< Jeremiah 2 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
Majd szóla az Úr nékem, mondván:
2 “Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
Menj el, és kiálts Jeruzsálem füleibe, mondván: Ezt mondja az Úr: Emlékezem reád gyermekkorod ragaszkodására, mátkaságod szeretetére, a mikor követtél engem a pusztában, a még be nem vetett földön.
3 Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
Szent volt Izráel az Úrnak, az ő termésének zsengéje; a kik emésztik vala őt, mind vétkeznek vala, veszedelem támada rájok, azt mondja az Úr.
4 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
Halljátok meg az Úr szavát, Jákób háza és Izráel házának minden nemzetsége.
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
Így szól az Úr: Micsoda hamisságot találtak bennem a ti atyáitok, hogy elidegenedtek tőlem, és hiábavalóság után jártak, és hiábavalókká lettek?
6 Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
Még csak azt sem mondták: Hol van az Úr, a ki felhozott minket Égyiptom földéről, a ki vezérelt minket a pusztában, a kietlen és járatlan földön, a szomjúságnak és a halál árnyékának földén, a melyen nem vonult át ember, és a hol halandó nem lakott?
7 Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
És bevittelek titeket a bőség földébe, hogy annak gyümölcseivel és javaival éljetek; és bementetek, és megfertőztettétek az én földemet, és az én örökségemet útálatossá tevétek.
8 Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
A papok nem mondták: Hol van az Úr? A törvény magyarázói nem ismertek engem, és a pásztorok hűtelenekké lettek hozzám, a próféták pedig a Baál által prófétáltak, és azok után jártak, a kik tehetetlenek.
9 “Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
Azért még perbe szállok veletek, mondja az Úr, és perelni fogok a ti fiaitok fiaival is!
10 Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
Menjetek csak át a Kittim szigeteire, és lássátok meg; és küldjetek Kédárba is és szorgalmasan vizsgálódjatok, és lássátok meg, ha volt-é ott ehhez hasonló?
11 Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
Ha cserélt-é valamely nemzet isteneket? noha azok nem istenek. Az én népem pedig felcserélte az ő dicsőségét tehetetlenséggel!
12 Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
Álmélkodjatok ezen, oh egek, és borzadjatok és rémüljetek meg igen! azt mondja az Úr.
13 “Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
Mert kettős gonoszságot követett el az én népem: Elhagytak engem, az élő vizek forrását, hogy kútakat ássanak magoknak; és repedezett kútakat ástak, a melyek nem tartják a vizet.
14 Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
Szolga-é Izráel, a vagy otthon szülött-é ő? Miért lett prédává?
15 Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
Oroszlánok ordítanak reá, megeresztik hangjokat, és sivataggá teszik földjét; városai szétromboltatnak, lakatlanok.
16 Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
Nóf és Tahpan fiai is betörik koponyádat.
17 Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
Vajjon nem te szerezted-é ezt magadnak? Elhagytad az Urat, a te Istenedet, a mikor vezérelt téged az úton!
18 Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
Most is mi dolgod van néked Égyiptom útjával? Hogy Nilus-vizet igyál? Vagy mi dolgod van néked Assúr útjával? Hogy a folyam vizét igyad?
19 Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
A magad gonoszsága fenyít meg téged, és a te elpártolásod büntet meg téged. Tudd meg hát és lásd meg: mily gonosz és keserves dolog, hogy elhagytad az Urat, a te Istenedet, és hogy nem félsz engemet, ezt mondja az Úr, a Seregeknek Ura.
20 “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
Bizony régóta széttörtem a te igádat, és letéptem köteleidet, és azt mondtad: Nem leszek rabszolga; mindamellett minden magas halmon és minden lombos fa alatt bujkálsz vala te, mint egy parázna.
21 Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
Pedig én úgy plántállak vala el téged, mint nemes szőlővesszőt, mindenestől hűséges magot: mimódon változtál hát nékem idegen szőlőtőnek fattyú hajtásává?
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Még ha lúgban mosakodnál is, vagy szappanodat megsokasítanád is, feljegyezve marad a te álnokságod előttem, mondja az Úr Isten.
23 “Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
Mimódon mondhatnád: Nem undokíttattam meg, nem jártam a Baálok után?! Lásd meg a te útadat a völgyben, ismerd meg csak: mit cselekedtél! Gyorslábú kancza-teve, a mely ide-oda futkos útain.
24 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
Pusztához szokott nőstény vadszamár, a mely érzékiségének kívánságában levegő után kapkod. Gerjedelmét kicsoda csillapíthatja le? Senki ne fáraszsza magát, a ki ezt keresi, megtalálja ezt a maga hónapjában.
25 Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
Tartóztasd meg lábadat a mezítelenségtől, és torkodat a szomjúságtól! És te azt mondod: Hiába, nem lehet! mert idegeneket szeretek, és utánok járok.
26 “Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
A miképen megszégyenül a tolvaj, ha rajtakapják, akképen szégyenül meg Izráel háza: ő maga, az ő királyai, fejedelmei, papjai és prófétái,
27 Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
A kik azt mondják a fának: Te vagy az én atyám! a kőnek pedig: Te szűltél engem! Bizony háttal fordulnak felém és nem arczczal, de nyomorúságuk idején azt mondják majd: Kelj föl és szabadíts meg minket!
28 Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
De hol vannak a te isteneid, a melyeket magadnak készítél? Keljenek fel, ha megszabadíthatnak téged a te nyomorúságod idején; hiszen annyi istened volt, oh Júda, a hány városod!
29 “Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
Miért perlekedtek velem? Mindnyájan hűtelenekké lettetek hozzám, mondja az Úr.
30 “Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
Hiába ostoroztam fiaitokat, a fenyítés nem fogott rajtok; fegyveretek úgy emésztette prófétáitokat, mint pusztító oroszlán.
31 “Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
Oh te nemzetség! Lásd meg az Úr dolgát! A puszta voltam-é én Izráelnek, avagy a setétség földje? Miért mondotta az én népem: Szabadok vagyunk, nem megyünk többé hozzád!
32 Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
Vajjon elfelejtkezik-é a lány az ő ékszereiről; a menyasszony az ő nyaklánczairól? Az én népem pedig számtalan napokon elfelejtett engem!
33 Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
Mit szépíted a te útadat, hogy te szeretetet keresel; holott még a gonoszokat is tanítod a te útaidra!
34 Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
Még ruháid szélén is található szegény, ártatlan emberek vére, nem azért, hogy betörésen kaptad őket, hanem mindamazokért!
35 ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
És azt mondod: Bizonyára ártatlan vagyok, hiszen elfordult tőlem az ő haragja! Ímé, én törvénybe szállok veled, mivelhogy azt mondod: Nem vétkeztem!
36 Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
Mit futkosol oly igen, változtatván útadat? Égyiptom miatt is megszégyenülsz, a mint megszégyenültél Assúr miatt.
37 Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.
Még ettől is elszakadsz s kezeidet fejedre kulcsolod, mert útálja az Úr a te bizodalmasaidat, és nem leszel velök szerencsés.