< Jeremiah 19 >

1 Èyí ní ohun tí Olúwa wí: “Lọ ra ìkòkò lọ́dọ̀ alámọ̀, mú dání lára àwọn àgbàgbà ọkùnrin àti wòlíì.
Astfel spune DOMNUL: Du-te și ia un urcior de lut de la olar și ia dintre bătrânii poporului și dintre bătrânii preoților;
2 Kí o sì lọ sí àfonífojì ọmọ Beni-Hinnomu, níwájú ẹnu ibodè Harsiti, níbẹ̀ ni kí o sì kéde gbogbo ọ̀rọ̀ tí èmi yóò sọ fún ọ.
Și ieși la valea fiului lui Hinom, care este la intrarea porții de est și vestește acolo cuvintele pe care ți le voi zice,
3 Kí o sì wí pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba àwọn Juda àti ẹ̀yin ará Jerusalẹmu. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli sọ. Dẹtí sí mi! Èmi yóò mú ìparun wá síbí, etí gbogbo wọn tó bá gbọ́ ọ yóò hó yaya.
Și spune: Ascultați cuvântul DOMNULUI, împărați ai lui Iuda și locuitori ai Ierusalimului: Astfel spune DOMNUL oștirilor, Dumnezeul lui Israel: Iată, voi aduce asupra acestui loc, răul, de care îi vor țiui urechile oricui aude.
4 Nítorí wọ́n ti gbàgbé mi, wọ́n sì ti sọ ibí di ilé fún òrìṣà àjèjì; wọ́n ti sun ẹbọ nínú rẹ̀ fún òrìṣà tí àwọn baba wọn tàbí tí ọba Juda kò mọ̀ rí, wọ́n ti fi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kún ilẹ̀ yìí.
Pentru că ei m-au părăsit și au înstrăinat acest loc și au ars tămâie în el, altor dumnezei, pe care nici ei nici părinții lor nu i-au cunoscut, nici împărații lui Iuda, și au umplut acest loc cu sângele celor nevinovați;
5 Wọ́n ti kọ́ ibi gíga fún Baali láti sun ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí ohun ẹbọ sísun sí Baali—èyí tí èmi kò pàṣẹ láti ṣe, tí èmi kò sì sọ, tàbí tí kò sì ru sókè láti inú ọkàn mi.
Au zidit de asemenea înălțimi lui Baal, ca să îi ardă pe fiii lor cu foc ca ofrande arse lui Baal, ceea ce eu nu am poruncit, nici nu am vorbit, nici nu mi-a venit în minte;
6 Nítorí náà ṣọ́ra ọjọ́ ń bọ̀ ni Olúwa wí nígbà tí àwọn ènìyàn kì yóò pe ibí ní Tofeti mọ́ tàbí àfonífojì ọmọ Hinnomu, ṣùgbọ́n àfonífojì Ìpakúpa.
De aceea, iată, vin zilele, spune DOMNUL, când acest loc nu va mai fi numit Tofet, nici valea fiului lui Hinom, ci Valea măcelului.
7 “‘Ní ibí yìí ni èmi yóò ti pa èrò Juda àti Jerusalẹmu run. Èmí yóò mú wọn ṣubú nípa idà níwájú àwọn ọ̀tá wọn, lọ́wọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn. Èmi yóò sì fi òkú wọn ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.
Și voi zădărnici sfatul lui Iuda și al Ierusalimului în acest loc; și îi voi face să cadă prin sabie înaintea dușmanilor lor și prin mâinile celor ce le caută viețile; și trupurile lor moarte le voi da ca hrană pentru păsările cerului și pentru fiarele pământului.
8 Èmi yóò sọ ìlú yìí di ahoro àti ohun ẹ̀gàn, gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò bẹ̀rù wọn yóò sì máa fòyà nítorí gbogbo ọgbẹ́ rẹ̀.
Și voi face această cetate pustie și un motiv de șuierare: oricine trece prin ea va fi înmărmurit și va șuiera din cauza tuturor plăgilor ei.
9 Èmi yóò mú kí wọ́n jẹ ẹran-ara ọmọ wọn ọkùnrin àti ẹran-ara ọmọ wọn obìnrin, ẹnìkínní yóò sì jẹ ẹran-ara ẹnìkejì, nígbà ìdótì àti ìhámọ́ láti ọwọ́ ọ̀tá wọn, àti àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn.’
Și îi voi face să mănânce carnea fiilor lor și carnea fiicelor lor și vor mânca fiecare carnea prietenului său în asediul și în strâmtorarea cu care îi vor strâmtora dușmanii lor și cei care le caută viața.
10 “Nígbà náà ni ìwọ yóò fọ́ ìkòkò náà ní ojú àwọn tí ó bá ọ lọ.
Atunci să spargi urciorul înaintea ochilor oamenilor care merg cu tine,
11 Kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. Èmi a fọ́ orílẹ̀-èdè yìí àti ìlú yìí gẹ́gẹ́ bí ìkòkò amọ̀ yìí ṣe fọ́ tí kò sì ní sí àtúnṣe. Wọn a sì sin àwọn òkú sí Tofeti títí tí kò fi ní sí ààyè mọ́.
Și să le spui: Astfel spune DOMNUL oștirilor: Astfel voi zdrobi acest popor și această cetate, precum cineva sparge un vas al olarului, care nu mai poate fi întregit; și ei îi vor îngropa în Tofet, până când nu va mai fi loc de îngropare.
12 Èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí ibí yìí àti àwọn tí ń gbé ní ibí yìí ni Olúwa wí. Èmi yóò mú ìlú yìí dàbí Tofeti.
Astfel voi face acestui loc, spune DOMNUL și locuitorilor lui, și voi face chiar această cetate precum Tofetul;
13 Àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu àti ti ọba ìlú Juda ni a ó sọ di àìmọ́ bí Tofeti, gbogbo ilé tí wọ́n ti ń sun tùràrí ni orí òrùlé sí gbogbo ogun ọ̀run, tí a sì ń rú ẹbọ mímu sí ọlọ́run mìíràn.’”
Și casele Ierusalimului și casele împăraților lui Iuda vor fi întinate ca locul Tofetului, din cauza tuturor caselor pe a căror acoperișuri ei au ars tămâie întregii oștiri a cerului și au turnat daruri de băutură altor dumnezei.
14 Jeremiah sì padà láti Tofeti níbi tí Olúwa rán an sí láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ó sì dúró ní gbangba tẹmpili Olúwa, ó sì sọ fún gbogbo ènìyàn pé,
Atunci a venit Ieremia din Tofet, unde îl trimisese DOMNUL să profețească; și a stat în picioare în curtea casei DOMNULUI; și a spus întregului popor:
15 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò mú ìdààmú tí mo ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ bá ìlú yìí àti ìgbèríko tí ó yí i ká, nítorí ọlọ́rùn líle ni wọ́n, wọn kò si ní fẹ́ fetí sí ọ̀rọ̀ mi.’”
Astfel spune DOMNUL oștirilor, Dumnezeul lui Israel: Iată, voi aduce asupra acestei cetăți și asupra tuturor orașelor ei tot răul pe care l-am pronunțat împotriva ei, pentru că și-au împietrit gâturile, ca să nu asculte cuvintele mele.

< Jeremiah 19 >