< Jeremiah 2 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
Hahoi BAWIPA e lawk teh kai koe a pha.
2 “Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
Cet nateh, Jerusalem ka thai lah hram haw. BAWIPA ni hettelah a dei, phaw hoeh e kahrawng hoi kingkadi e kahrawng dawk kaie hnuk na kâbang awh navah, na nawca nah, na ngainae hoi na lawkkam na lungpatawnae hah ka pahnim hoeh.
3 Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
Isarel te BAWIPA koe thoungnae lah ao, hmaloe e aluepaw lah ao. Ahni kacatnaw pueng teh, raphoe lah ao han. Ahnimae lathueng vah, rawknae a pha han, telah BAWIPA ni a dei.
4 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
Oe, Jakop imthung hoi Isarel imthungnaw pueng BAWIPA e lawk hah thai awh haw.
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
BAWIPA ni hettelah a dei. Na mintoenaw ni kai dawkvah bangpatet e lanhoehnae maw a hmu awh teh, kai koehoi kahlatpoung lah a cei te, meikaphawk pâlei teh, kabawknaw lah a coung awh.
6 Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
BAWIPA ni Izip ram hoi na tâcokhai teh, kingkadi e kahrawng, tangkom apapnae hmuen, duenae tâhlip hoi, thingyeiyawn pinihai a cei hoeh nae, ao boihoeh nae hmuen dawk, kacetkhainaw hah, na maw ao telah hai bout tet awh hoeh.
7 Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
Canei hane kahawi apapnae ram dawk na kâenkhai awh. Hateiteh, na kâen awh toteh, ka ram dawk na kamhnawng awh teh, ka râw hah panuettho e lah na coungsak awh.
8 Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
Na maw BAWIPA teh ao telah, vaihmanaw ni tet awh hoeh. Cakathutkungnaw ni hai kai na panuek awh hoeh. Ka ukkungnaw ni hai, kai na taran awh teh, profetnaw ni Baal e lawk hah a pâpho awh teh, cungkeihoehe hno hah a pâlei awh.
9 “Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
Hatdawkvah, namamouh hoi na catounnaw totouh, kai ni na taran awh han, telah BAWIPA ni a ti.
10 Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
Bangkongtetpawiteh, Kittim tuilum hloilah cet awh nateh, khen awh. Kedar ram dawk, tami patoun awh nateh, kahawicalah pouk awh, het patet e hno het ao boimaw.
11 Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
Miphun alouke ni amamae cathut hah cathut katang nahoeh ei, a thung boimaw. Hatei ka taminaw ni bawilennae naw hah banghai cungkeihoeh lah a thung awh toe.
12 Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
Oe, Kalvannaw, kângairu awh, muenruengthaw lah, pâyaw hoi awm awh, telah BAWIPA ni a dei.
13 “Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
Bangkongtetpawiteh, ka taminaw ni kathoute kahni touh a sak awh. Tui kahring a phueknae, kai hah na ceitakhai awh teh, songkong kâbawng e tui kamuem thai hoeh e hah a sak awh.
14 Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
Isarel teh san na maw. Ahni teh, im hoi ka tâcawt e san na maw. Bangkongmaw lawphno lah a coung.
15 Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
Sendektan kanawnaw ni a huksin awh. Nangmouh koe a hram teh, a ram hah koung a raphoe awh. A khopui hai karingkung awm laipalah hmai be a kak.
16 Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
Noph tami hoi Tahpanhes tami nihai, na bawilukhung hah rak a hem awh.
17 Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
Nangmanaw lam ka hrawi e BAWIPA Cathut hah na pahnawt awh dawkvah, hete heh nangmouh lathueng a pha sak nahoehmaw.
18 Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
Sihor tui nei hanelah, bangkongmaw Izip lamthung na dawn. Euphrates palang tui nei hanelah, bangkongmaw, Assiria lamthung na dawn.
19 Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Na hawihoehnae ni na hringnae a toun vaiteh, hnukkhu lah na bannae ni na yue han. Hatdawkvah, BAWIPA Cathut na pahnawtnae hoi, kai na takinae na thung vah, kaawm hoeh e hah, yonnae hoi, kakhat e doeh tie hah, kamcengcalah panuek, telah ransahu Bawipa Jehovah ni a dei.
20 “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
Bangkongtetpawiteh, ayan e na kahnam hah ka khoe teh, a rui hai ka bouk toe, mon rasang tangkuem hoi, thing rahim tangkuem vah, na tabut teh, tak na kâyo, nange kâ ka ek mahoeh telah na ti.
