< Jeremiah 2 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
Ningĩ ndũmĩrĩri ya Jehova nĩyanginyĩrire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
2 “Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
“Thiĩ ũkaanĩrĩre ũkĩiguagwo nĩ andũ a Jerusalemu, ũmeere atĩrĩ: “‘Nĩndirikanaga ũrĩa weheanĩte kũrĩ niĩ rĩrĩa warĩ mwĩthĩ, na ũrĩa wanyendete rĩrĩa ndakũhikirie na ũkĩnũmĩrĩra kũu werũ-inĩ, tũgĩtuĩkanĩria kũu bũrũri ũcio ũtaahandagwo irio.
3 Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
Isiraeli-rĩ, aatũũrĩte aamũrĩirwo Jehova, arĩ maciaro ma mbere ma magetha make; arĩa othe maamũtambuuraga maatuirwo ahĩtia, nao magĩkinyĩrĩrwo nĩ mwanangĩko,’” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
4 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
Thikĩrĩriai mũigue ndũmĩrĩri ya Jehova, inyuĩ andũ a nyũmba ya Jakubu, inyuĩ inyuothe andũ a mĩhĩrĩga yothe ya nyũmba ya Isiraeli.
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
Jehova ekuuga atĩrĩ: “Nĩ mahĩtia marĩkũ maithe manyu maanyonire namo, atĩ nĩkĩo maandirikire, makĩndaihĩrĩria ũguo? Maarũmĩrĩire mĩhianano ĩtarĩ kĩene, nao ene makĩaga kĩene.
6 Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
Matiigana kũũria atĩrĩ: ‘Jehova arĩ ha, ũrĩa watũrutire bũrũri wa Misiri, agĩtũgereria werũ-inĩ ũtaarĩ kĩndũ, tũkĩgerera bũrũri warĩ wa werũ na iharũrũka, bũrũri ũtoiraga mbura, na warĩ nduma ta ya gĩkuũ, bũrũri ũtaageragĩrwo na ũtaatũũragwo nĩ mũndũ?’
7 Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
Nĩndamũrehire bũrũri mũnoru, nĩguo mũrĩĩage matunda maguo, na mwĩgune na indo ciakuo iria njega. No inyuĩ muokire, mũgĩthaahia bũrũri wakwa na mũgĩtũma igai rĩakwa rĩthũũrwo mũno.
8 Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
Athĩnjĩri-Ngai matiigana kũũria atĩrĩ: ‘Jehova arĩ ha?’ Arĩa marũmbũyagia watho matiigana kũũmenya; atongoria ao nĩmanemeire. Anabii maarathaga mohoro makĩgwetaga Baali, marũmĩrĩire mĩhianano ĩtarĩ kĩene.
9 “Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
“Nĩ ũndũ ũcio nĩngũmũciirithia o rĩngĩ,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga. “Ningĩ nĩngaciirithia ciana cia ciana cianyu.
10 Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
Ringai mũthiĩ hũgũrũrũ-inĩ cia Kitimu mũkerorere, ningĩ mũtũmane gũthiio Kedari gũgatuĩrio wega, muone kana kũrĩ kuoneka ũndũ ta ũyũ:
11 Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
Atĩrĩrĩ, nĩ kũrĩ rũrĩrĩ rũrĩ rwatirika ngai ciaruo, rũkĩgarũrũkĩra ngai ingĩ? (O na harĩa ngai icio itarĩ ngai.) No rĩrĩ, andũ akwa nĩmakũũranĩtie Riiri wao na mĩhianano ĩtarĩ kĩene.
12 Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
Inyuĩ igũrũ-rĩ, makaai nĩ ũndũ wa ũhoro ũcio, inainai mũrĩ na kĩeha kĩnene,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
13 “Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
“Andũ akwa nĩmekĩte mehia meerĩ: Nĩmandirikĩte, o niĩ gĩthima kĩa maaĩ ma muoyo, na makeyenjera marima mangĩ ma maaĩ, namo nĩ marima mamethũkangu, matangĩiga maaĩ.
