< Jeremiah 19 >

1 Èyí ní ohun tí Olúwa wí: “Lọ ra ìkòkò lọ́dọ̀ alámọ̀, mú dání lára àwọn àgbàgbà ọkùnrin àti wòlíì.
Tā saka Tas Kungs: ej un pērc sev no podnieka māla krūzi, un ņem pie sevis kādus no ļaužu vecajiem un no priesteru vecajiem.
2 Kí o sì lọ sí àfonífojì ọmọ Beni-Hinnomu, níwájú ẹnu ibodè Harsiti, níbẹ̀ ni kí o sì kéde gbogbo ọ̀rọ̀ tí èmi yóò sọ fún ọ.
Un ej ārā uz Ben-Inoma ieleju, kas ir priekš Ķieģeļu vārtiem, un sludini tur tos vārdus, ko Es uz tevi runāšu,
3 Kí o sì wí pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba àwọn Juda àti ẹ̀yin ará Jerusalẹmu. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli sọ. Dẹtí sí mi! Èmi yóò mú ìparun wá síbí, etí gbogbo wọn tó bá gbọ́ ọ yóò hó yaya.
Un saki: klausiet Tā Kunga vārdu, Jūda ķēniņi un Jeruzālemes iedzīvotāji! Tā saka Tas Kungs Cebaot, Israēla Dievs: redzi, Es vedīšu nelaimi pār šo vietu, no kā visiem, kas to dzirdēs, ausīs skanēs.
4 Nítorí wọ́n ti gbàgbé mi, wọ́n sì ti sọ ibí di ilé fún òrìṣà àjèjì; wọ́n ti sun ẹbọ nínú rẹ̀ fún òrìṣà tí àwọn baba wọn tàbí tí ọba Juda kò mọ̀ rí, wọ́n ti fi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kún ilẹ̀ yìí.
Tāpēc ka tie Mani atstāj un šo vietu svešiem nodevuši un tur kvēpinājuši svešiem dieviem, ko ne viņi, ne viņu tēvi, ne Jūda ķēniņi nav pazinuši, un to vietu piepildījuši ar nenoziedzīgām asinīm,
5 Wọ́n ti kọ́ ibi gíga fún Baali láti sun ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí ohun ẹbọ sísun sí Baali—èyí tí èmi kò pàṣẹ láti ṣe, tí èmi kò sì sọ, tàbí tí kò sì ru sókè láti inú ọkàn mi.
Un Baālam uztaisījuši altārus un savus bērnus ar uguni sadedzinājuši Baālam par dedzināmiem upuriem, ko Es neesmu pavēlējis, un neesmu runājis, un kas Man nav nācis sirdī.
6 Nítorí náà ṣọ́ra ọjọ́ ń bọ̀ ni Olúwa wí nígbà tí àwọn ènìyàn kì yóò pe ibí ní Tofeti mọ́ tàbí àfonífojì ọmọ Hinnomu, ṣùgbọ́n àfonífojì Ìpakúpa.
Tādēļ, redzi, nāks dienas, saka Tas Kungs, ka šī vieta vairs netaps nosaukta Tovete vai Ben-Inoma ieleja, bet slepkavu ieleja.
7 “‘Ní ibí yìí ni èmi yóò ti pa èrò Juda àti Jerusalẹmu run. Èmí yóò mú wọn ṣubú nípa idà níwájú àwọn ọ̀tá wọn, lọ́wọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn. Èmi yóò sì fi òkú wọn ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.
Jo Es iznīcināšu Jūda un Jeruzālemes padomu šinī vietā, un tiem likšu krist caur zobenu priekš viņu ienaidniekiem un caur to rokām, kas viņu dvēseli meklē, un Es nodošu viņu miesas par barību putniem apakš debess un zvēriem virs zemes.
8 Èmi yóò sọ ìlú yìí di ahoro àti ohun ẹ̀gàn, gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò bẹ̀rù wọn yóò sì máa fòyà nítorí gbogbo ọgbẹ́ rẹ̀.
Un šo pilsētu Es likšu par posta vietu un par apsmieklu; visi, kas iet garām, tie iztrūksies un svilpos par visām viņu mokām.
9 Èmi yóò mú kí wọ́n jẹ ẹran-ara ọmọ wọn ọkùnrin àti ẹran-ara ọmọ wọn obìnrin, ẹnìkínní yóò sì jẹ ẹran-ara ẹnìkejì, nígbà ìdótì àti ìhámọ́ láti ọwọ́ ọ̀tá wọn, àti àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn.’
Un Es tiem došu ēst viņu dēlu miesas un viņu meitu miesas, un tie ēdīs ikviens sava tuvāka miesas tais bēdās un bailēs, ar ko tos spaidīs viņu ienaidnieki un kas viņu dvēseles meklē.
10 “Nígbà náà ni ìwọ yóò fọ́ ìkòkò náà ní ojú àwọn tí ó bá ọ lọ.
Tad tev to krūzi būs sadauzīt priekš to vīru acīm, kas tev gājuši līdz,
11 Kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. Èmi a fọ́ orílẹ̀-èdè yìí àti ìlú yìí gẹ́gẹ́ bí ìkòkò amọ̀ yìí ṣe fọ́ tí kò sì ní sí àtúnṣe. Wọn a sì sin àwọn òkú sí Tofeti títí tí kò fi ní sí ààyè mọ́.
Un uz tiem sacīt: tā saka Tas Kungs Cebaot: tāpat es šos ļaudis un šo pilsētu sadauzīšu, tā kā sadauza māla trauku, kas vairs nevar vesels tapt, un Tovetē raks līķus, tāpēc ka citas kapu vietas nebūs.
12 Èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí ibí yìí àti àwọn tí ń gbé ní ibí yìí ni Olúwa wí. Èmi yóò mú ìlú yìí dàbí Tofeti.
Tā es šai vietai darīšu, saka Tas Kungs, un viņas iedzīvotājiem, un darīšu šo pilsētu kā Toveti.
13 Àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu àti ti ọba ìlú Juda ni a ó sọ di àìmọ́ bí Tofeti, gbogbo ilé tí wọ́n ti ń sun tùràrí ni orí òrùlé sí gbogbo ogun ọ̀run, tí a sì ń rú ẹbọ mímu sí ọlọ́run mìíràn.’”
Un Jeruzālemes nami un Jūda ķēniņu nami būs sagānīti, tā kā Tovetes vieta, un visi tie nami, uz kuru jumtiem tie kvēpinājuši visam debess spēkam un dzeramus upurus upurējuši svešiem dieviem.
14 Jeremiah sì padà láti Tofeti níbi tí Olúwa rán an sí láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ó sì dúró ní gbangba tẹmpili Olúwa, ó sì sọ fún gbogbo ènìyàn pé,
Kad nu Jeremija no Tovetes pārnāca, kurp Tas Kungs viņu bija sūtījis sludināt, tad viņš nostājās Tā Kunga nama pagalmā un sacīja uz visu tautu:
15 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò mú ìdààmú tí mo ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ bá ìlú yìí àti ìgbèríko tí ó yí i ká, nítorí ọlọ́rùn líle ni wọ́n, wọn kò si ní fẹ́ fetí sí ọ̀rọ̀ mi.’”
Tā saka Tas Kungs Cebaot, Israēla Dievs: redzi, Es likšu nākt pār šo pilsētu un visām viņas pilsētām visai nelaimei, ko Es par to esmu runājis, tādēļ ka tie savu pakausi apcietinājuši un Manus Vārdus nav klausījuši.

< Jeremiah 19 >