on Herra tehnyt näin tälle suurelle kaupungille?'
9 Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’”
Ja siihen vastataan: 'Siksi, että he hylkäsivät Herran, Jumalansa, liiton ja kumarsivat muita jumalia ja palvelivat niitä'.
10 Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú nítorí kì yóò padà wá mọ́ tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.
Älkää kuollutta itkekö älkääkä häntä surkutelko, vaan itkekää tuota poiskulkevaa, sillä hän ei enää palaja eikä saa nähdä synnyinmaatansa.
11 Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́.
Sillä näin sanoo Herra Sallumista, Joosian pojasta, Juudan kuninkaasta, joka tuli kuninkaaksi isänsä Joosian sijaan ja joka on vaeltanut pois tästä paikasta: Hän ei enää tänne palaja;
12 Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”
vaan mihin hänet on vangiksi viety, sinne hän kuolee eikä näe enää tätä maata.
13 “Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo, àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́ tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.
Voi häntä, joka ei vanhurskaudella taloansa rakenna eikä yläsalejansa oikeudella; joka ilmaiseksi teettää työtä lähimmäisellään eikä anna hänelle hänen palkkaansa;
14 Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀, ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’ A ó sì fi igi kedari bò ó, a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
joka sanoo: 'Minä rakennan itselleni tilavan talon ja avarat yläsalit', joka hakkauttaa siihen ikkunat, laudoittaa sen setripuulla ja maalauttaa punavärillä.
15 “Ìwọ ó ha jẹ ọba kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari? Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu? Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo, nítorí náà ó dára fún un.
Siksikö sinä olet kuningas, että sinulla on into setripuuhun? Eikö sinun isäsikin syönyt ja juonut ja kuitenkin ollut oikeuden ja vanhurskauden tekijä? Ja silloin hänen kävi hyvin.
16 Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní, ohun gbogbo sì dára fún un. Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?” ni Olúwa wí.
Hän hankki oikeuden kurjalle ja köyhälle; silloin kaikki kävi hyvin. Eikö tämä juuri ole minun tuntemistani, sanoo Herra?
17 “Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ wà lára èrè àìṣòótọ́ láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”
Mutta sinun silmäsi ja sydämesi eivät pyydä muuta kuin omaa voittoasi, muuta kuin vuodattaa viatonta verta ja harjoittaa väkivaltaa ja sortoa.
18 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda: “Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’ Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’
Sentähden, näin sanoo Herra Joojakimista, Joosian pojasta, Juudan kuninkaasta: Ei hänelle pidetä valittajaisia eikä huudeta: 'Voi veljeni! Voi sisareni!' Ei hänelle pidetä valittajaisia eikä huudeta: 'Voi herraamme! Voi hänen loistoansa!'
19 A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.”
Hänet haudataan niinkuin aasi haudataan: raahataan pois ja viskataan Jerusalemin porttien tuolle puolen.
20 “Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta, kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani, kí o kígbe sókè láti Abarimu, nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.
Nouse Libanonille ja huuda, korota äänesi Baasanissa. Huuda Abarimin vuorilta, sillä kaikki sinun rakastajasi ovat murskaksi muserretut.
21 Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu, ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’ Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ, ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.
Minä puhuin sinulle onnesi päivinä. Sinä vastasit: 'En tahdo kuulla'. Tämä on ollut sinun tapasi nuoruudestasi asti: et ole kuullut minun ääntäni.
22 Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ, gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn, nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́ nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.
Myrskytuuli on kaitseva kaikkia sinun kaitsijoitasi, ja sinun rakastajasi menevät vankeuteen; silloin sinä saat häpeän ja pilkan kaiken pahuutesi tähden.
23 Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’ tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari, ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ, ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!
Sinä, joka asut Libanonissa, pidät pesääsi setripuissa: kuinka olet voihkiva, kun sinulle tuskat tulevat, kouristus niinkuin synnyttäväiselle!
24 “Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀.
Niin totta kuin minä elän, sanoo Herra: olkoon Konja, Joojakimin poika, Juudan kuningas, vaikka sinettisormus minun oikeassa kädessäni-siitäkin minä sinut repäisen irti.
25 Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli.
Ja minä annan sinut niiden käsiin, jotka etsivät sinun henkeäsi, niiden käsiin, joita sinä kauhistut: Nebukadressarin, Baabelin kuninkaan, ja kaldealaisten käsiin.
26 Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí.
Ja minä heitän sinut ja sinun äitisi, joka on sinut synnyttänyt, vieraalle maalle, missä te ette ole syntyneet, ja sinne te kuolette.
27 Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”
Mutta maahan, jonne heidän sielunsa halajaa palata, sinne he eivät palaa.
28 Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo, ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́? Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.
Onko sitten tämä mies, Konja, arvoton, rikottu astia, kelvoton kapine? Minkätähden on hänet ja hänen jälkeläisensä heitetty pois, viskattu pois-maahan, jota eivät tunne?
29 Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Maa, maa, maa! Kuule Herran sana!
30 Báyìí ni Olúwa wí: “Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ, ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀; nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere, èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”
Näin sanoo Herra: Merkitkää tämä mies lapsettomaksi, mieheksi, jolla ei elinpäivinänsä onnea ole. Sillä ei kenellekään hänen jälkeläisistänsä sitä onnea tule, että istuisi Daavidin valtaistuimella ja hallitsi vielä Juudaa."

< Jeremiah 22 >