< Jeremiah 2 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
Yahweh gave me another message
2 “Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
[to proclaim to everyone in Jerusalem. He said that I should tell them this] [MET]: “I, Yahweh, remember that you very much wanted to please me [long ago]. [You tried to please me like] a bride [tries to please her husband]; You loved me, and you followed me through the desert [DOU].
3 Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
[At that time you] Israelis (were set apart/belonged only) to me; [you belonged to me like] the first part of the harvests belong to me [MET]. I promised to punish all those who harmed you, my people, and truly I did send disasters on them. [That happened because I], Yahweh, said [that it would happen].”
4 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
So, you [descendants of] [MTY] Jacob, all you people of [MTY] Israel,
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
listen to what Yahweh says: “(What sin did I commit [RHQ] that caused your ancestors to turn far away from me?/Though your ancestors found no fault in me, they turned far away from me.) They worshiped worthless idols, and they themselves became worthless.
6 Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
They did not say, ‘Yahweh brought us [safely] out of Egypt, and he led us through a desert where there were a lot of pits; he led us where there was no water and where it was very dangerous, through a land where no one lives, and no one even travels. (So where is Yahweh now?/So he should be helping us now!) [RHQ]’
7 Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
And when I brought you into a very fertile land, in order that you could enjoy [all] the fruit and [other] good things that you would harvest, you caused the land that I promised to give to you to be unfit for me and to become disgusting/detestable to me.
8 Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
[Your] priests also did not say, ‘(Where is Yahweh now?/Yahweh should be helping us now!)’ [RHQ] Those who teach/explain my laws do not [want to] know me, and [your] leaders have rebelled against me. [Your] prophets gave you messages from [their god] Baal, and they worship worthless idols.”
9 “Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
“So, I will accuse you in court. [In future years], I will say what your children and your grandchildren have done that is wrong. [That will happen because I], Yahweh, have said [that it will happen].
10 Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
If you go [west] to the island of Cyprus, or if you go [east] to Kedar [land, ] and if you ask people in those places, they will tell you that no people [from their countries] have ever done the wicked things that you people have done!
11 Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
The people of no other nation have ever [RHQ] abandoned their gods that they thought were glorious and started to worship gods that are not really gods, but you people have abandoned me, your glorious God, and are worshiping gods that are useless.
12 Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
[It is as though everything in] the sky is surprised and dismayed/appalled [about what you have done]; [it is as though] they tremble because they are very horrified.
13 “Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
[You], my people, have done two evil things: You have rejected me, the one who is [like] [MET] a fountain [where you can obtain] fresh water, and you [are worshiping gods that are like] [MET] pits in the ground that are cracked and which are not able to hold any water.
14 Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
You Israeli people, you were certainly not [RHQ] slaves when you were born; you were captured [by your enemies].
15 Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
[Your enemies] [MET] roared [like] lions, and they destroyed your land. [Now] your towns have been burned, and no one lives in them.
16 Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
Soldiers from Memphis and Tahpenes, [cities in Egypt], have [defeated you] [and] shaved your heads [to show that you are their slaves].
17 Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
But it is [RHQ] because you abandoned [me], Yahweh, that these disasters have happened to you.
18 Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
So (why are you trying to make an alliance with [MET] the rulers of Egypt?/it certainly will not help you to make an alliance with the rulers of Egypt) [RHQ]. Why are you trying to make an alliance with [MET] the rulers of Assyria who live near the [Euphrates] River?
19 Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
[It is because] you have been [very] wicked that I [PRS] will punish you. It is because you have turned away from me that I [PRS] will condemn you. [When I do that], you will realize that painful and evil [DOU] things will happen to you because you have forsaken [me], Yahweh, your God, and you no [longer] revere me. [That will certainly happen because] I, Yahweh, the Commander of the armies of angels in heaven, have said it.
20 “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
Long ago, you stopped obeying [me] [MET], and you would not allow [me] to lead you [MET]; you refused to worship [me]. Instead, you worship idols that are under trees on the top of every hill, and your young women have sex with [EUP] [men at those places].
21 Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
[It is as though] [MET] you were a grapevine that I planted when it was a cutting from a very good vine. So now it is disgusting that [RHQ] you have become [like] a rotten worthless vine.
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Your guilt from your sins is like [MET] very bad stains on a cloth, and you cannot get rid of those stains even by using very strong soap. [This is true because I], Yahweh, have said it.
23 “Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
You say that you have not sinned. You say ‘We have not become unacceptable to God; we have not worshiped Baal.’ But think about [the disgusting things that you do very eagerly] in [Hinnom] Valley [outside Jerusalem]. You are like desperate female camels, running here and there [to find male camels to have sex with].
24 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
You are [like] wild female donkeys in the desert. They sniff the air to find where the male donkeys are, and no one can [RHQ] restrain them. The male donkeys that want them do not become tired searching for them, because at mating time they find them [easily].
25 Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
You constantly run here and there [to find idols to worship], with the result that your sandals are worn out, and your throats have become dry. [I told you to stop doing that], but you said, ‘We cannot stop, because we love foreign gods, and we must worship them.’”
26 “Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
[Yahweh says this]: “A robber is disgraced when he is caught. And all of you, including your kings and priests and prophets, are similarly disgraced.
27 Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
You say to [a piece of] wood [that is carved to become a sacred idol], ‘You are our father!’ And you say to a stone [that you have set up], ‘You are our mother!’ You have rejected [IDM] me, but when you experience troubles, you cry out to me to rescue you.
28 Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
Why do you not [RHQ] cry out to the gods that you made? You have as many gods as you have cities [and towns] in Judah. So why do you not plead with them to rescue you when you experience disasters?
29 “Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
You complain that it was wrong for me [not to have rescued you], but you have all rebelled against me.
30 “Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
I punished some of you, but you did not learn anything from my doing that. You have killed many of the prophets that I [sent to you], like [SIM] fierce lions kill [other animals].
31 “Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
You people of Israel, pay attention to what I say. I have certainly [RHQ] never [abandoned you] in a desert; I have never [left you] in a land full of darkness. So, why do you, my people, say ‘We are free from God’s control; we will not return to [worship] God any more’?
32 Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
A young woman would certainly never [RHQ] forget [to wear] her jewelry, and a bride would never [RHQ] forget to wear her wedding dress, but you my people have forgotten me for many years.
33 Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
You know how to easily find [gods from other countries] whom you can love. You can find them as easily as a prostitute [can find men to sleep with].
34 Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
Although you have on your clothes the blood of poor people whom you have murdered, people who (were innocent/had not done things that are wrong),
35 ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
you say ‘We have not done anything that is wrong; so surely [Yahweh] is not angry with us.’ But I will punish [MTY] you [severely] for saying ‘We have not sinned.’
36 Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
Previously you requested [the army of] Assyria to help you, but they were not able to help you. Now you have requested [the army of] Egypt to help you, but they will not be able to help you, either.
37 Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.
They will capture you, and you will be [their prisoners] [MTY], led to Egypt, [very ashamed] with your hands on your heads. That will happen because I, Yahweh, have rejected those [nations] that you are relying on, and they will not be able to help you at all.”

< Jeremiah 2 >