< Jeremiah 18 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá wí pe:
A palavra que veio de Javé a Jeremias, dizendo:
2 “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé amọ̀kòkò, níbẹ̀ ni èmi yóò ti bá ọ sọ̀rọ̀.”
“Levantem-se e vão até a casa do oleiro, e lá farei com que ouçam minhas palavras”.
3 Nígbà náà ni mo lọ sí ilé amọ̀kòkò mo sì rí i tí ó ń ṣiṣẹ́ kan lórí kẹ̀kẹ́.
Depois fui até a casa do oleiro, e eis que ele estava fazendo algo sobre as rodas.
4 Ṣùgbọ́n ìkòkò tí ó ń mọ láti ara amọ̀ bàjẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀, nítorí náà ni amọ̀kòkò fi ṣe ìkòkò mìíràn, ó mọ ọ́n bí èyí tí ó dára jù ní ojú rẹ̀.
Quando o vaso que ele fez do barro foi estragado na mão do oleiro, ele o fez novamente outro vaso, como parecia bom para o oleiro fazer.
5 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
Então a palavra de Javé veio até mim, dizendo:
6 “Ẹyin ilé Israẹli, èmi kò ha lè ṣe fún un yín gẹ́gẹ́ bí amọ̀kòkò yìí ti ṣe?” ni Olúwa wí. “Gẹ́gẹ́ bí amọ̀ ní ọwọ́ amọ̀kòkò bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin rí ní ọwọ́ mi, ẹ̀yin ilé Israẹli.
“Casa de Israel, não posso fazer com você como este oleiro?” diz Javé. “Eis que, como o barro na mão do oleiro, também tu estás na minha mão, casa de Israel”.
7 Bí ó bá jẹ́ ìgbà kan, tí èmi kéde kí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan di fífà tu láti dojúdé àti láti parun,
No momento em que falo a respeito de uma nação, e a respeito de um reino, para arrancá-lo, derrubá-lo e destruí-lo,
8 tí orílẹ̀-èdè ti mo kìlọ̀ fún bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú wọn, nígbà náà ni Èmi yóò yí ọkàn mi padà nínú àjálù tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.
se essa nação, a respeito da qual falei, se converter de seu mal, arrepender-me-ei do mal que pensei em fazer-lhes.
9 Ní ìgbà mìíràn tí èmi bá tún kéde láti tẹ̀dó tàbí gbin orílẹ̀-èdè kan tàbí ìjọba kan.
No instante em que eu falar sobre uma nação, e sobre um reino, para construí-lo e plantá-lo,
10 Bí ó bá sì ṣe búburú níwájú mi, tí kò sì gba ohùn mi gbọ́, nígbà náà ni èmi yóò yí ọkàn mi padà ní ti rere, èyí tí mo wí pé, èmi ó ṣe fún wọn.
se eles fizerem o que é mau aos meus olhos, que não obedecem à minha voz, então eu me arrependerei do bem com o qual eu disse que os beneficiaria.
11 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, sọ fún àwọn ènìyàn Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa wí: Wò ó! Èmi ń gbèrò ibi sí yin, èmi sì ń ṣe ìpinnu kan lórí yín. Nítorí náà ẹ yípadà kúrò lọ́nà búburú yín kí olúkúlùkù yín sì tún ọ̀nà àti ìṣe rẹ̀ ṣe.’
“Agora, portanto, fale aos homens de Judá e aos habitantes de Jerusalém, dizendo: 'Javé diz: “Eis que eu incrimino o mal contra ti, e invento um plano contra ti. Todos retornam agora de seu mau caminho, e emendam seus caminhos e seus atos”.
12 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Kò ṣe nǹkan kan, àwa yóò tẹ̀síwájú nínú èrò wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa, yóò hùwà agídí ọkàn búburú rẹ̀.’”
Mas eles dizem: 'É em vão; pois caminharemos após nossos próprios planos, e cada um seguirá a teimosia de seu coração maligno'”.
13 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: “Ẹ béèrè nínú orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá ti gbọ́ irú nǹkan wọ̀nyí ri? Ohun tí ó burú gidi ni wúńdíá Israẹli ti ṣe.
Portanto, diz Yahweh: “Pergunte agora entre as nações, Quem já ouviu tais coisas? A virgem de Israel tem feito uma coisa muito horrível.
14 Ǹjẹ́ omi ojo dídì Lebanoni yóò ha dá láti máa sàn láti ibi àpáta? Tàbí odò tí ó jìnnà, tí ó tútù, tí ó ń sàn, yóò ha gbẹ bí?
Será que a neve do Líbano falhará na rocha do campo? Será que as águas frias que descem de longe serão secas?
