< Jeremiah 19 >

1 Èyí ní ohun tí Olúwa wí: “Lọ ra ìkòkò lọ́dọ̀ alámọ̀, mú dání lára àwọn àgbàgbà ọkùnrin àti wòlíì.
Assim disse Javé: “Vá e compre um recipiente de barro de oleiro, e leve alguns dos anciãos do povo e dos anciãos dos sacerdotes;
2 Kí o sì lọ sí àfonífojì ọmọ Beni-Hinnomu, níwájú ẹnu ibodè Harsiti, níbẹ̀ ni kí o sì kéde gbogbo ọ̀rọ̀ tí èmi yóò sọ fún ọ.
e saia para o vale do filho de Hinnom, que é pela entrada do portão Harsith, e proclame lá as palavras que eu lhe direi.
3 Kí o sì wí pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba àwọn Juda àti ẹ̀yin ará Jerusalẹmu. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli sọ. Dẹtí sí mi! Èmi yóò mú ìparun wá síbí, etí gbogbo wọn tó bá gbọ́ ọ yóò hó yaya.
Diga: 'Ouçam a palavra de Javé, reis de Judá e habitantes de Jerusalém': Javé dos Exércitos, o Deus de Israel diz: “Eis que eu trarei o mal sobre este lugar, o qual, quem ouvir, seus ouvidos formigarão.
4 Nítorí wọ́n ti gbàgbé mi, wọ́n sì ti sọ ibí di ilé fún òrìṣà àjèjì; wọ́n ti sun ẹbọ nínú rẹ̀ fún òrìṣà tí àwọn baba wọn tàbí tí ọba Juda kò mọ̀ rí, wọ́n ti fi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kún ilẹ̀ yìí.
Porque me abandonaram, e contaminaram este lugar, e queimaram incenso nele para outros deuses que não conheciam - eles, seus pais e os reis de Judá - e encheram este lugar com o sangue de inocentes,
5 Wọ́n ti kọ́ ibi gíga fún Baali láti sun ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí ohun ẹbọ sísun sí Baali—èyí tí èmi kò pàṣẹ láti ṣe, tí èmi kò sì sọ, tàbí tí kò sì ru sókè láti inú ọkàn mi.
e construíram os lugares altos de Baal para queimar seus filhos no fogo para holocaustos a Baal, que eu não comandei, nem falei, que nem sequer entrou em minha mente.
6 Nítorí náà ṣọ́ra ọjọ́ ń bọ̀ ni Olúwa wí nígbà tí àwọn ènìyàn kì yóò pe ibí ní Tofeti mọ́ tàbí àfonífojì ọmọ Hinnomu, ṣùgbọ́n àfonífojì Ìpakúpa.
Portanto, eis que vêm os dias”, diz Javé, “que este lugar não será mais chamado 'Topheth', nem 'The Valley of the son of Hinnom', mas 'The valley of Slaughter'.
7 “‘Ní ibí yìí ni èmi yóò ti pa èrò Juda àti Jerusalẹmu run. Èmí yóò mú wọn ṣubú nípa idà níwájú àwọn ọ̀tá wọn, lọ́wọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn. Èmi yóò sì fi òkú wọn ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.
““““Vou invalidar o conselho de Judá e Jerusalém neste lugar. Farei com que caiam pela espada diante de seus inimigos, e pela mão daqueles que buscam sua vida”. Darei seus corpos mortos para serem alimento para as aves do céu e para os animais da terra”.
8 Èmi yóò sọ ìlú yìí di ahoro àti ohun ẹ̀gàn, gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò bẹ̀rù wọn yóò sì máa fòyà nítorí gbogbo ọgbẹ́ rẹ̀.
Vou fazer desta cidade um espanto e um assobio. Todos os que passarem por ela ficarão espantados e assobiarão por causa de todas as suas pragas.
9 Èmi yóò mú kí wọ́n jẹ ẹran-ara ọmọ wọn ọkùnrin àti ẹran-ara ọmọ wọn obìnrin, ẹnìkínní yóò sì jẹ ẹran-ara ẹnìkejì, nígbà ìdótì àti ìhámọ́ láti ọwọ́ ọ̀tá wọn, àti àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn.’
Eu os farei comer a carne de seus filhos e a carne de suas filhas. Cada um deles comerá a carne de seu amigo no cerco e na angústia com que seus inimigos, e aqueles que procuram sua vida, os afligirão”.
10 “Nígbà náà ni ìwọ yóò fọ́ ìkòkò náà ní ojú àwọn tí ó bá ọ lọ.
“Então você quebrará o recipiente à vista dos homens que vão com você,
11 Kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. Èmi a fọ́ orílẹ̀-èdè yìí àti ìlú yìí gẹ́gẹ́ bí ìkòkò amọ̀ yìí ṣe fọ́ tí kò sì ní sí àtúnṣe. Wọn a sì sin àwọn òkú sí Tofeti títí tí kò fi ní sí ààyè mọ́.
e lhes dirá: 'Yahweh dos Exércitos diz: “Mesmo assim quebrarei este povo e esta cidade quando alguém quebrar um vaso de oleiro, que não pode ficar inteiro novamente. Eles vão enterrar em Topheth até que não haja lugar para enterrar.
12 Èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí ibí yìí àti àwọn tí ń gbé ní ibí yìí ni Olúwa wí. Èmi yóò mú ìlú yìí dàbí Tofeti.
Isto é o que farei com este lugar”, diz Yahweh, “e com seus habitantes, até mesmo fazendo desta cidade como Topheth”.
13 Àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu àti ti ọba ìlú Juda ni a ó sọ di àìmọ́ bí Tofeti, gbogbo ilé tí wọ́n ti ń sun tùràrí ni orí òrùlé sí gbogbo ogun ọ̀run, tí a sì ń rú ẹbọ mímu sí ọlọ́run mìíràn.’”
As casas de Jerusalém e as casas dos reis de Judá, que estão contaminadas, serão como o lugar de Topheth, mesmo todas as casas em cujos telhados queimaram incenso para todo o exército do céu e derramaram ofertas de bebida para outros deuses”””.
14 Jeremiah sì padà láti Tofeti níbi tí Olúwa rán an sí láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ó sì dúró ní gbangba tẹmpili Olúwa, ó sì sọ fún gbogbo ènìyàn pé,
Então Jeremias veio de Topheth, onde Iavé o havia enviado para profetizar, e ficou na corte da casa de Iavé, e disse a todo o povo:
15 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò mú ìdààmú tí mo ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ bá ìlú yìí àti ìgbèríko tí ó yí i ká, nítorí ọlọ́rùn líle ni wọ́n, wọn kò si ní fẹ́ fetí sí ọ̀rọ̀ mi.’”
“Iavé dos Exércitos, o Deus de Israel diz: 'Eis que trarei sobre esta cidade e sobre todas as suas cidades todo o mal que pronunciei contra ela, porque endureceram o pescoço, para que não ouçam minhas palavras'”.

< Jeremiah 19 >