< Jeremiah 18 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá wí pe:
Beseda, ki je prišla Jeremiju od Gospoda, rekoč:
2 “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé amọ̀kòkò, níbẹ̀ ni èmi yóò ti bá ọ sọ̀rọ̀.”
»Vstani in pojdi dol k lončarjevi hiši in tam ti bom povzročil, da boš slišal moje besede.«
3 Nígbà náà ni mo lọ sí ilé amọ̀kòkò mo sì rí i tí ó ń ṣiṣẹ́ kan lórí kẹ̀kẹ́.
Potem sem odšel dol k lončarjevi hiši in glej, izdeloval je delo na kolesih.
4 Ṣùgbọ́n ìkòkò tí ó ń mọ láti ara amọ̀ bàjẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀, nítorí náà ni amọ̀kòkò fi ṣe ìkòkò mìíràn, ó mọ ọ́n bí èyí tí ó dára jù ní ojú rẹ̀.
Posoda, ki jo je naredil iz ila je bila iznakažena v lončarjevi roki. Tako je še enkrat naredil drugo posodo, kakor se je lončarju zdelo dobro, da jo naredi.
5 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
Potem je k meni prišla Gospodova beseda, rekoč:
6 “Ẹyin ilé Israẹli, èmi kò ha lè ṣe fún un yín gẹ́gẹ́ bí amọ̀kòkò yìí ti ṣe?” ni Olúwa wí. “Gẹ́gẹ́ bí amọ̀ ní ọwọ́ amọ̀kòkò bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin rí ní ọwọ́ mi, ẹ̀yin ilé Israẹli.
»Oh Izraelova hiša, mar ne morem narediti z vami kakor ta lončar?« govori Gospod. »Glejte, kakor je ilo v lončarjevi roki, tako ste vi v moji roki, oh Izraelova hiša.
7 Bí ó bá jẹ́ ìgbà kan, tí èmi kéde kí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan di fífà tu láti dojúdé àti láti parun,
V kakšnem trenutku bom govoril glede naroda in glede kraljestva, da ga izruvam, poderem in uničim.
8 tí orílẹ̀-èdè ti mo kìlọ̀ fún bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú wọn, nígbà náà ni Èmi yóò yí ọkàn mi padà nínú àjálù tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.
Če [pa] se ta narod, zoper katerega sem proglasil, obrne od svojega zla, se bom pokesal od zla, ki sem jim ga mislil storiti.
9 Ní ìgbà mìíràn tí èmi bá tún kéde láti tẹ̀dó tàbí gbin orílẹ̀-èdè kan tàbí ìjọba kan.
V kakšnem trenutku bom govoril glede naroda in glede kraljestva, da ga zgradim in zasadim.
10 Bí ó bá sì ṣe búburú níwájú mi, tí kò sì gba ohùn mi gbọ́, nígbà náà ni èmi yóò yí ọkàn mi padà ní ti rere, èyí tí mo wí pé, èmi ó ṣe fún wọn.
Če [pa] dela zlo v mojem pogledu, da ne uboga mojega glasu, potem se bom pokesal dobrega, s katerim sem rekel, da bi jim koristil.
11 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, sọ fún àwọn ènìyàn Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa wí: Wò ó! Èmi ń gbèrò ibi sí yin, èmi sì ń ṣe ìpinnu kan lórí yín. Nítorí náà ẹ yípadà kúrò lọ́nà búburú yín kí olúkúlùkù yín sì tún ọ̀nà àti ìṣe rẹ̀ ṣe.’
Zdaj torej pojdi, govori Judovim možem in prebivalcem Jeruzalema, rekoč: ›Tako govori Gospod; ›Glejte, zoper vas oblikujem zlo in zoper vas naklepam naklep. Torej se vrnite, vsakdo iz svoje hudobne poti in naredite svoje poti in svoja dejanja dobra.‹«
12 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Kò ṣe nǹkan kan, àwa yóò tẹ̀síwájú nínú èrò wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa, yóò hùwà agídí ọkàn búburú rẹ̀.’”
Rekli so: »Tam ni nobenega upanja, temveč bomo hodili po svojih lastnih naklepih in vsakdo izmed nas bo počel zamisel svojega zlega srca.«
13 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: “Ẹ béèrè nínú orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá ti gbọ́ irú nǹkan wọ̀nyí ri? Ohun tí ó burú gidi ni wúńdíá Israẹli ti ṣe.
Zato tako govori Gospod: »Vprašajte torej med pogani, kdo je slišal takšne stvari. Izraelova devica je storila zelo strašno stvar.
14 Ǹjẹ́ omi ojo dídì Lebanoni yóò ha dá láti máa sàn láti ibi àpáta? Tàbí odò tí ó jìnnà, tí ó tútù, tí ó ń sàn, yóò ha gbẹ bí?
Mar bo človek zapustil libanonski sneg, ki prihaja iz poljske skale? Mar bodo hladne tekoče vode, ki prihajajo iz drugega kraja, zapuščene?
