< Jeremiah 20 >
1 Ní ìgbà tí àlùfáà Paṣuri ọmọkùnrin Immeri olórí àwọn ìjòyè tẹmpili Olúwa gbọ́ tí Jeremiah ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nǹkan wọ̀nyí.
And Pashhur son of Immer the priest—who [is] also overseer, leader in the house of YHWH—hears Jeremiah prophesying these things,
2 Ó mú kí wọ́n lù wòlíì Jeremiah, kí wọ́n sì fi sínú túbú tí ó wà ní òkè ẹnu-ọ̀nà ti Benjamini ní tẹmpili Olúwa.
and Pashhur strikes Jeremiah the prophet, and puts him in the stocks that [are] by the Upper Gate of Benjamin, that [is] by the house of YHWH.
3 Ní ọjọ́ kejì tí Paṣuri tú u sílẹ̀ nínú túbú, Jeremiah sì sọ fún un wí pé, “Orúkọ Olúwa fun ọ kì í ṣe Paṣuri bí kò ṣe ìpayà.
And it comes to pass on the next day, that Pashhur brings Jeremiah out from the stocks, and Jeremiah says to him, “YHWH has not called your name Pashhur, but Terror on Every Side.
4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ. Èmi yóò mú ọ di ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ sí ara rẹ àti sí gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Ní ojú ara rẹ, ìwọ yóò sì rí tí wọ́n ṣubú nípa idà ọ̀tá wọn. Èmi yóò fi gbogbo àwọn ọ̀tá Juda lé ọba Babeli lọ́wọ́, òun yóò sì kó wọn lọ sí Babeli tàbí kí ó pa wọ́n.
For thus said YHWH: Behold, I am making you for a fear to yourself, And to all loving you, And they have fallen by the sword of their enemies, and your eyes are beholding, And all Judah I give into the hand of the king of Babylon, And he has removed them to Babylon, And he has struck them with the sword.
5 Èmi yóò jọ̀wọ́ gbogbo ọrọ̀ inú ìlú yìí fún ọ̀tá wọn. Gbogbo ìní wọ́n gbogbo ọlá ọba Juda. Wọn yóò sì ru ìkógun lọ sí Babeli.
And I have given all the strength of this city, And all its labor, and all its precious things, Indeed, I give all the treasures of the kings of Judah into the hand of their enemies, And they have spoiled them, and taken them, And have brought them into Babylon.
6 Àti ìwọ Paṣuri, gbogbo ènìyàn inú ilé rẹ yóò sì lọ ṣe àtìpó ní Babeli. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí, tí wọn yóò sì sin ọ́ síbẹ̀, ìwọ àti gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tí ìwọ ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún.”
And you, Pashhur, and all dwelling in your house, Go into captivity. And you enter Babylon, And there you die, and there you are buried, You and all loving you, To whom you have prophesied falsely.”
7 Olúwa, o tàn mí jẹ́, o sì ṣẹ́gun. Mo di ẹni ẹ̀gàn ní gbogbo ọjọ́, gbogbo ènìyàn fi mí ṣẹlẹ́yà.
You have persuaded me, O YHWH, and I am persuaded; You have hardened me, and prevail, I have been for a laughter all the day, Everyone is mocking at me,
8 Nígbàkígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, èmi sì kígbe síta èmi á sọ nípa ipá àti ìparun. Nítorí náà, ọ̀rọ̀ Olúwa ti mú àbùkù àti ẹ̀gàn bá mi ni gbogbo ìgbà.
Because from the time I speak I cry out, I shout, “Violence and destruction!” For the word of YHWH has been to me For reproach and for derision all the day.
9 Ṣùgbọ́n bí mo bá sọ pé, “Èmi kì yóò dárúkọ rẹ tàbí sọ nípa orúkọ rẹ̀ mọ́, ọ̀rọ̀ rẹ̀ ń bẹ bi iná tí ń jó nínú mi nínú egungun mi, agara dá mi ní inú mi nítòótọ́ èmi kò lè ṣe é.
And I said, “I do not mention Him, Nor do I speak anymore in His Name,” And it has been in my heart As a burning fire shut up in my bones, And I have been weary of containing, And I am not able.
10 Mo gbọ́ sísọ ọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ìbẹ̀rù ni ibi gbogbo. Fi í sùn! Jẹ́ kí a fi sùn! Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ mi ń dúró kí èmi ṣubú, wọ́n sì ń sọ pé, bóyá yóò jẹ́ di títàn, nígbà náà ni àwa yóò borí rẹ̀, àwa yóò sì gba ẹ̀san wa lára rẹ̀.”
For I have heard the evil report of many, “Fear [is] all around!” “Declare, and we declare it!” All my allies are watching [for] my halting, “Perhaps he is enticed, and we prevail over him, And we take our vengeance on him.”
11 Ṣùgbọ́n Olúwa ń bẹ pẹ̀lú mi gẹ́gẹ́ bí akọni ẹlẹ́rù. Nítorí náà, àwọn tí ó ń lépa mi yóò kọsẹ̀, wọn kì yóò sì borí. Wọn yóò kùnà, wọn yóò sì gba ìtìjú púpọ̀. Àbùkù wọn kì yóò sì di ohun ìgbàgbé.
And YHWH [is] with me, as a mighty, awesome One, Therefore my persecutors stumble and do not prevail, They have been exceedingly ashamed, For they have not acted wisely, Continuous confusion is not forgotten.
12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ìwọ tí ó ń dán olódodo wò tí o sì ń ṣe àyẹ̀wò ọkàn àti ẹ̀mí fínní fínní, jẹ́ kí èmi kí ó rí ìgbẹ̀san rẹ lórí wọn, nítorí ìwọ ni mo gbé ara mi lé.
And, O YHWH of Hosts, trier of the righteous, Beholder of reins and heart, I see Your vengeance on them, For I have revealed my cause to you.
13 Kọrin sí Olúwa! Fi ìyìn fún Olúwa! Ó gba ẹ̀mí àwọn aláìní lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.
Sing to YHWH, praise YHWH, For He has delivered the soul of the needy From the hand of evildoers.
14 Ègbé ni fún ọjọ́ tí a bí mi! Kí ọjọ́ tí ìyá mi bí mi má ṣe di ti ìbùkún.
Cursed [is] the day in which I was born, The day that my mother bore me, Let it not be blessed!
15 Ègbé ni fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún baba mi, tí ó mú kí ó yọ̀, tí ó sì sọ wí pé, “A bí ọmọ kan fún ọ—ọmọkùnrin!”
Cursed [is] the man who bore tidings [to] my father, Saying, “A male child has been born to you,” Making him very glad!
16 Kí ọkùnrin náà dàbí ìlú tí Olúwa gbàkóso lọ́wọ́ rẹ̀ láìkáàánú Kí o sì gbọ́ ariwo ọ̀fọ̀ ní àárọ̀, ariwo ogun ní ọ̀sán.
Then that man has been as the cities, That YHWH overthrew, and did not relent, And he has heard a cry in the morning, And a shout at noontime.
17 Nítorí kò pa mí nínú, kí ìyá mi sì dàbí títóbi ibojì mi, kí ikùn rẹ̀ sì di títí láé.
Because he has not put me to death from the womb, And my mother is to me—my grave, And her womb [is] a perpetual pregnancy.
18 Èéṣe tí mo jáde nínú ikùn, láti rí wàhálà àti ọ̀fọ̀ àti láti parí ayé mi nínú ìtìjú?
Why [is] this? I have come out from the womb To see labor and sorrow, Indeed, my days are consumed in shame!