< Jeremiah 17 >

1 “Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
Juda synd är uppskriven med järnstift, med diamantgriffel; den är inristad på deras hjärtas tavla och på edra altarens horn,
2 Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
så visst som deras barn vid gröna träd och på höga kullar komma ihåg sina altaren och Aseror.
3 Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
Du mitt berg på fältet, ditt gods, ja, alla dina skatter skall jag lämna till plundring, så ock dina offerhöjder, till straff för vad du har syndat i hela ditt land.
4 Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
Och du skall nödgas avstå -- och detta genom din egen förskyllan -- från den arvedel som jag har givit dig; och jag skall låta dig tjäna dina fiender i ett land som du icke känner. Ty I haven upptänt min vredes eld, och den skall brinna till evig tid.
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
Så säger HERREN: Förbannad är den man som förtröstar på människor och sätter kött sig till arm och med sitt hjärta viker av ifrån HERREN.
6 Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
Han skall bliva såsom en torr buske på hedmarken och skall icke få se något gott komma, utan skall bo på förbrända platser i öknen, i ett land med salthedar, där ingen bor.
7 “Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
Men välsignad är den man som förtröstar på HERREN, den som har HERREN till sin förtröstan.
8 Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
Han är lik ett träd som är planterat vid vatten, och som sträcker ut sina rötter till bäcken; ty om än hetta kommer, så förskräckes det icke, utan bevarar sina löv grönskande; och om ett torrt år kommer, så sörjer det icke och upphör ej heller att bara frukt.
9 Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
Ett illfundigt och fördärvat ting är hjärtat framför allt annat; vem kan förstå det?
10 “Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
Dock, Jag, HERREN, utrannsakar hjärtat och prövar njurarna, och giver så åt var och en efter hans vägar, efter hans gärningars frukt.
11 Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
Lik en rapphöna som ruvar på ägg, vilka hon ej själv har lagt, är den som samlar rikedom med orätt; i sina halva dagar måste han lämna den och vid sitt slut skall han stå såsom en dåre.
12 Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
En härlighetens tron, en urgammal höjd är vår helgedoms plats.
13 Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
HERREN är Israels hopp; alla som övergiva dig komma på skam. de som vika av ifrån mig likna en skrift i sanden; ty de hava övergivit HERREN, källan med det friska vattnet.
14 Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
Hela du mig, HERRE, så varde jag helad; fräls mig du, så varder jag frälst. Ty du är mitt lov.
15 Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
Se, dessa säga till mig: »Vad bliver av HERRENS ord? Må det fullbordas!»
16 Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
Det är ju så, att jag ej har undandragit mig herdekallet i din efterföljd, och fördärvets dag har jag icke åstundat; du vet det själv. Vad mina läppar hava uttalat, det har talats inför ditt ansikte.
17 Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
Så bliv då icke till skräck för mig; du som är min tillflykt på olyckans dag.
18 Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
Låt dem som förfölja mig komma på skam, men låt icke mig komma på skam; låt dem bliva förfärade, men låt ej mig bliva förfärad. Låt en olycksdag komma över dem, och krossa dem i dubbelt mått.
19 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
Så sade HERREN till mig: Gå åstad och ställ dig i Menighetsporten, där Juda konungar gå in och gå ut, och sedan i Jerusalems alla andra portar;
20 Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
och säg till dem: Hören HERRENS ord, I Juda konungar med hela Juda, och I alla Jerusalems invånare som gån in genom dessa portar.
21 Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
Så säger HERREN: Tagen eder val till vara för att på sabbatsdagen bära någon börda eller föra in någon sådan genom Jerusalems portar.
22 Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
Och fören icke på sabbatsdagen någon börda ut ur edra hus, och gören ej heller något annat arbete, utan helgen sabbatsdagen, såsom jag bjöd edra fäder,
23 Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
fastän de icke ville höra eller böja sitt öra därtill, utan voro hårdnackade, så att de icke hörde eller togo emot tuktan.
24 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
Men om I viljen höra mig, säger HERREN, så att I på sabbatsdagen icke fören någon börda in genom denna stads portar, utan helgen sabbatsdagen, så att I på den icke gören något arbete,
25 Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
då skola konungar och furstar som komma att sitta på Davids tron få draga in genom denna stads portar, på vagnar och hästar, följda av sina furstar, av Juda man och Jerusalems invånare; och denna stad skall då förbliva bebodd evinnerligen.
26 Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
Och från Juda städer, från Jerusalems omnejd och från Benjamins land, från Låglandet, Bergsbygden och Sydlandet skall man komma och frambära brännoffer, slaktoffer, spisoffer och rökelse och frambära lovoffer till HERRENS hus.
27 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”
Men om I icke hören mitt bud att helga sabbaten och att icke bära någon börda in genom Jerusalems portar på sabbatsdagen, då skall jag tända eld på dess portar, och elden skall förtära Jerusalems palatser och skall icke kunna utsläckas.

< Jeremiah 17 >