< Jeremiah 2 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
És lett hozzám az Örökkévaló igéje, mondván:
2 “Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
Menj és hirdesd Jeruzsálem fülei hallatára, mondván: Így szól az Örökkévaló: Megemlékezem számodra ifjúkorod kegyéről, menyasszonykorod szeretetéről, hogy követtél engem a pusztában, be nem vetett földön.
3 Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
Szentség Izrael az Örökkévalónak, termésének zsengéje, mind akik megeszik, bűnbe esnek, veszedelem jön rájuk, úgymond az Örökkévaló.
4 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
Halljátok az Örökkévaló igéjét, Jákob haza, és mind az Izrael házának nemzetségei.
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
Így szól az Örökkévaló: mi jogtalanságot találtak bennem őseitek, hogy eltávolodtak tőlem és jártak a hiábavalóság után és hiábavalókká lettek?
6 Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
És nem mondták: Hol van az Örökkévaló, ki felhozott bennünket Egyiptom országából, ki bennünket vezetett a pusztában, sivatag és gödör földjén, szárazság és sötétség földjén, oly földön, melyen nem ment át senki és ahol ember nem lakott.
7 Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
És elvittelek benneteket termőföld országába, hogy egyétek gyümölcsét és javát; de ti bejöttetek és megtisztátalanítottátok országomat, birtokomat pedig utálattá tettétek.
8 Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
A papok nem mondták, hol van az Örökkévaló, a tan kezelői nem ismertek engem, a pásztorok elpártoltak tőlem, és a próféták a Báalban prófétáltak és nem-használók után jártak.
9 “Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
Ezért egyre pörölök veletek, úgymond az Örökkévaló, és fiaitok fiaival is pörölök.
10 Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
Mert keljetek át a kittimbeliek szigeteire és lássátok, s Kédárba küldjetek és figyeljétek meg nagyon és lássátok, vajon történt-e ilyesmi?
11 Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
Vajon cserélt-e nemzet istent – noha azok nem istenek – népem pedig felcserélte dicsőségét nem használóval!
12 Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
Iszonyodjatok amiatt egek, borzadjatok és irtózzatok nagyon, úgymond az Örökkévaló.
13 “Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
Mert két gonoszságot követett el a népem: engem elhagytak, élő víz forrását, hogy kutakat vájjanak ki maguknak, repedezett kutakat, melyek nem fogják a vizet.
14 Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
Rabszolga-e Izrael, avagy házban szülött-e, miért lett prédává?
15 Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
Ráordítottak oroszlánok, hallatták hangjukat; országát pusztulássá tették, városai felgyújtattak, nincs lakójuk.
16 Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
Nóf és Tachpanchész fiai is zúzzák fejed tetejét.
17 Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
Nemde ezt az hozza rád, hogy elhagytad az Örökkévalót, Istenedet, midőn vezetőd volt az úton!
18 Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
Most pedig mi dolgod van az Egyiptomba való úton, hogy a Síchór vizét igyad? És mi dolgod van az Assúrba való úton, hogy a folyam vizét igyad?
19 Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Megfenyít téged a gonoszságod és elpártolásaid megbüntetnek téged: tudd meg hát és lásd, hogy rossz és keserű az, hogy elhagytad az Örökkévalót, Istenedet, és nincs rajtad az én félelmem, úgymond az Úr, az Örökkévaló, a seregek ura.
20 “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
Mert régtől fogva eltörted igádat, széttépted köteleidet és mondtad: nem szolgálok; mert minden magas dombon és minden zöldellő fa alatt leterülsz, te parázna!
21 Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
Én pedig nemes venyigéül ültettelek, csupa igaz magot; és hogyan változtál át idegen szőlőtő vadhajtásaivá!
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Bizony, ha lúggal mosakodnál és tékozolnád magadra a szappant, folt előttem a te bűnöd, úgymond az Úr, az Örökkévaló.
23 “Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
Hogy mondhatod: nem tisztátalanodtam meg, a Báalok után nem jártam! Lásd utadat a völgyben, ismerd meg mit cselekedtél, gyors kancateve, mely összekuszálja útjait!
24 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
Nőstény vadszamár, szokva a pusztához, lelke vágyában lihegett levegő után, kívánságát ki gátolja meg? Mind a keresői nem fáradnak el, az ő hónapjában megtalálják.
25 Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
Óvd lábadat a meztelenségtől és torkodat a szomjúságtól! De azt mondtad: hiába, nem, mert szeretem az idegeneket és utánuk megyek.
26 “Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
Valamint megszégyenül a tolvaj, midőn rajtakapják. úgy vallott szégyent Izrael háza, ők, királyaik, nagyjaik, papjaik és prófétáik.
27 Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
Azt mondják a fának: atyám vagy, és a kőnek: te szültél bennünket, mert háttal fordultak felém és nem arccal, de veszedelmük idején azt mondják kelj fel és segíts meg bennünket!
28 Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
Hol vannak hát isteneid, melyeket készítettél magadnak? Keljenek fel, vajon megsegítenek-e téged veszedelmed idején! Mert városaid száma szerint vannak a te isteneid, oh Jehúda.
29 “Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
Miért pereltek ellenem? Mindnyájatok elpártoltatok tőlem, úgymond az Örökkévaló.
30 “Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
Hiába vertem fiaitokat, fenyítést nem fogadtak el, megemésztette kardotok prófétáitokat, mint pusztító oroszlán.
31 “Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
Nemzedék ti, lássátok az Örökkévaló igéjét! Vajon puszta voltam-e Izraelnek vagy sötétség országa; miért mondta népem: dacolunk, nem jövünk többé hozzád.
32 Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
Vajon elfelejti-e a hajadon az ő díszét, a menyasszony az ő övét? Népem pedig elfelejtett engem számtalan napokon át.
33 Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
De jól intézed utadat, hogy szerelmet keress ezért a rossz nőket is tanítottad útjaidra.
34 Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
Ruháid szélén is találtatott megölt ártatlan szegényeknek vére, nem betörésen érted őket, hanem mind a helyeken!
35 ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
Azt mondtad: ártatlan vagyok, bizony elfordul tőlem haragja; íme én ítéletre szállok veled, mivelhogy azt mondod: nem vétkeztem.
36 Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
Mit járkálsz oly nagyon megváltoztatva utadat? Egyiptom miatt is meg fogsz szégyenülni, amint megszégyenültél Assúr miatt.
37 Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.
Ettől is kimész kezeiddel fejed fölött: mert megvetette az Örökkévaló a te birodalmadat és nem fogsz velük boldogulni.

< Jeremiah 2 >