< Jeremiah 20 >

1 Ní ìgbà tí àlùfáà Paṣuri ọmọkùnrin Immeri olórí àwọn ìjòyè tẹmpili Olúwa gbọ́ tí Jeremiah ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nǹkan wọ̀nyí.
И услыша Пасхор сын Еммеров священник, иже поставлен бе началник в дому Господни, Иеремию пророчествующа словеса сия:
2 Ó mú kí wọ́n lù wòlíì Jeremiah, kí wọ́n sì fi sínú túbú tí ó wà ní òkè ẹnu-ọ̀nà ti Benjamini ní tẹmpili Olúwa.
и удари Пасхор Иеремию пророка и вверже его в кладу, яже бе во вратех Вениаминих вышних в дому Господни.
3 Ní ọjọ́ kejì tí Paṣuri tú u sílẹ̀ nínú túbú, Jeremiah sì sọ fún un wí pé, “Orúkọ Olúwa fun ọ kì í ṣe Paṣuri bí kò ṣe ìpayà.
Бывшу же утру, изведе Пасхор Иеремию от клады. И рече к нему Иеремиа: не Пасхор нарече (Господь) имя твое, но Преселника Отвсюду.
4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ. Èmi yóò mú ọ di ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ sí ara rẹ àti sí gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Ní ojú ara rẹ, ìwọ yóò sì rí tí wọ́n ṣubú nípa idà ọ̀tá wọn. Èmi yóò fi gbogbo àwọn ọ̀tá Juda lé ọba Babeli lọ́wọ́, òun yóò sì kó wọn lọ sí Babeli tàbí kí ó pa wọ́n.
Понеже сия глаголет Господь: се, Аз дам тя в преселение и всех другов твоих: и падут мечем враг своих, и очи твои узрят, и тебе и всего Иуду дам в руки царя Вавилонска, и преведут их в Вавилон и побиют их мечьми.
5 Èmi yóò jọ̀wọ́ gbogbo ọrọ̀ inú ìlú yìí fún ọ̀tá wọn. Gbogbo ìní wọ́n gbogbo ọlá ọba Juda. Wọn yóò sì ru ìkógun lọ sí Babeli.
И дам всю силу града сего и вся труды его и вся сокровища царя Иудина дам в руки врагов его, и расхитят их и возмут и отведут в Вавилон.
6 Àti ìwọ Paṣuri, gbogbo ènìyàn inú ilé rẹ yóò sì lọ ṣe àtìpó ní Babeli. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí, tí wọn yóò sì sin ọ́ síbẹ̀, ìwọ àti gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tí ìwọ ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún.”
Ты же, Пасхор, и вси обитателие дому твоего, отидете во пленение, и в Вавилон приидеши и тамо умреши, тамо же и погребешися ты и вси друзие твои, имже пророчествовал еси лжу.
7 Olúwa, o tàn mí jẹ́, o sì ṣẹ́gun. Mo di ẹni ẹ̀gàn ní gbogbo ọjọ́, gbogbo ènìyàn fi mí ṣẹlẹ́yà.
Прельстил мя еси, Господи, и прельщен есмь, креплейший мене еси и превозмогл еси: бых в посмех весь день, вси ругаются мне.
8 Nígbàkígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, èmi sì kígbe síta èmi á sọ nípa ipá àti ìparun. Nítorí náà, ọ̀rọ̀ Olúwa ti mú àbùkù àti ẹ̀gàn bá mi ni gbogbo ìgbà.
Понеже горьким словом моим посмеюся, отвержение и бедность наведу, яко бысть в поношение мне слово Господне и в посмех весь день.
9 Ṣùgbọ́n bí mo bá sọ pé, “Èmi kì yóò dárúkọ rẹ tàbí sọ nípa orúkọ rẹ̀ mọ́, ọ̀rọ̀ rẹ̀ ń bẹ bi iná tí ń jó nínú mi nínú egungun mi, agara dá mi ní inú mi nítòótọ́ èmi kò lè ṣe é.
И рекох: не воспомяну имене Господня, ниже возглаголю ктому во имя Его. И бысть в сердцы моем яко огнь горящь, палящь в костех моих, и разслабех отвсюду, и не могу носити:
10 Mo gbọ́ sísọ ọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ìbẹ̀rù ni ibi gbogbo. Fi í sùn! Jẹ́ kí a fi sùn! Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ mi ń dúró kí èmi ṣubú, wọ́n sì ń sọ pé, bóyá yóò jẹ́ di títàn, nígbà náà ni àwa yóò borí rẹ̀, àwa yóò sì gba ẹ̀san wa lára rẹ̀.”
слышах бо досадителства многих собравшихся окрест: нападите, нападим нань, вси мужие друзие его: наблюдайте помышление его, аще (како) прельстится, и преможем нань и сотворим отмщение наше ему.
11 Ṣùgbọ́n Olúwa ń bẹ pẹ̀lú mi gẹ́gẹ́ bí akọni ẹlẹ́rù. Nítorí náà, àwọn tí ó ń lépa mi yóò kọsẹ̀, wọn kì yóò sì borí. Wọn yóò kùnà, wọn yóò sì gba ìtìjú púpọ̀. Àbùkù wọn kì yóò sì di ohun ìgbàgbé.
Господь же со мною есть яко борец крепкий: сего ради погнаша и уразумети не могоша: постыдешася зело, яко не разумеша безчестия своего, еже во век не забвено будет.
12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ìwọ tí ó ń dán olódodo wò tí o sì ń ṣe àyẹ̀wò ọkàn àti ẹ̀mí fínní fínní, jẹ́ kí èmi kí ó rí ìgbẹ̀san rẹ lórí wọn, nítorí ìwọ ni mo gbé ara mi lé.
И Ты, Господи сил, искушаяй праведная, ведаяй утробы и сердца, (молютися, ) да вижду мщение Твое на них, Тебе бо открых прю мою.
13 Kọrin sí Olúwa! Fi ìyìn fún Olúwa! Ó gba ẹ̀mí àwọn aláìní lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.
Пойте Господу, хвалите Господа, яко избави душу убогаго от руки лукавых.
14 Ègbé ni fún ọjọ́ tí a bí mi! Kí ọjọ́ tí ìyá mi bí mi má ṣe di ti ìbùkún.
Проклят день, в оньже родихся: день, в оньже породи мя мати моя, да не будет благословен.
15 Ègbé ni fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún baba mi, tí ó mú kí ó yọ̀, tí ó sì sọ wí pé, “A bí ọmọ kan fún ọ—ọmọkùnrin!”
Проклят муж, иже возвести отцу моему, рекий: родися тебе отрок мужеск, и яко радостию возвесели его.
16 Kí ọkùnrin náà dàbí ìlú tí Olúwa gbàkóso lọ́wọ́ rẹ̀ láìkáàánú Kí o sì gbọ́ ariwo ọ̀fọ̀ ní àárọ̀, ariwo ogun ní ọ̀sán.
Да будет человек той якоже гради, яже преврати Господь яростию и не раскаяся: да слышит вопль заутра и рыдание во время полуденное:
17 Nítorí kò pa mí nínú, kí ìyá mi sì dàbí títóbi ibojì mi, kí ikùn rẹ̀ sì di títí láé.
яко не убил мене в ложеснах матере, и была бы мне мати моя гроб мой и ложесна зачатия вечнаго.
18 Èéṣe tí mo jáde nínú ikùn, láti rí wàhálà àti ọ̀fọ̀ àti láti parí ayé mi nínú ìtìjú?
Вскую изыдох из ложесн, да вижду труды и болезни, и скончашася в постыдении дние мои?

< Jeremiah 20 >