< Jeremiah 17 >
1 “Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
Păcatul lui Iuda este scris cu un toc de fier și cu vârful unui diamant; este gravat pe tăblița inimii lor și pe coarnele altarelor voastre;
2 Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
În timp ce copiii lor își amintesc de altarele lor și de altarele lor lângă copacii verzi de pe dealurile înalte.
3 Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
O, muntele meu în câmp, eu voi da averea ta și toate tezaurele tale ca pradă, și înălțimile tale pentru păcat, în toate granițele tale.
4 Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
Și tu, chiar tu însuți, vei renunța la moștenirea ta pe care ți-o dădusem; și te voi face să servești dușmanilor tăi în țara pe care nu o cunoști, pentru că ați aprins în mânia mea un foc, ce va arde pentru totdeauna.
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
Astfel spune DOMNUL: Blestemat fie omul care se încrede în om și care își face carnea braț al său și a cărui inimă se depărtează de DOMNUL.
6 Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
Fiindcă el va fi ca un rug într-un loc uscat, și nu va vedea când vine binele; ci va locui în locurile arse ale pustiei, într-un pământ sărat și nelocuit.
7 “Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
Binecuvântat este omul care se încrede în DOMNUL și a cărui speranță este DOMNUL.
8 Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
Pentru că el va fi ca un copac sădit lângă ape și care își întinde rădăcinile lângă râu și nu va vedea când vine arșița, ci frunza lui va fi verde; și nu se va îngrijora în anul de secetă, nici nu va înceta de la a da rod.
9 Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
Inima [este] mai înșelătoare decât toate și este nespus de stricată: cine o poate cunoaște?
10 “Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
Eu DOMNUL cercetez inima, eu încerc rărunchii, ca să dau fiecărui om conform căilor lui și conform rodului facerilor sale.
11 Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
Precum potârnichea clocește ouă pe care nu le-a făcut, astfel cel care obține bogății, dar nu pe drept, le va lăsa la jumătatea zilelor lui și la sfârșitul lui va fi un nebun.
12 Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
Un tron înalt glorios de la început este locul sanctuarului nostru.
13 Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
DOAMNE, speranța lui Israel, toți cei care te părăsesc vor fi rușinați, și cei care se depărtează de mine vor fi scriși pe pământ, pentru că l-au părăsit pe DOMNUL, fântâna apelor vii.
14 Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
Vindecă-mă, DOAMNE, și voi fi vindecat; salvează-mă, și voi fi salvat, pentru că tu ești lauda mea.
15 Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
Iată, ei îmi spun: Unde este cuvântul DOMNULUI? Să vină acum.
16 Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
Cât despre mine, eu nu m-am grăbit să încetez a fi un păstor care te urmează; nici nu am dorit eu ziua cea jalnică; tu știi; ceea ce a ieșit de pe buzele mele a fost drept înaintea ta.
17 Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
Nu fi o teroare pentru mine: tu ești speranța mea în ziua răului.
18 Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
Să fie încurcați cei care mă persecută, dar nu mă lăsa să fiu eu încurcat; să fie ei descurajați, dar să nu fiu eu descurajat; adu asupra lor ziua răului și nimicește-i cu o dublă nimicire.
19 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
Astfel mi-a spus DOMNUL: Du-te și stai în picioare la poarta copiilor poporului, prin care împărații lui Iuda intră și prin care ei ies afară, și la toate porțile Ierusalimului;
20 Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
Și spune-le: Ascultați cuvântul DOMNULUI, voi împărați ai lui Iuda și tot Iuda și toți locuitorii Ierusalimului, care intrați pe aceste porți;
21 Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
Astfel spune DOMNUL: Luați seama la voi înșivă și nu purtați nicio povară în ziua sabatului, nici nu o aduceți pe porțile Ierusalimului;
22 Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
Nici nu scoateți vreo povară din casele voastre în ziua sabatului, nici nu faceți vreo lucrare, ci sfințiți ziua sabatului, precum am poruncit părinților voștri.
23 Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
Dar ei nu au făcut ce am poruncit, nici nu și-au plecat urechea, ci și-au înțepenit gâtul, ca să nu audă, nici să nu primească instruire.
24 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
Și se va întâmpla, spune DOMNUL, dacă îmi veți da ascultare cu atenție, să nu aduceți vreo povară pe porțile acestei cetăți în ziua sabatului, ci să sfințiți ziua sabatului, pentru a nu face nicio lucrare în ea;
25 Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
Atunci vor intra pe porțile cetății acesteia împărați și prinți șezând pe tronul lui David, stând în care și pe cai, ei și prinții lor, bărbații lui Iuda și locuitorii Ierusalimului; și această cetate va rămâne pentru totdeauna.
26 Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
Și ei vor veni din cetățile lui Iuda și din locurile de lângă Ierusalim și din țara lui Beniamin și de la câmpie și din munți și de la sud, aducând ofrande arse și sacrificii și daruri de mâncare și tămâie și aducând sacrificii de laudă în casa DOMNULUI.
27 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”
Dar dacă nu îmi veți da ascultare pentru a sfinți ziua sabatului și a nu purta vreo povară, chiar intrând pe porțile Ierusalimului în ziua sabatului; atunci voi aprinde un foc la porțile lui care va mistui palatele Ierusalimului și nu va fi stins.