< Jeremiah 20 >

1 Ní ìgbà tí àlùfáà Paṣuri ọmọkùnrin Immeri olórí àwọn ìjòyè tẹmpili Olúwa gbọ́ tí Jeremiah ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nǹkan wọ̀nyí.
And Phassur, the sone of Emyner, the preest, that was ordeyned prince in the hous of the Lord, herde Jeremye profesiynge these wordis.
2 Ó mú kí wọ́n lù wòlíì Jeremiah, kí wọ́n sì fi sínú túbú tí ó wà ní òkè ẹnu-ọ̀nà ti Benjamini ní tẹmpili Olúwa.
And Phassur smoot Jeremye, the profete, and sente hym in to the stockis, that weren in the hiyere yate of Beniamyn, in the hous of the Lord.
3 Ní ọjọ́ kejì tí Paṣuri tú u sílẹ̀ nínú túbú, Jeremiah sì sọ fún un wí pé, “Orúkọ Olúwa fun ọ kì í ṣe Paṣuri bí kò ṣe ìpayà.
And whanne it was cleer in the morewe, Phassur ledde Jeremye out of the stockis. And Jeremye seide to hym, The Lord clepide not Phassur thi name, but Drede on ech side.
4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ. Èmi yóò mú ọ di ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ sí ara rẹ àti sí gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Ní ojú ara rẹ, ìwọ yóò sì rí tí wọ́n ṣubú nípa idà ọ̀tá wọn. Èmi yóò fi gbogbo àwọn ọ̀tá Juda lé ọba Babeli lọ́wọ́, òun yóò sì kó wọn lọ sí Babeli tàbí kí ó pa wọ́n.
For the Lord seith these thingis, Lo! Y schal yyue thee and alle thi freendis in to drede, and thei schulen falle doun bi the swerd of her enemyes; and thin iyen schulen se; and Y schal yyue al Juda in the hond of the king of Babiloyne, and he schal lede hem ouer in to Babiloyne, and he schal smyte hem bi swerd.
5 Èmi yóò jọ̀wọ́ gbogbo ọrọ̀ inú ìlú yìí fún ọ̀tá wọn. Gbogbo ìní wọ́n gbogbo ọlá ọba Juda. Wọn yóò sì ru ìkógun lọ sí Babeli.
And Y schal yyue al the catel of this citee, and al the trauel therof, and al the prijs; and Y schal yyue alle the tresours of the kingis of Juda in the hond of her enemyes; and thei schulen rauysche tho, and schulen take, and lede forth in to Babiloyne.
6 Àti ìwọ Paṣuri, gbogbo ènìyàn inú ilé rẹ yóò sì lọ ṣe àtìpó ní Babeli. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí, tí wọn yóò sì sin ọ́ síbẹ̀, ìwọ àti gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tí ìwọ ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún.”
Forsothe thou, Phassur, and alle the dwelleris of thin hous, schulen go in to caitifte; and thou schalt come in to Babiloyne, and thou schalt die there; and thou schalt be biried there, thou and alle thi freendis, to whiche thou profesiedist a leesyng.
7 Olúwa, o tàn mí jẹ́, o sì ṣẹ́gun. Mo di ẹni ẹ̀gàn ní gbogbo ọjọ́, gbogbo ènìyàn fi mí ṣẹlẹ́yà.
Lord, thou disseyuedist me, and Y am disseyued; thou were strongere than Y, and thou haddist the maistrie; Y am maad in to scorn al dai.
8 Nígbàkígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, èmi sì kígbe síta èmi á sọ nípa ipá àti ìparun. Nítorí náà, ọ̀rọ̀ Olúwa ti mú àbùkù àti ẹ̀gàn bá mi ni gbogbo ìgbà.
Alle men bymowen me, for now a while ago Y speke criynge wickidnesse, and Y criede distriynge. And the word of the Lord is maad to me in to schenschip, and in to scorn al dai.
9 Ṣùgbọ́n bí mo bá sọ pé, “Èmi kì yóò dárúkọ rẹ tàbí sọ nípa orúkọ rẹ̀ mọ́, ọ̀rọ̀ rẹ̀ ń bẹ bi iná tí ń jó nínú mi nínú egungun mi, agara dá mi ní inú mi nítòótọ́ èmi kò lè ṣe é.
