< Jeremiah 2 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
Og Herrens ord kom til mig, og det lød så:
2 “Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
Gå avsted og rop ut for Jerusalems ører og si: Så sier Herren: Jeg kommer i hu din ungdoms hullskap, dine trolovelsesdagers kjærlighet, hvorledes du fulgte mig i ørkenen, i et land hvor ingen sår.
3 Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
Hellig var Israel for Herren, hans førstegrøde; alle som vilde ete det, måtte bøte, ulykke kom over dem, sier Herren.
4 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
Hør Herrens ord, Jakobs hus og alle ætter av Israels hus!
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
Så sier Herren: Hvad urett har eders fedre funnet hos mig, siden de gikk langt bort fra mig og fulgte de tomme guder og blev selv tomme?
6 Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
Og de sa ikke: Hvor er Herren, som førte oss op fra Egyptens land, som ledet oss i ørkenen, i et land med ødemarker, fullt av kløfter, et land med tørke og dødsskygge, et land der ingen mann har faret, og intet menneske har bodd?
7 Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
Og jeg førte eder inn i et land med fruktbare marker, så I fikk ete av dets frukt og dets gode ting; men da I kom inn, gjorde I mitt land urent og min arv til en vederstyggelighet.
8 Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
Prestene sa ikke: Hvor er Herren? Og de som syslet med loven, kjente mig ikke, og hyrdene falt fra mig, og profetene spådde ved Ba'al og fulgte dem som ikke kan hjelpe.
9 “Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
Derfor vil jeg fremdeles gå i rette med eder, sier Herren; ja, med eders barnebarn vil jeg gå i rette.
10 Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
Dra over til kitteernes øer og se, og send bud til Kedar og gi nøie akt og se om noget sådant er skjedd!
11 Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
Har vel et hedningefolk byttet bort sine guder, enda de ikke er guder? Men mitt folk har byttet bort sin ære mot det som ikke kan hjelpe.
12 Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
Forskrekkes, I himler, over dette, og gys, bli storlig forferdet, sier Herren.
13 “Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
For to onde ting har mitt folk gjort: Mig har de forlatt, kilden med det levende vann, og hugget sig ut brønner, sprukne brønner som ikke holder vann.
14 Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
Er Israel en træl? Er han en hjemmefødt træl? Hvorfor er han blitt røvet?
15 Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
Unge løver brølte mot ham; de lot sin røst høre, og de gjorde hans land til en ørken; hans byer blev opbrent, så ingen bor i dem.
16 Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
Også Memfis' og Tahpenes' barn gjorde din isse skallet.
17 Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
Mon ikke det at du forlot Herren din Gud den tid han vilde lede dig på veien, har voldt dig dette?
18 Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
Og nu, hvorfor tar du veien til Egypten for å drikke Sikors vann? Og hvorfor tar du veien til Assyria for å drikke elvens vann?
19 Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Din ondskap tukter dig, og dine frafall straffer dig; kjenn da og se at det er ondt og bittert at du forlater Herren din Gud, og at frykt for mig ikke kommer over dig, sier Herren, Israels Gud, hærskarenes Gud.
20 “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
For fra fordums tid brøt du ditt åk, rev du i stykker dine bånd, og du sa: Jeg vil ikke tjene. Men på hver høi bakke og under hvert grønt tre la du dig ned og drev utukt.
21 Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
Og enda hadde jeg plantet dig som en edel ranke, helt igjennem av ekte sæd; hvorledes er du da blitt omskapt for mig til ville skudd av et fremmed vintre?
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
For om du enn vilde tvette dig med pottaske og bruke meget lut, så skulde dog din misgjerning være skitten for mitt åsyn, sier Herren, Israels Gud.
23 “Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
Hvorledes kan du si: Jeg er ikke blitt uren, jeg har ikke gått efter Ba'alene? Se på din vei i dalen! Forstå hvad du har gjort, du lette kamelhoppe som løper hit og dit!
24 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
Lik et villesel som er vant til ørkenen, snapper hun efter været i sin sjels attrå; hennes brynde - hvem kan dempe den? Alle de som søker henne, slipper å løpe sig trette; i hennes måned finner de henne.
25 Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
La ikke din fot bli bar og din strupe bli tørst! Men du sier: Forgjeves! Nei! Jeg elsker fremmede, og efter dem vil jeg gå.
26 “Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
Likesom en tyv må skamme sig når han blir grepet, således må Israels hus skamme sig, de selv, deres konger, deres høvdinger, deres prester og deres profeter,
27 Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
fordi de sier til treet: Du er min far, og til stenen: Du har født mig. For de har vendt ryggen til mig og ikke ansiktet. Men i sin ulykkes tid sier de: Reis dig og hjelp oss!
28 Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
Hvor er da dine guder som du gjorde dig? La dem reise sig, om de kan hjelpe dig i din ulykkes tid! For så mange som dine byer er, så mange er dine guder blitt, Juda!
29 “Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
Hvorfor tretter I med mig? I er alle sammen falt fra mig, sier Herren.
30 “Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
Forgjeves slo jeg eders barn; de tok ikke imot tukt; eders sverd fortærte eders profeter som en ødeleggende løve.
31 “Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
Du onde slekt! Gi akt på Herrens ord! Har jeg vært en ørken for Israel eller et belgmørkt land? Hvorfor sier mitt folk: Vi har gjort oss fri, vi vil ikke mere komme til dig?
32 Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
Mon en jomfru glemmer sitt smykke, en brud sitt belte? Men mitt folk har glemt mig i dager uten tall.
33 Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
Hvor vel vet du ikke å legge din vei for å søke kjærlighet! Derfor har du også vent dine veier til det onde.
34 Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
Det finnes endog blod av uskyldige fattigfolk på dine kjortelfliker; du grep dem ikke i innbrudd, men på grunn av alt dette var det.
35 ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
Og allikevel sier du: Jeg er uskyldig, hans vrede har visselig vendt sig fra mig. Se, jeg vil gå i rette med dig fordi du sier: Jeg har ikke syndet.
36 Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
Hvorfor farer du så meget om og skifter din vei? Også ved Egypten skal du bli til skamme, likesom du blev til skamme ved Assyria.
37 Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.
Også derfra skal du gå ut med hendene på hodet; for Herren har forkastet dem du setter din lit til, og du skal ikke ha nogen lykke med dem.

< Jeremiah 2 >