15 Nítorí àwọn ènìyàn mi gbàgbé mi, wọ́n sun tùràrí fún òrìṣà asán, tí ó mú wọn kọsẹ̀ ní ọ̀nà wọn, àti ọ̀nà wọn àtijọ́. Wọ́n mú wọn rìn ní ọ̀nà àtijọ́, àti ní ojú ọ̀nà ti a kò ṣe.
Pois meu povo me esqueceu. Eles queimaram incenso para falsos deuses. Eles têm sido obrigados a tropeçar em seus caminhos nos caminhos antigos, para entrar pelos caminhos, de uma forma não construída,
16 Ilẹ̀ wọn yóò wà lásán yóò sì di nǹkan ẹ̀gàn títí láé, gbogbo àwọn tí ó ń kọjá yóò bẹ̀rù, wọn yóò sì mi orí wọn.
para fazer de suas terras um espanto, e um assobio perpétuo. Todos que passarem por ela ficarão surpresos, e abanar a cabeça.
17 Gẹ́gẹ́ bí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn, Èmi yóò tú wọn ká lójú àwọn ọ̀tá wọn. Èmi yóò sì kọ ẹ̀yìn sí wọn, n kì yóò kọjú sí wọn ní ọjọ́ àjálù wọn.”
Vou espalhá-los como com um vento leste diante do inimigo. Vou mostrar-lhes as costas, e não o rosto, no dia de sua calamidade.
18 Wọ́n sọ wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ ṣọ̀tẹ̀ sí Jeremiah, nítorí òfin ìkọ́ni láti ẹnu àwọn àlùfáà kì yóò jásí asán, tàbí ìmọ̀ràn fún àwọn ọlọ́gbọ́n tàbí ọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì. Nítorí náà wá, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú pẹ̀lú ahọ́n wa, kí a má sì ṣe tẹ́tí sí ohunkóhun tí ó bá sọ.”
Então eles disseram: “Venha! Vamos elaborar planos contra Jeremias; pois a lei não perecerá do sacerdote, nem o conselho dos sábios, nem a palavra do profeta. Venha, e vamos golpeá-lo com a língua, e não vamos dar ouvidos a nenhuma de suas palavras”.
19 Dẹtí sí ọ̀rọ̀ mi Olúwa, gbọ́ ohun tí àwọn tí ó fi mí sùn ń sọ.
Preste atenção em mim, Yahweh, e ouvir a voz daqueles que lutam comigo.
20 Ṣe kí a fi rere san búburú? Síbẹ̀ wọ́n ti gbẹ́ kòtò fún mi. Rántí pé mo dúró níwájú rẹ, mo sì sọ̀rọ̀ nítorí wọn, láti yí ìbínú rẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
O mal deve ser recompensado pelo bem? Pois eles cavaram um poço para minha alma. Lembrem-se de como eu estava diante de vocês para falar bem por eles, para desviar deles a sua ira.
21 Nítorí náà, jẹ́ kí ìyàn mú ọmọ wọn jọ̀wọ́ wọn fún ọwọ́ idà jẹ́ kí ìyàwó wọn kí ó di aláìlọ́mọ àti opó jẹ́ kí a pa àwọn ọkùnrin wọn kí a sì fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn lójú ogun.
Portanto, entregam seus filhos à fome, e entregá-los ao poder da espada. Deixem suas esposas ficarem sem filhos e viúvas. Que seus homens sejam mortos e seus jovens atingidos pela espada em batalha.
22 Jẹ́ kí a gbọ́ ohùn ẹkún láti ilé wọn nígbà tí ó bá mu àwọn jagunjagun kọlù wọ́n lójijì nítorí wọ́n ti gbẹ́ kòtò láti mú mi. Wọ́n ti dẹ okùn fún ẹsẹ̀ mi.
Let um grito seja ouvido de suas casas quando você traz uma tropa de repente sobre eles; pois eles cavaram um poço para me levar e laços escondidos para os meus pés.
23 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa mọ gbogbo ète wọn láti pa mí, má ṣe dárí ẹ̀bi wọn jì wọ́n bẹ́ẹ̀ ni má ṣe pa ẹ̀ṣẹ̀ wọn rẹ́ kúrò lójú rẹ. Jẹ́ kí wọn kí ó ṣubú níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó sì ṣe sí wọn nígbà ìbínú rẹ.
Ainda assim, Javé, você conhece todos os conselhos deles contra mim para me matar. Não perdoe sua iniqüidade. Não apague o pecado deles de sua vista, Deixe-os ser derrubados diante de você. Lidar com eles no momento de sua raiva.

< Jeremiah 18 >