And Y seide, Y schal not haue mynde on hym, and Y schal no more speke in his name. And the word of the Lord was maad, as fier swalynge in myn herte, and cloosid in my boonys; and Y failide, not suffryng to bere.
10 Mo gbọ́ sísọ ọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ìbẹ̀rù ni ibi gbogbo. Fi í sùn! Jẹ́ kí a fi sùn! Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ mi ń dúró kí èmi ṣubú, wọ́n sì ń sọ pé, bóyá yóò jẹ́ di títàn, nígbà náà ni àwa yóò borí rẹ̀, àwa yóò sì gba ẹ̀san wa lára rẹ̀.”
For Y herde dispisyngis of many men, and drede in cumpas, Pursue ye, and pursue we hym, of alle men that weren pesible to me, and kepynge my side; if in ony maner he be disseyued, and we haue the maistrie ayens hym, and gete veniaunce of hym.
11 Ṣùgbọ́n Olúwa ń bẹ pẹ̀lú mi gẹ́gẹ́ bí akọni ẹlẹ́rù. Nítorí náà, àwọn tí ó ń lépa mi yóò kọsẹ̀, wọn kì yóò sì borí. Wọn yóò kùnà, wọn yóò sì gba ìtìjú púpọ̀. Àbùkù wọn kì yóò sì di ohun ìgbàgbé.
Forsothe the Lord as a stronge werriour is with me, therfor thei that pursuen me schulen falle, and schulen be sijk; and thei schulen be schent greetli, for thei vndurstoden not euerlastynge schenschip, that schal neuere be don awei.
12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ìwọ tí ó ń dán olódodo wò tí o sì ń ṣe àyẹ̀wò ọkàn àti ẹ̀mí fínní fínní, jẹ́ kí èmi kí ó rí ìgbẹ̀san rẹ lórí wọn, nítorí ìwọ ni mo gbé ara mi lé.
And thou, Lord of oostis, the preuere of a iust man, which seest the reynes and herte, Y biseche, se Y thi veniaunce of hem; for Y haue schewid my cause to thee.
13 Kọrin sí Olúwa! Fi ìyìn fún Olúwa! Ó gba ẹ̀mí àwọn aláìní lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.
Synge ye to the Lord, herie ye the Lord, for he delyueride the soule of a pore man fro the hond of yuel men.
14 Ègbé ni fún ọjọ́ tí a bí mi! Kí ọjọ́ tí ìyá mi bí mi má ṣe di ti ìbùkún.
Cursid be the dai where ynne Y was borun, the dai where ynne my modir childide me, be not blessid.
15 Ègbé ni fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún baba mi, tí ó mú kí ó yọ̀, tí ó sì sọ wí pé, “A bí ọmọ kan fún ọ—ọmọkùnrin!”
Cursid be the man, that telde to my fadir, and seide, A knaue child is borun to thee, and made hym glad as with ioye.
16 Kí ọkùnrin náà dàbí ìlú tí Olúwa gbàkóso lọ́wọ́ rẹ̀ láìkáàánú Kí o sì gbọ́ ariwo ọ̀fọ̀ ní àárọ̀, ariwo ogun ní ọ̀sán.
Thilke man be as the citees ben, whiche the Lord distriede, and it repentide not hym;
17 Nítorí kò pa mí nínú, kí ìyá mi sì dàbí títóbi ibojì mi, kí ikùn rẹ̀ sì di títí láé.
he that killide not me fro the wombe, here cry eerli, and yellynge in the tyme of myddai; that my modir were a sepulcre to me, and hir wombe were euerlastinge conseyuyng.
18 Èéṣe tí mo jáde nínú ikùn, láti rí wàhálà àti ọ̀fọ̀ àti láti parí ayé mi nínú ìtìjú?
Whi yede Y out of the wombe, that Y schulde se trauel and sorewe, and that mi daies schulen be waastid in schenschipe?

< Jeremiah 20 >