14 Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
Rĩu-rĩ, anga Isiraeli nĩ ndungata, o mũndũ ũciarĩirwo ũkombo-inĩ? Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte atuĩke mũndũ wa gũtahwo?
15 Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
Mĩrũũthi nĩĩraramĩte; nĩĩmũraramĩire. Nĩyanangĩte bũrũri wake; matũũra make macinĩtwo na mwaki, na magatigwo matarĩ mũndũ.
16 Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
O na andũ a Memufisi, na a Tahapanahesi nĩmagũtiihĩtie, magagwĩkĩra rũhara ruototia rwa mũtwe.
17 Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
Githĩ tiwe mwene wĩrehereire maũndũ maya nĩ ũndũ wa gũtirika Jehova Ngai waku, o rĩrĩa we aagũtongoragia na njĩra ĩrĩa wageraga?
18 Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
Rĩu-rĩ, nĩ kĩĩ gĩgũtũma ũcooke bũrũri wa Misiri ũkanyue maaĩ ma Shihoru? Na ningĩ-rĩ, ũgũthiĩ Ashuri nĩkĩ, ũkanyue maaĩ ma Rũũĩ rwa Farati?
19 Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Waganu waku nĩguo ũgaakũherithia, nakuo gũcooka na thuutha gwaku nĩgũgakũrũithia. Tondũ ũcio wĩciirie wega na ũmenye ũrĩa arĩ ũndũ mũũru mũno na ũrĩ ruo harĩwe, rĩrĩa ũtirikĩte Jehova Ngai waku, na rĩrĩa ũkwaga kwĩĩndigĩra,” ũguo nĩguo Mwathani, o we Jehova Mwene-Hinya-Wothe, ekuuga.
20 “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
“Nĩwoinangire icooki rĩaku rĩa ngingo o tene, na ũgĩtuuanga mĩhĩndo yaku; woigire atĩrĩ, ‘Ndigũcooka gũgũtungata!’ Tondũ-rĩ, tũrĩma-inĩ tũrĩa tuothe tũraihu na igũrũ, na rungu rwa mũtĩ o wothe mũruru nĩkuo wakomaga ũkĩhũũra ũmaraya.
21 Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
Niĩ ndaakũhaandĩte ũrĩ ta mũthabibũ mũthuuranĩre wa mũthemba ũrĩa mwega. Wagĩcookire kũngarũrũka atĩa, ũgĩthũka, ũgĩtuĩka ta mũthabibũ wa gĩthaka?
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
O na ũngĩĩthamba na igata, o na ũhũthĩre thabuni mũingĩ mũno-rĩ, kĩmeni kĩa wĩhia waku ndingĩtiga gũkĩona,” ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.
23 “Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
“Rĩu-rĩ, ũngĩhota atĩa kuuga atĩrĩ: ‘Niĩ ndiĩthaahĩtie; ndirũmĩrĩire kĩrĩra kĩa Mabaali’? Ta rora wone mĩtugo yaku kũu gĩtuamba-inĩ; wĩcũũranie wega maũndũ marĩa wĩkĩte. Wee ũhaana ta moori ya ngamĩĩra ĩgĩcangacanga kũndũ na kũndũ,
24 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
ũkahaana ta njagĩ ĩrĩa ĩmenyerete gũikara werũ-inĩ, ĩrĩa ĩnuhanuhaga rĩrĩa ĩkwenda kũhaicwo; rĩrĩa ĩrĩ na mũrukĩ-rĩ, nũũ ũngĩhota kũmĩrigĩrĩria? Njamba iria ingĩmĩenda, itingĩĩnogia ikĩmĩcaria; mweri wayo wakinya, nĩikamĩona.
