< Jeremiah 18 >
1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá wí pe:
Słowo, które doszło do Jeremiasza od PANA, mówiące:
2 “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé amọ̀kòkò, níbẹ̀ ni èmi yóò ti bá ọ sọ̀rọ̀.”
Wstań i zejdź do domu garncarza, a tam sprawię, że usłyszysz moje słowa.
3 Nígbà náà ni mo lọ sí ilé amọ̀kòkò mo sì rí i tí ó ń ṣiṣẹ́ kan lórí kẹ̀kẹ́.
Zstąpiłem więc do domu garncarza, a oto on wykonywał pracę na kole.
4 Ṣùgbọ́n ìkòkò tí ó ń mọ láti ara amọ̀ bàjẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀, nítorí náà ni amọ̀kòkò fi ṣe ìkòkò mìíràn, ó mọ ọ́n bí èyí tí ó dára jù ní ojú rẹ̀.
A naczynie, które wykonywał z gliny, uległo zniekształceniu w ręce garncarza. Uczynił więc z niej inne naczynie, jak mu się podobało uczynić.
5 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
6 “Ẹyin ilé Israẹli, èmi kò ha lè ṣe fún un yín gẹ́gẹ́ bí amọ̀kòkò yìí ti ṣe?” ni Olúwa wí. “Gẹ́gẹ́ bí amọ̀ ní ọwọ́ amọ̀kòkò bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin rí ní ọwọ́ mi, ẹ̀yin ilé Israẹli.
Czyż nie mogę z wami postąpić tak jak ten garncarz, domu Izraela? – mówi PAN. Oto jak glina w ręce garncarza tak wy jesteście w moim ręku, domu Izraela.
7 Bí ó bá jẹ́ ìgbà kan, tí èmi kéde kí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan di fífà tu láti dojúdé àti láti parun,
Gdy raz ogłoszę przeciwko narodowi i przeciwko królestwu, że je wykorzenię, wywrócę i zniszczę;
8 tí orílẹ̀-èdè ti mo kìlọ̀ fún bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú wọn, nígbà náà ni Èmi yóò yí ọkàn mi padà nínú àjálù tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.
A jednak ten naród, przeciw któremu mówiłem, odwróci się od swojego zła, będę żałował nieszczęścia, które zamierzam na niego zesłać.
9 Ní ìgbà mìíràn tí èmi bá tún kéde láti tẹ̀dó tàbí gbin orílẹ̀-èdè kan tàbí ìjọba kan.
Gdy innym razem ogłoszę o narodzie i o królestwie, że je zbuduję i zasadzę;
10 Bí ó bá sì ṣe búburú níwájú mi, tí kò sì gba ohùn mi gbọ́, nígbà náà ni èmi yóò yí ọkàn mi padà ní ti rere, èyí tí mo wí pé, èmi ó ṣe fún wọn.
Jeśli jednak uczyni to, co złe w moich oczach i nie usłucha mego głosu, ja będę żałował tego dobrodziejstwa, jakim obiecałem je obdarzyć.
11 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, sọ fún àwọn ènìyàn Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa wí: Wò ó! Èmi ń gbèrò ibi sí yin, èmi sì ń ṣe ìpinnu kan lórí yín. Nítorí náà ẹ yípadà kúrò lọ́nà búburú yín kí olúkúlùkù yín sì tún ọ̀nà àti ìṣe rẹ̀ ṣe.’
Dlatego powiedz teraz do Judejczyków i do mieszkańców Jerozolimy: Tak mówi PAN: Oto przygotowuję na was nieszczęście i obmyślam zamysł przeciwko wam. Niech więc każdy zawróci ze swojej złej drogi; poprawcie wasze drogi i czyny.
12 Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Kò ṣe nǹkan kan, àwa yóò tẹ̀síwájú nínú èrò wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa, yóò hùwà agídí ọkàn búburú rẹ̀.’”
Ale [oni] odpowiedzieli: Nic z tego. Pójdziemy raczej za własnymi zamysłami, każdy będzie postępował według uporu swego złego serca.
13 Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: “Ẹ béèrè nínú orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá ti gbọ́ irú nǹkan wọ̀nyí ri? Ohun tí ó burú gidi ni wúńdíá Israẹli ti ṣe.
Dlatego tak mówi PAN: Zapytajcie teraz wśród pogan, czy ktoś słyszał coś takiego. Straszny czyn popełniła dziewica Izraela.
14 Ǹjẹ́ omi ojo dídì Lebanoni yóò ha dá láti máa sàn láti ibi àpáta? Tàbí odò tí ó jìnnà, tí ó tútù, tí ó ń sàn, yóò ha gbẹ bí?
Czy [człowiek] opuści śnieg ze skalistych pól Libanu? Czy ktoś opuści zimne wody płynące z daleka?
