< Jeremiah 2 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
RAB bana şöyle seslendi:
2 “Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
“Git, şunları Yeruşalim halkına duyur. RAB diyor ki, “‘Gençliğindeki bağlılığını, Gelinliğindeki sevgini, Çölde, ekilmemiş toprakta Beni nasıl izlediğini anımsıyorum.
3 Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
İsrail RAB için kutsal bir halk, Hasadının ilk ürünüydü. Onu yeren herkes suçlu sayılır, Başına felaket gelirdi’” diyor RAB.
4 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
RAB'bin sözünü dinleyin, Ey Yakup soyu, İsrail'in bütün boyları!
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
RAB diyor ki, “Atalarınız bende ne haksızlık buldular da Benden uzaklaştılar? Değersiz putları izleyerek Kendileri de değersiz oldular.
6 Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
‘Mısır'dan bizi çıkaran, Çölde, çukurlarla dolu çorak toprakta, Koyu karanlıkta kalan kurak toprakta, Kimsenin geçmediği, Kimsenin yaşamadığı toprakta Bize yol gösteren RAB nerede?’ diye sormadılar.
7 Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
Meyvesini, en iyi ürününü yiyesiniz diye Sizi verimli bir ülkeye getirdim. Oysa siz gelir gelmez ülkemi kirlettiniz, Mülkümü iğrenç bir yere çevirdiniz.
8 Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
Kâhinler, ‘RAB nerede?’ diye sormadılar, Kutsal Yasa uzmanları beni tanımadılar, Yöneticiler bana başkaldırdılar; Peygamberler Baal adına peygamberlik edip İşe yaramaz putların ardınca gittiler.
9 “Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
“Bu yüzden sizden yine davacı olacağım” diyor RAB, “Torunlarınızdan da davacı olacağım.
10 Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
Gidin de Kittim kıyılarına bakın! Kedar ülkesine adam gönderip iyice inceleyin, Hiç böyle bir şey oldu mu, olmadı mı görün.
11 Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
Hiçbir ulus ilahlarını değiştirdi mi? –Ki onlar zaten tanrı değildirler– Ama benim halkım görkemini İşe yaramaz putlara değişti.
12 Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
Ey gökler, şaşın buna, Tir tir titreyin, şaşakalın” diyor RAB.
13 “Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
“Çünkü halkım iki kötülük yaptı: Beni, diri suların pınarını bıraktı, Kendilerine sarnıçlar, Su tutmayan çatlak sarnıçlar kazdılar.
14 Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
İsrail uşak mı? Köle olarak mı doğdu? Öyleyse neden gümbür gümbür kükreyen Genç aslanlara av oldu? Ülkeyi viraneye çevirdiler, Kentler yerle bir edildi, kimsesiz bırakıldı!
15 Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
16 Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
Nof ve Tahpanhes halkı Kafanı kırdı.
17 Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
Seni yolda yürüten Tanrın RAB'bi bırakmakla Başına bunları getirdin.
18 Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
Şimdi Şihor suyundan içmek için Mısır'a gitmek size yarar sağlar mı? Fırat suyundan içmek için Asur'a gitmek size ne sağlar?
19 Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Seni kendi kötülüğün yola getirecek, Dönekliğin seni paylayacak. Tanrın RAB'bi bırakmanın, Benden korkmamanın Ne kadar kötü, ne kadar acı olduğunu gör de anla.” Rab, Her Şeye Egemen RAB böyle diyor.
20 “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
“Boyunduruğunu çok önce kırdın, Bağlarını kopardın. ‘Kulluk etmeyeceğim’ dedin. Gerçekten de her yüksek tepede, Her bol yapraklı ağacın altında Fahişe gibi yatıp kalktın.
21 Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
Oysa ben seni en iyi cinsten Seçme bir asma olarak dikmiştim. Nasıl oldu da yozlaşıp yabanıl asmaya döndün?
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Çamaşır sodasıyla yıkansan, Bol kül suyu kullansan bile, Suçun önümde yine leke gibi duruyor” Diyor Egemen RAB.
23 “Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
“Öyleyken nasıl, ‘Ben kirlenmedim, Baallar'ı izlemedim’ diyebilirsin? Vadide nasıl davrandığına bak da Ne yaptığını anla. Sen orada burada dolaşan Ayağı tez bir dişi devesin.
24 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
Kösnüyüp havayı koklayan Kıra alışkın yaban eşeğisin. Azgınken kim tutabilir onu? Peşine düşenlerin yorulması gerekmez, Çiftleşme zamanı gelince onu bulurlar.
25 Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
Yalınayak koşmaktan sakın, Susuzluktan boğazını koru. Ama sen, ‘Boş ver! Ben başka ilahları seviyorum, Onları izleyeceğim’ dedin.
26 “Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
“Hırsız yakalandığında nasıl utanırsa, İsrail'in halkı, kralları, önderleri, Kâhinleri, peygamberleri de öyle utanacak.
27 Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
Onlar ağaca, ‘Babamsın’, Taşa, ‘Bizi sen doğurdun’ derler. Çünkü bana yüzlerini değil, Sırtlarını çevirdiler. Ama felakete uğrayınca, ‘Kalk da bizi kurtar’ diye yakarırlar.
28 Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
Hani nerede kendiniz için yaptığınız ilahlar? Felakete uğradığınızda kurtarabiliyorlarsa, Kalkıp gelsinler. Kentlerinin sayısı kadar İlahların var, ey Yahuda halkı.”
29 “Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
“Neden bana dava açıyorsunuz? Hepiniz bana başkaldırdınız” diyor RAB.
30 “Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
“Halkınızı boşuna cezalandırdım, yola gelmediler. Kılıcınız yırtıcı aslan gibi öldürdü peygamberlerinizi.
31 “Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
“Ey siz, bu kuşağın çocukları, RAB'bin sözünü anlayın! Ben İsrail için bir çöl, Kapkaranlık bir ülke mi oldum? Öyleyse halkım neden, ‘Başımıza buyruğuz, Artık sana dönmeyeceğiz’ diyor?
32 Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
Erden kız takılarını, Gelin çeyizini unutabilir mi? Ama halkım sayısız günlerce unuttu beni.
33 Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
Aşkı kovalamakta Ne kadar beceriklisin! Kötü kadınlara bile kendi yöntemlerini öğretebildin.
34 Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
Eteğin suçsuz yoksulların kanıyla lekelenmiş, Oysa ev soyarken yakalamadın onları. Bütün bunlara karşın,
35 ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
‘Ben suçsuzum, Kuşkusuz RAB'bin bana öfkesi dindi’ diyorsun. Ama ‘Günah işlemedim’ dediğin için Yargılayacağım seni.
36 Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
Neden boyuna döneklik yapıp duruyorsun? Asur'da düşkırıklığına uğradığın gibi, Mısır'da da düşkırıklığına uğrayacaksın.
37 Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.
Oradan da ellerin başında çıkacaksın, Çünkü RAB senin güvendiklerini reddetti; Onlardan yarar sağlamayacaksın.”

< Jeremiah 2 >