21 Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
Kahawipounge ati hoi ka talue e misur lah na ung. Bangkongmaw, ka hmaitung hoi na kamlang teh, misur kaphawk lah na coung.
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Bangkongtetpawiteh, longtui hoi na kâpasu teh, sapet moikapap na ka hno nakunghai, na yonnae teh, ka hmalah a kamnue, telah Bawipa Jehovah ni a ti.
23 “Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
Ka kâkhinsak hoeh, Baal hai ka kâbang hoeh, telah bangkong na tithai, tanghling dawk na khosaknae khenhaw. Na sak e hah pahnim hanh. Nang teh yuengyoe kâva e kalauk patetlah na o.
24 Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
Kahrawngum kaawm niteh, cuknae lahoi kahlî ka pahap e kahrawng e la atueng a pha toteh apini maw, a ngang pouh thai han. Katawnkungnaw hah reithai hoi awm hanh naseh, atueng akuep nah bout a hmu awh han doeh.
25 Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
Na khok dawk khokkhawm khawm laipalah awm hanh, na adangka hai ke hanh naseh. Hatei nang ni na ngaihawi hane awm hoeh toe. Bangkongtetpawiteh, imyin hah lung ka pataw teh, a hnuk vah kâbang han, telah na ti.
26 “Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
Tamru a man teh, kaya e patetlah, Isarel imthung te a kaya awh toe. Ahnimouh hoi, ahnimae siangpahrangnaw, bawinaw, vaihmanaw hoi, profetnaw hoi, a kaya awh.
27 Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
Thingkung koevah, apa lah na o, a titeh, lungsongpui koe, kahrawikung lah na o, telah ti awh, bangkongtetpawiteh, Ahnimae a hmalah laipalah, hnuklah na kamlang takhai awh. Hateiteh, rucatnae a kâhmo toteh, thaw haw, kaimouh na rungngang haw ati awh han.
28 Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
Hateiteh, na sake na cathut hah, na maw ao. Na rucatnae dawk hoi nangmanaw na rungngang thai pawiteh, ahnimanaw hah thaw sak haw khe, bangkongtetpawiteh, oe, Judah, na cathut te na khopuinaw yit touh a pha awh.
29 “Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
Bang kecu dawk maw, kaie lathueng vah na phuen na ang awh. Nangmouh pueng ni kai na taran lahoi, lawk na ek awh, telah BAWIPA ni a ti.
30 “Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
Ayawmyin lah na canaw ka rek teh, kâponae lah hno ngai awh hoeh. Kamamae profetnaw koung a ca.
31 “Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
Oe, atu se thung e taminaw, BAWIPA e lawk hah khenhaw! Isarel hanelah, kahrawngum hoi kahmawt e ram lah ka o maw. Bang kecu dawk maw, ka taminaw ni, bawi lah ka o awh, nang koe ka tho mahoeh toe, telah ati awh.
32 Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
Tanglakacuem ni a kamthoupnae, yuvâ kâpaluen e ni kâpathoupnae a pahnim thai han na maw. Hatei ka taminaw ni hnin moikasaw lah na pahnim awh.
33 Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
Bangkongmaw lungpatawkung tawng hanelah na kamthoup. Hatdawkvah napui kahawihoehe ni na hringnuen na cangkhai toe.
34 Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
Yonnae ka tawn hoeh e karoedengnaw na theinae thi hah na hni pawi dawk ka hmu. Arulah ka tuet teh ka hmu e nahoeh. Hatei hete hnonaw pueng teh hmantang vah hmu e doeh.
35 ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
Hatei nang ni yonnae ka sak hoeh dawkvah, a lungkhueknae teh kai koe hoi a roum han doeh, khenhaw! yonnae ka sak hoeh na ti dawkvah, nang na taran lahoi yah, ka lawk hah bout ka pouk han rah, telah a ti.
36 Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
Bangkongmaw, na hringnae kâthung hanelah, yuengyoe na kâva. Assiria na kayakhai e patetlah, Izip hai na kayakhai han.
37 Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.
Na lû dawk na kut na toung hoi ahni koehoi na cei han, bangkongtetpawiteh, BAWIPA ni na kâuepkhai e hah a pahnawt teh, ahnimouh koehoi hawinae na hmawt mahoeh.

< Jeremiah 2 >