< Jeremiah 2 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
Ja minulle tuli tämä Herran sana:
2 “Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
"Mene ja julista Jerusalemin kuullen ja sano: Näin sanoo Herra: Minä muistan sinun nuoruutesi armauden, morsiusaikasi rakkauden, kuinka sinä seurasit minua erämaassa, maassa, jossa ei kylvöä tehdä.
3 Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
Herralle pyhitetty oli Israel, hänen satonsa esikoinen. Kaikki, jotka sitä söivät, joutuivat syynalaisiksi; onnettomuus kohtasi heitä, sanoo Herra.
4 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
Kuulkaa Herran sana, Jaakobin heimo ja kaikki Israelin heimon sukukunnat.
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
Näin sanoo Herra: Mitä vääryyttä teidän isänne minusta löysivät, koska he erkanivat kauas minusta ja lähtivät seuraamaan turhia jumalia ja turhanpäiväisiksi tulivat.
6 Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
He eivät kysyneet: 'Missä on Herra, joka toi meidät pois Egyptin maasta, joka johdatti meitä erämaassa, arojen ja kuilujen maassa, kuivuuden ja synkeyden maassa, maassa, jossa ei kukaan kulje eikä yksikään ihminen asu?'
7 Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
Minä toin teidät hedelmätarhojen maahan syömään sen hedelmää ja hyvyyttä, mutta sinne tultuanne te saastutitte minun maani ja teitte minun perintöosani kauhistukseksi.
8 Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
Papit eivät kysyneet: 'Missä on Herra?' Lainkäyttäjät eivät minua tunteneet, ja paimenet luopuivat minusta; profeetat ennustivat Baalin nimessä ja seurasivat niitä, joista ei apua ole.
9 “Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
Sentähden minä vielä käyn oikeutta teidän kanssanne, sanoo Herra, ja teidän lastenne lasten kanssa minä käyn oikeutta.
10 Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
Menkää kittiläisten saarille katsomaan ja lähettäkää Keedariin panemaan tarkoin merkille ja katsomaan, onko senkaltaista tapahtunut.
11 Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
Onko mikään pakanakansa vaihtanut jumalia, vaikka ne eivät olekaan jumalia? Mutta minun kansani on vaihtanut kunniansa siihen, josta ei apua ole.
12 Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
Hämmästykää tästä, te taivaat, kauhistukaa, peräti tyrmistykää, sanoo Herra.
13 “Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
Sillä minun kansani on tehnyt kaksinkertaisen synnin: minut, elävän veden lähteen, he ovat hyljänneet, ja ovat hakanneet itselleen vesisäiliöitä, särkyviä säiliöitä, jotka eivät vettä pidä.
14 Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
Onko Israel ostettu orja tai kotona syntynyt? Minkätähden hän on joutunut saaliiksi?
15 Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
Häntä vastaan kiljuivat nuoret leijonat, antoivat äänensä kuulua; ne tekivät hänen maansa autioksi, hänen kaupunkinsa hävitettiin asujattomiksi.
16 Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
Myöskin noofilaiset ja tahpanheelaiset pitivät sinun päälakeasi laitumenansa.
17 Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
Eikö tee tätä sinulle se, että sinä hylkäät Herran, sinun Jumalasi, silloin kun hän tahtoo sinua tiellä kuljettaa?
18 Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
Ja nyt, mitä menemistä sinulla on Egyptiin juomaan Siihorin vettä? Ja mitä menemistä sinulla on Assuriin juomaan Eufrat-virran vettä?
19 Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Sinun pahuutesi tuottaa sinulle kurituksen, ja luopumuksesi saattaa sinut rangaistukseen; niin tiedä ja näe, kuinka onnetonta ja katkeraa se on, että sinä hylkäät Herran, sinun Jumalasi, etkä minua pelkää, sanoo Herra, Herra Sebaot.