15 Nítorí àwọn ènìyàn mi gbàgbé mi, wọ́n sun tùràrí fún òrìṣà asán, tí ó mú wọn kọsẹ̀ ní ọ̀nà wọn, àti ọ̀nà wọn àtijọ́. Wọ́n mú wọn rìn ní ọ̀nà àtijọ́, àti ní ojú ọ̀nà ti a kò ṣe.
Ale mój lud zapomniał o mnie, pali kadzidło marnościom, [które sprawiły, że] potyka się na swoich drogach, na starodawnych ścieżkach, by chodzić po ścieżkach, [po] drodze nieutorowanej;
16 Ilẹ̀ wọn yóò wà lásán yóò sì di nǹkan ẹ̀gàn títí láé, gbogbo àwọn tí ó ń kọjá yóò bẹ̀rù, wọn yóò sì mi orí wọn.
Aby zamienić swoją ziemię w spustoszenie, w wieczne świstanie. Każdy, kto będzie przez nią przechodził, zdumieje się i będzie kiwał głową.
17 Gẹ́gẹ́ bí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn, Èmi yóò tú wọn ká lójú àwọn ọ̀tá wọn. Èmi yóò sì kọ ẹ̀yìn sí wọn, n kì yóò kọjú sí wọn ní ọjọ́ àjálù wọn.”
Jak wschodni wiatr rozproszę ich przed wrogiem. Pokażę im plecy, a nie twarz w dniu ich zatracenia.
18 Wọ́n sọ wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ ṣọ̀tẹ̀ sí Jeremiah, nítorí òfin ìkọ́ni láti ẹnu àwọn àlùfáà kì yóò jásí asán, tàbí ìmọ̀ràn fún àwọn ọlọ́gbọ́n tàbí ọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì. Nítorí náà wá, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú pẹ̀lú ahọ́n wa, kí a má sì ṣe tẹ́tí sí ohunkóhun tí ó bá sọ.”
I powiedzieli: Chodźcie, obmyślmy zamysły przeciwko Jeremiaszowi, bo nie zaginie prawo od kapłana, ani rada od mądrego, ani słowo od proroka. Chodźcie, uderzmy go językiem i nie zważajmy na żadne jego słowa.
19 Dẹtí sí ọ̀rọ̀ mi Olúwa, gbọ́ ohun tí àwọn tí ó fi mí sùn ń sọ.
Zważaj na mnie, PANIE, i słuchaj głosu tych, którzy się spierają ze mną.
20 Ṣe kí a fi rere san búburú? Síbẹ̀ wọ́n ti gbẹ́ kòtò fún mi. Rántí pé mo dúró níwájú rẹ, mo sì sọ̀rọ̀ nítorí wọn, láti yí ìbínú rẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Czy odpłaca się złem za dobro? Bo wykopali dół dla mojej duszy. Wspomnij, że stawałem przed tobą, aby mówić za nimi dla ich dobra i odwrócić od nich twój gniew.
21 Nítorí náà, jẹ́ kí ìyàn mú ọmọ wọn jọ̀wọ́ wọn fún ọwọ́ idà jẹ́ kí ìyàwó wọn kí ó di aláìlọ́mọ àti opó jẹ́ kí a pa àwọn ọkùnrin wọn kí a sì fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn lójú ogun.
Dlatego wydaj ich dzieci na głód i spraw, aby padli od mocy miecza; niech ich żony będą osierocone i owdowiałe, ich mężczyźni haniebnie uśmierceni, a ich młodzieńcy zabici mieczem na wojnie.
22 Jẹ́ kí a gbọ́ ohùn ẹkún láti ilé wọn nígbà tí ó bá mu àwọn jagunjagun kọlù wọ́n lójijì nítorí wọ́n ti gbẹ́ kòtò láti mú mi. Wọ́n ti dẹ okùn fún ẹsẹ̀ mi.
Niech będzie słychać krzyk z ich domów, gdy nagle sprowadzisz na nich wojsko. Wykopali bowiem dół, aby mnie schwytać, zastawili sidła na moje nogi.
23 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa mọ gbogbo ète wọn láti pa mí, má ṣe dárí ẹ̀bi wọn jì wọ́n bẹ́ẹ̀ ni má ṣe pa ẹ̀ṣẹ̀ wọn rẹ́ kúrò lójú rẹ. Jẹ́ kí wọn kí ó ṣubú níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó sì ṣe sí wọn nígbà ìbínú rẹ.
Lecz ty, PANIE, znasz wszystkie ich plany przeciwko mnie, [chcą] mojej śmierci. Nie przebaczaj im ich nieprawości, a ich grzechu nie zmaż sprzed swego oblicza, ale niech upadną przed tobą. Postąp z nimi [tak] w czasie twojego gniewu.