< Jeremiah 17 >
1 “Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
Yǝⱨudaning gunaⱨi almas uqluⱪ tɵmür ⱪǝlǝm bilǝn taxtahtay kǝbi yürǝklirigǝ wǝ ⱪurbangaⱨliridiki münggüzlǝrgǝ oyulƣan;
2 Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
balilirimu yexil dǝrǝhlǝr boyida tiklǝngǝn, egiz dɵnglǝr üstidǝ yasiƣan [butlirining] ⱪurbangaⱨlirini wǝ «Axǝraⱨ»lirini ⱨǝrdaim seƣinidu.
3 Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
Mǝn taƣliringlarda wǝ etizliringlarda, ⱨǝm bayliⱪliringni ⱨǝm hǝziniliringni, — sening «yuⱪiri jaylar»ingmu buning sirtida ǝmǝs — bu qetingdin u qetinggiqǝ bolƣan gunaⱨing tüpǝylidin olja boluxⱪa tapxurimǝn;
4 Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
Ɵzüngning xori, Mǝn sanga tǝⱪdim ⱪilƣan mirasing ⱪolungdin ketidu; Mǝn sǝn tonumaydiƣan bir zeminda seni düxmǝnliringning ⱪulluⱪiƣa tapxurimǝn; qünki silǝr ƣǝzipimgǝ ot yeⱪip uni ⱪozƣiƣansilǝr; u mǝnggügǝ kɵyidu.
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — — Adǝmgǝ tayanƣan, adǝmning ǝt-küqini tayanqi ⱪilƣan, ⱪǝlbi Pǝrwǝrdigardin qǝtnigǝn adǝmning ⱨaliƣa lǝnǝt bolsun!
6 Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
U qɵl-bayawanda ɵskǝn ⱪara arqa qatⱪilidǝk bolidu; bǝht-yahxiliⱪ kǝlsimu u buni kɵrmǝydu; u bǝlki qɵldiki ⱪaƣjiraⱪ yǝrlǝrdǝ, adǝmzatsiz xorluⱪ bir zeminda turidu.
7 “Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
Pǝrwǝrdigarƣa tayanƣan, Pǝrwǝrdigarni tayanq ⱪilƣan adǝm bǝht-bǝrikǝtlik bolidu!
8 Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
U sular boyida tiklǝngǝn, eriⱪ boyida kǝng yiltiz tartⱪan dǝrǝhdǝk; piȥƣirim issiⱪtin u ⱪorⱪmaydu; uning yopurmaⱪliri ⱨǝmixǝ yexildur; ⱪurƣaⱪqiliⱪ yili u solaxmaydu wǝ mewǝ berixtin ⱪalmaydu.
9 Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
Ⱪǝlb ⱨǝmmidin aldamqi, uning dawasi yoⱪtur. Kimmu uni qüxinǝlisun?
10 “Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
Mǝnki Pǝrwǝrdigar insan ⱪǝlbini kɵzitip tǝkxürimǝn; ⱨǝrbirsigǝ ɵz yolliri boyiqǝ, ⱪilƣan ǝmǝllirining mewisi boyiqǝ tǝⱪsim ⱪilix üqün, insan wijdanini sinaymǝn.
11 Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
Huddi ɵzi tuƣmiƣan tuhumlarni besiwalƣan kǝkliktǝk, ⱨaramdin bayliⱪlarƣa erixkǝn kiximu xundaⱪ bolidu; künlirining yerimi ɵtmǝyla erixkinidin ayrilidu, u ahirida ǝhmǝⱪ bolup qiⱪidu.
12 Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
Xan-xǝrǝplik bir tǝht, ǝzǝldin yuⱪiriƣa tiklǝngǝn, dǝl bizning baxpanaⱨimiz bolƣan jaydur;
13 Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
i Pǝrwǝrdigar, Sǝn Israilning ümidisǝn! Sǝndin waz kǝqkǝn ⱨǝmmǝylǝn yǝrgǝ ⱪarap ⱪalidu; Sǝndin yiraⱪlaxⱪanlar tupraⱪta yatⱪanlar arisida tizimlinidu; qünki ular ⱨayatliⱪ sulirining mǝnbǝsi bolƣan Pǝrwǝrdigardin waz kǝqkǝn.
14 Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
Meni saⱪaytⱪin, i Pǝrwǝrdigar, mǝn xuning bilǝn jǝzmǝn saⱪaytilimǝn! Meni ⱪutⱪuzƣin, xuning bilǝn jǝzmǝn ⱪutⱪuzulimǝn! — Qünki Ɵzüng mening mǝdⱨiyǝmdursǝn!
15 Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
Mana, ular manga: — Pǝrwǝrdigarning sɵz-bexariti ⱪeni?! Ⱪeni, u ǝmǝlgǝ axurulsun!» — dǝydu.