20 “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
Sillä jo ammoisista ajoista sinä olet särkenyt ikeesi, katkaissut siteesi ja sanonut: 'En tahdo palvella'. Sillä kaikilla korkeilla kukkuloilla ja kaikkien viheriäin puitten alla sinä porttona viruit.
21 Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
Minä olin istuttanut sinut jaloksi viiniköynnökseksi, puhtaimmasta siemenestä; kuinka olet muuttunut minulle vieraan viinipuun villiköynnöksiksi?
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Vaikka pesisit itsesi saippualla ja käyttäisit paljon lipeätä, saastaiseksi jää sittenkin sinun syntisi minun edessäni, sanoo Herra, Herra.
23 “Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
Kuinka saatat sanoa: 'En ole saastuttanut itseäni, en ole baaleja seurannut'! Katso menoasi laaksossa, huomaa, mitä olet tehnyt, sinä nopea, nuori naaraskameli, joka juokset sinne ja tänne;
24 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
sinä villiaasi, erämaahan tottunut, joka himossasi ilmaa ahmit! Kuka hillitsee sen kiiman? Joka sitä etsii, sen ei tarvitse väsyttää itseään; sen löytää, kun tulee sen kuukausi.
25 Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
Varo, ettet juokse jalkaasi anturattomaksi ja kurkkuasi janoiseksi. Mutta sinä sanot: 'Se on turhaa! Ei! Sillä minä rakastan vieraita ja niitä minä seuraan.'
26 “Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
Niinkuin teosta tavattu varas on häpeissänsä, niin joutuu Israelin heimo häpeään, se ja sen kuninkaat, ruhtinaat, papit ja profeetat,
27 Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
he, jotka sanovat puulle: 'Sinä olet minun isäni' ja kivelle: 'Sinä olet minut synnyttänyt'. Sillä he ovat kääntäneet minulle selkänsä eivätkä kasvojansa; mutta onnettomuutensa aikana he sanovat: 'Nouse ja pelasta meidät'.
28 Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
Mutta missä ovat sinun jumalasi, jotka olet itsellesi tehnyt? Nouskoot ne, jos voivat pelastaa sinut onnettomuutesi aikana. Sillä yhtä monta, kuin sinulla on kaupunkeja, on sinulla jumalia, Juuda.
29 “Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
Miksi riitelette minua vastaan? Olettehan te kaikki luopuneet minusta, sanoo Herra.
30 “Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
Turhaan minä olen lyönyt teidän lapsianne; he eivät ole ottaneet kuritusta varteen. Teidän miekkanne on syönyt teidän profeettojanne, niinkuin hävittävä leijona.
31 “Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
Voi sukukuntaa-teitä! Katsokaa Herran sanaa: olenko minä ollut Israelille erämaa, pimeyden maa? Miksi sanoo minun kansani: 'Me juoksemme valtoimina, emme tule enää sinun tykösi'.
32 Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
Unhottaako neitsyt koristeensa, morsian koruvyönsä? Mutta minun kansani on unhottanut minut epälukuisina päivinä.
33 Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
Kuinka ovelasti sinä kuljet lempeä etsiessäsi! Niinpä oletkin perehtynyt pahuuden teihin.
34 Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
Vaatteesi liepeetkin ovat köyhien, viatonten veressä. Et tavannut heitä murtautumasta sisälle, mutta yhtäkaikki-!
35 ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
Ja kuitenkin sinä sanot: 'Minä olen syytön; hänen vihansa on kaiketi kääntynyt minusta pois'. Katso, minä käyn oikeutta sinun kanssasi, koska sinä sanot: 'En ole syntiä tehnyt'.
36 Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
Kuinka niin kovin kiiruhdat vaihtamaan tiesi! Egyptistäkin olet saava häpeän, niinkuin olet häpeän saanut Assurista.
37 Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.
Senkin tyköä olet lähtevä kädet pääsi päällä, sillä Herra on hyljännyt ne, joihin sinä luotat, ja heistä ei sinulle menestystä tule."

< Jeremiah 2 >