15 Nítorí àwọn ènìyàn mi gbàgbé mi, wọ́n sun tùràrí fún òrìṣà asán, tí ó mú wọn kọsẹ̀ ní ọ̀nà wọn, àti ọ̀nà wọn àtijọ́. Wọ́n mú wọn rìn ní ọ̀nà àtijọ́, àti ní ojú ọ̀nà ti a kò ṣe.
Ker me je moje ljudstvo pozabilo so zažigali kadilo ničnostim in le-ti so jim storili, da se spotikajo na svojih poteh od starodavnih steza, da hodijo po stezah, na poti, ki ni nasuta,
16 Ilẹ̀ wọn yóò wà lásán yóò sì di nǹkan ẹ̀gàn títí láé, gbogbo àwọn tí ó ń kọjá yóò bẹ̀rù, wọn yóò sì mi orí wọn.
da naredijo svojo deželo zapuščeno in neprestan posmeh; vsak, kdor gre tam mimo, bo osupel in bo zmajeval z glavo.
17 Gẹ́gẹ́ bí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn, Èmi yóò tú wọn ká lójú àwọn ọ̀tá wọn. Èmi yóò sì kọ ẹ̀yìn sí wọn, n kì yóò kọjú sí wọn ní ọjọ́ àjálù wọn.”
Pred sovražnikom jih bom razkropil kakor z vzhodnim vetrom; pokazal jim bom hrbet in ne obraza, na dan njihove katastrofe.«
18 Wọ́n sọ wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ ṣọ̀tẹ̀ sí Jeremiah, nítorí òfin ìkọ́ni láti ẹnu àwọn àlùfáà kì yóò jásí asán, tàbí ìmọ̀ràn fún àwọn ọlọ́gbọ́n tàbí ọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì. Nítorí náà wá, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú pẹ̀lú ahọ́n wa, kí a má sì ṣe tẹ́tí sí ohunkóhun tí ó bá sọ.”
Potem so rekli: »Pridite in naklepajmo naklepe zoper Jeremija; kajti postava ne bo izginila od duhovnika, niti nasvet od modrega, niti beseda od preroka. Pridite in udarimo ga z jezikom in ne dajmo pozornosti katerikoli izmed njegovih besed.«
19 Dẹtí sí ọ̀rọ̀ mi Olúwa, gbọ́ ohun tí àwọn tí ó fi mí sùn ń sọ.
Nakloni mi pozornost, oh Gospod in prisluhni glasu tistih, ki se pričkajo z menoj.
20 Ṣe kí a fi rere san búburú? Síbẹ̀ wọ́n ti gbẹ́ kòtò fún mi. Rántí pé mo dúró níwájú rẹ, mo sì sọ̀rọ̀ nítorí wọn, láti yí ìbínú rẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Mar bo zlo poplačilo za dobro? Kajti izkopali so jamo za mojo dušo. Spomni se, da sem stal pred teboj, da govorim dobro zanje in da odvrnem tvoj bes od njih.
21 Nítorí náà, jẹ́ kí ìyàn mú ọmọ wọn jọ̀wọ́ wọn fún ọwọ́ idà jẹ́ kí ìyàwó wọn kí ó di aláìlọ́mọ àti opó jẹ́ kí a pa àwọn ọkùnrin wọn kí a sì fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn lójú ogun.
Zato njihove otroke izroči lakoti in njihovo kri izlij s silo meča; in naj bodo njihove žene oropane svojih otrok in bodo vdove; in naj bodo njihovi možje usmrčeni; naj bodo njihovi mladeniči v bitki umorjeni z mečem.
22 Jẹ́ kí a gbọ́ ohùn ẹkún láti ilé wọn nígbà tí ó bá mu àwọn jagunjagun kọlù wọ́n lójijì nítorí wọ́n ti gbẹ́ kòtò láti mú mi. Wọ́n ti dẹ okùn fún ẹsẹ̀ mi.
Naj bo krik slišan od njihovih hiš, ko boš nadnje nenadoma privedel krdelo, kajti izkopali so jamo, da bi me ujeli in skrili pasti za moja stopala.
23 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa mọ gbogbo ète wọn láti pa mí, má ṣe dárí ẹ̀bi wọn jì wọ́n bẹ́ẹ̀ ni má ṣe pa ẹ̀ṣẹ̀ wọn rẹ́ kúrò lójú rẹ. Jẹ́ kí wọn kí ó ṣubú níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó sì ṣe sí wọn nígbà ìbínú rẹ.
Vendar, Gospod, ti poznaš vse njihove namere zoper mene, da me ubijejo. Ne odpusti njihove krivičnosti niti njihovega greha ne izbriši pred svojim pogledom, temveč naj bodo zrušeni pred teboj; tako postopaj z njimi v času svoje jeze.

< Jeremiah 18 >