16 Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
Lekin mǝn bolsam, Sanga ǝgǝxkinimdǝ «pada baⱪⱪuqi» boluxtin ⱨeq ⱪaqⱪan ǝmǝsmǝn, wǝ ǝjǝl künini ⱨeq arzu ⱪilmiƣanmǝn, — Sǝn bilisǝn! Aƣzimdin barliⱪ qiⱪⱪanlar Sening yüz aldingda bolƣan.
17 Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
Manga wǝⱨimǝ bolmiƣaysǝn; külpǝtlik künidǝ Sǝn mening baxpanaⱨimdursǝn.
18 Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
Manga ziyankǝxlik ⱪilƣuqilar yǝrgǝ ⱪarap ⱪalsun, lekin meni yǝrgǝ ⱪaratmiƣaysǝn! Ular dǝkkǝ-dükkigǝ qüxsun, lekin meni dǝkkǝ-dükkigǝ qüxürmigǝysǝn; ularning bexiƣa külpǝt künini qüxürgǝysǝn; ularni ikki ⱨǝssilik ⱨalakǝt bilǝn üzül-kesil paqaⱪlap taxliƣaysǝn!
19 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
Pǝrwǝrdigar manga mundaⱪ degǝn: — Barƣin, Yǝⱨuda padixaⱨliri xǝⱨǝrgǝ kiridiƣan wǝ qiⱪidiƣan «Hǝlⱪning baliliri» degǝn dǝrwazida, ⱨǝmdǝ Yerusalemning barliⱪ dǝrwazilirida turƣin, ularƣa mundaⱪ degin: —
20 Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
Pǝrwǝrdigarning sɵzini anglanglar, i muxu dǝrwazilardin kiridiƣan Yǝⱨudaning padixaⱨliri, barliⱪ Yǝⱨuda wǝ Yerusalemda turuwatⱪan halayiⱪ!
21 Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Ɵz jeninglarƣa ⱨezi bolunglar! «xabat» künidǝ ⱨeqⱪandaⱪ yükni kɵtürmǝnglar, Yerusalemning dǝrwaziliridin ⱨeqnǝrsini epkirmǝnglar;
22 Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
xabat künliridǝ ɵyliringlardin ⱨeq yükni kɵtürüp elip qiⱪmanglar, wǝ ⱨeqⱪandaⱪ ǝmgǝk ⱪilmanglar; bǝlki Mǝn ata-bowiliringlarƣa buyruƣinimdǝk, xabat künini Ɵzümgǝ atalƣan muⱪǝddǝs bir kün dǝp ⱪaranglar.
23 Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
Lekin ular ⱨeq anglimiƣan yaki ⱪulaⱪ salmiƣan, bǝlki anglimasliⱪⱪa ⱨǝm tǝrbiyini ⱪobul ⱪilmasliⱪⱪa boynini ⱪattiⱪ ⱪilƣan.
24 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
Xundaⱪ boliduki, silǝr awazimni kɵngül ⱪoyup anglisanglar, — dǝydu Pǝrwǝrdigar, — yǝni xabat künidǝ xǝⱨǝr dǝrwaziliridin ⱨeq yükni elip kirmisǝnglar wǝ ⱨeq ǝmgǝk ⱪilmasliⱪ arⱪiliⱪ xabat künini Manga pak-muⱪǝddǝs bir kün ⱨesablisanglar,
25 Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
bu xǝⱨǝr dǝrwaziliridin Dawutning tǝhtigǝ olturidiƣan padixaⱨliri wǝ ǝmirliri jǝng ⱨarwiliriƣa olturup wǝ atlarƣa minip kiridu; ular, ularning ǝmirliri, Yǝⱨudadikilǝr wǝ Yerusalemda turuwatⱪanlarmu kirip-qiⱪixidu; bu xǝⱨǝr mǝnggü awat bolidu.
26 Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
Xundaⱪ ⱪilsanglar, hǝlⱪlǝr Yǝⱨuda xǝⱨǝrliridin, Yerusalem ǝtrapidiki yezilardin, Binyaminning zeminidin, [ƣǝrbtiki] «Xǝfǝlaⱨ» egizlikidin, jǝnubtiki [taƣliⱪtin], Yǝⱨudadiki jǝnubiy bayawanlardin Pǝrwǝrdigarning ɵyigǝ «kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪ»lar, «inaⱪliⱪ ⱪurbanliⱪliri», «axliⱪ ⱨǝdiyǝ»lǝr wǝ huxbuylarni tutup, [Pǝrwǝrdigarƣa bolƣan] rǝⱨmǝtlirini eytixⱪa kiridiƣan bolidu.
27 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”
Lekin silǝr Manga ⱪulaⱪ salmisanglar, yǝni xabat künini Ɵzümgǝ pak-muⱪǝddǝs ⱨesablimay, xabat künidǝ Yerusalemning dǝrwaziliridin yük kɵtürüp kirsǝnglar, ǝmdi Mǝn dǝrwazilarƣa bir ot yaⱪimǝn, u Yerusalemdiki ordilarni yǝwetidu, uni ⱨeq ɵqürǝlmǝydu.