25 Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
Tiga kũhanyũka nginya ũthirĩrwo nĩ iraatũ magũrũ, naguo mũmero waku ũngʼare. No wee ũkiuga atĩrĩ, ‘Hatirĩ bata! nĩnyendete ngai cia kũngĩ, na no nginya ndĩciume thuutha.’
26 “Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
“O ta ũrĩa mũici aconorithagio aanyiitwo, ũguo no taguo nyũmba ĩno ya Isiraeli ĩconorithĩtio: o ene, na athamaki ao, na anene ao, na athĩnjĩri-Ngai ao, na anabii ao.
27 Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
Meeraga mũtĩ atĩrĩ, ‘Wee nĩwe Baba,’ na makeera ihiga atĩrĩ, ‘Wee nĩwe wanjiarire.’ Nĩmahutatĩire, makaaga kũnyonia mothiũ mao; no rĩrĩa marĩ thĩĩna-inĩ manjĩĩraga atĩrĩ, ‘Ũka ũtũhonokie!’
28 Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
Ikĩrĩ kũ ngai icio mwethondekeire? Kĩrekei ciũke, aakorwo no imũhonokie rĩrĩa mũrĩ thĩĩna-inĩ! Nĩgũkorwo ngai ciaku cingĩhĩte o ta matũũra maku, wee Juda.
29 “Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
“Mũgũkĩndũithia nĩ ũndũ kĩ? Inyuothe nĩmũũnemeire,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
30 “Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
“Nĩ wĩra wa tũhũ ndaarutire ngĩherithia andũ anyu; matiigana kũigua maakaanio magarũrũke. Rũhiũ rwaku rwa njora nĩrũniinĩte anabii anyu, o ta mũrũũthi ũrĩa mũrĩĩani.
31 “Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
“Atĩrĩrĩ, inyuĩ andũ a rũciaro rũrũ, mwĩcũraniei wega ũhoro wa ndũmĩrĩri ĩno ya Jehova: “Kaĩ nduĩkĩte ta werũ harĩ Isiraeli, kana ta bũrũri ũrĩ nduma nene? Nĩ kĩĩ gĩtũmaga andũ akwa moige atĩrĩ, ‘Ithuĩ tũrĩĩkaga ũrĩa tũkwenda; tũtigagũcookerera rĩngĩ’?
32 Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
Rĩu-rĩ, mũirĩtu ahota kũriganĩrwo nĩ mathaga make ma kwĩgemia, kana mũhiki ariganĩrwo nĩ nguo ciake cia ũhiki? No rĩrĩ, andũ akwa nĩmariganĩirwo nĩ niĩ, matukũ maingĩ matangĩtarĩka.
33 Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
Kaĩ nĩ ũrĩ ũũgĩ mũingĩ rĩrĩa ũgũcaria wendo-ĩ! Nĩ ũndũ ũcio o na atumia arĩa aaganu mũno no merute na mĩthiĩre yaku.
34 Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
Nguo-inĩ ciaku-rĩ, andũ nĩmoonaga thakame ya athĩĩni arĩa matarĩ ũũru mekĩte, o na aakorwo ndwamanyiitire magĩtua nyũmba. No rĩrĩ, o na gũtariĩ ũguo
35 ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
wee uugaga atĩrĩ, ‘Niĩ ndirĩ ũndũ mũũru njĩkĩte; we ndandaakarĩire.’ No niĩ nĩngũgũtuĩra ciira, tondũ uugaga atĩrĩ, ‘Niĩ ndiĩhĩtie.’
36 Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
Ũriũngariũngaga nĩkĩ, ũkĩgarũraga mĩthiĩre yaku? Nĩũgaconorithio nĩ bũrũri wa Misiri, o ta ũrĩa waconorithirio nĩ Ashuri.
37 Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.
Ũgaacooka uume kũndũ kũu ũigĩrĩire moko mũtwe, nĩgũkorwo Jehova nĩaregete acio wĩhokete, o matigagũteithia.

< Jeremiah 2 >