< Jeremiah 17 >

1 “Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
»Judov greh je zapisan z železnim peresom in z diamantno konico. Ta je vrezan na ploščo njihovega srca in na rogove njihovih oltarjev,
2 Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
medtem ko se njihovi otroci spominjajo njihovih oltarjev in njihovih ašer pri zelenih drevesih na visokih hribih.
3 Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
Oh moja gora na polju, tvoje imetje in vse tvoje zaklade bom izročil v plen in tvoje visoke kraje zaradi greha, po vseh tvojih mejah.
4 Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
Ti pa, celo ti sam, boš odpravljen od svoje dediščine, ki sem ti jo dal in povzročil ti bom, da služiš svojim sovražnikom v deželi, ki je ne poznaš, kajti zanetili ste ogenj v moji jezi, ki bo gorel na veke.«
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
Tako govori Gospod: »Preklet bodi človek, ki zaupa v moža in postavlja osebo [za] svoj laket in katerega srce odhaja od Gospoda.
6 Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
Kajti podoben bo brinu v puščavi in ne bo videl, ko prihaja dobro, temveč bo naselil izsušene kraje v divjini, v slani in nenaseljeni deželi.
7 “Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
Blagoslovljen je človek, ki zaupa v Gospoda in čigar upanje je v Gospodu.
8 Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
Kajti on bo kakor drevo, posajeno ob vodah in ki razširja svoje korenine ob reki in ne bo videlo, ko prihaja vročina, temveč bo njegovo listje zeleno; v sušnem letu ne bo zaskrbljeno niti ne bo prenehalo rojevati sadu.
9 Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
Srce je varljivo nad vsemi stvarmi in obupno zlobno. Kdo ga lahko spozna?
10 “Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
Jaz, Gospod, preiskujem srce, jaz preizkušam notranjost, celó da vsakemu človeku dam glede na njegove poti in glede na sad njegovih dejanj.
11 Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
Kakor jerebica sedi na jajcih, ki jih ni znesla, tako tisti, ki pridobiva bogastva, pa ne po pravici, jih bo zapustil v sredi svojih dni in ob svojem koncu bo bedak.«
12 Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
Veličasten visok prestol od začetka je prostor našega svetišča.
13 Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
Oh Gospod, Izraelovo upanje, vsi, ki te zapustijo, bodo osramočeni in tisti, ki odidejo od mene, bodo zapisani v zemljo, ker so zapustili Gospoda, studenec živih vodá.
14 Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
Ozdravi me, oh Gospod in jaz bom ozdravljen, reši me in jaz bom rešen, kajti ti si moja hvala.
15 Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
Glej, pravijo mi: »Kje je beseda od Gospoda? Naj ta sedaj pride.«
16 Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
Kar se mene tiče, nisem hitel pred tem, da bi bil pastir, da ti sledim. Niti si nisem želel dneva, polnega gorja; ti veš. To, kar je prišlo iz mojih ustnic, je bilo pred teboj pravilno.
17 Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
Ne bodi mi strahota. Ti si moje upanje v dnevu zla.
18 Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
Naj bodo zbegani [tisti], ki me preganjajo, toda jaz naj ne bom zbegan. Naj bodo zaprepadeni, toda jaz naj ne bom zaprepaden. Nanje privedi dan zla in jih uniči z dvojnim uničenjem.
19 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
Tako mi je rekel Gospod: »Pojdi in stoj v velikih vratih otrok ljudstva, pri katerih Judovi kralji vstopajo in pri katerih gredo ven in v vseh jeruzalemskih velikih vratih
20 Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
in jim reci: ›Poslušajte Gospodovo besedo, vi Judovi kralji in ves Juda in vsi prebivalci Jeruzalema, ki vstopate pri teh velikih vratih.
21 Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
Tako govori Gospod: ›Pazite nase in na šabatni dan ne prenašajte nobenega bremena niti tega ne prinašajte noter pri jeruzalemskih velikih vratih.
22 Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
Niti ne prinašajte bremena iz svojih hiš na šabatni dan niti ne počnite nobenega dela, temveč posvečujte šabatni dan, kakor sem zapovedal vašim očetom.
23 Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
Toda niso ubogali niti niso nagnili svojega ušesa, temveč so otrdili svoj vrat, da ne bi niti slišali niti prejeli poučevanja.
24 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
In zgodilo se bo, če mi boste marljivo prisluhnili, ‹ govori Gospod, ›da ne prinašate nobenega bremena skozi velika vrata tega mesta na šabatni dan, temveč posvečujete šabatni dan, da v tem [dnevu] ne delate nobenega dela,
25 Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
potem bodo tam, v velika vrata tega mesta, vstopali kralji in princi, sedeč na Davidovem prestolu, jahajoč na bojnih vozovih in konjih, oni in njihovi princi, Judovi možje in prebivalci Jeruzalema; in to mesto bo ostalo na veke.
26 Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
Prišli bodo iz Judovih mest in iz krajev okoli Jeruzalema in iz Benjaminove dežele in ravnine in z gora in iz juga, prinašajoč žgalne daritve, klavne daritve, jedilne daritve in kadilo ter prinašajoč daritve hvale v Gospodovo hišo.
27 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”
Toda če mi ne boste prisluhnili, da posvečujete šabatni dan in da ne nosite bremena, celo ko vstopate pri jeruzalemskih velikih vratih na šabatni dan, potem bom zanetil ogenj v njegovih velikih vratih in ta bo požrl jeruzalemske palače in ne bo pogašen.‹«

< Jeremiah 17 >