< Jeremiah 17 >

1 “Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
Isono sakoJuda sibhaliwe ngepheni yensimbi, ngomcijo wendayimana; sibhalwe ngokugujwa esibhebheni senhliziyo yabo, lezimpondweni zamalathi enu;
2 Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
abantwana babo besakhumbula amalathi abo lezixuku zabo ngasezihlahleni eziluhlaza phezu kwamaqaqa aphakemeyo.
3 Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
Wena ntaba yami esegangeni, ngizanikela imfuyo yakho lakho konke okuligugu kwakho empangweni, lezindawo zakho eziphakemeyo, ngenxa yesono kuyo yonke imingcele yakho.
4 Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
Lawe, ngitsho ngokwakho, uzayekela ilifa lakho engakunika lona; njalo ngizakwenza usebenzele izitha zakho elizweni ongalaziyo; ngoba usuphembe umlilo ekuthukutheleni kwami; uzavutha kuze kube nininini.
5 Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
Itsho njalo iNkosi: Uqalekisiwe umuntu othembela emuntwini, esenza inyama ibe yingalo yakhe, lonhliziyo yakhe iphambuka eNkosini.
6 Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
Ngoba uzakuba njengesihlahlanyana enkangala, esingayikubona nxa okuhle kusiza; kodwa uzahlala ezindaweni ezomileyo enkangala, elizweni letshwayi, elingahlalwayo.
7 “Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
Ubusisiwe umuntu othembela eNkosini, lothemba lakhe liyiNkosi.
8 Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
Ngoba uzakuba njengesihlahla esihlanyelwe ngasemanzini, esinabisela impande zaso ngasemfuleni, esingesabi lapho kufika ukutshisa, kodwa ihlamvu laso lizakuba luhlaza; kasikhathazeki emnyakeni wokubalela, kasiyekeli ukuthela isithelo.
9 Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
Inhliziyo ilenkohliso okwedlula konke, futhi imbi kakhulu; ngubani ongayazi?
10 “Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
Mina Nkosi ngihlola inhliziyo, ngilinge izinso, ngitsho ukupha wonke umuntu njengokwezindlela zakhe, njengokwesithelo sezenzo zakhe.
11 Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
Njengethendele elifukamela amaqanda lingawachamuseli, unjalo lowo owenza inotho kodwa hatshi ngokulunga; uzakutshiya phakathi kwensuku zakhe, lekucineni kwakhe abe yisithutha.
12 Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
Isihlalo sobukhosi esilenkazimulo, esiphakanyisiweyo kwasekuqaleni, siyindawo yendlu yethu engcwele.
13 Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
Nkosi, themba likaIsrayeli, bonke abakudelayo bazayangeka; labasuka kimi bazabhalwa emhlabathini, ngoba bayidelile iNkosi, umthombo wamanzi aphilayo.
14 Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
Ngisilisa, Nkosi, njalo ngizasila; ngisindisa, njalo ngizasindiswa; ngoba uyindumiso yami.
15 Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
Khangela, bathi kimi: Lingaphi ilizwi leNkosi? Kalize khathesi!
16 Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
Kodwa mina kangiphangisanga ukuthi ngingabi ngumelusi emva kwakho; futhi kangilufisanga usuku olwesabekayo; wena uyakwazi; okwaphuma emlonyeni wami kwakuphambi kobuso bakho.
17 Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
Ungabi luvalo kimi; wena uyisiphephelo sami osukwini lobubi.
18 Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
Kabayangeke labo abangizingelayo, kodwa mina kangingayangeki, kabesabe bona, kodwa mina kangingesabi; behlisele usuku lobubi, ubephule ngokwephula okuphindiweyo.
19 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
Itsho njalo iNkosi kimi: Hamba uyekuma esangweni labantwana babantu, angena ngalo amakhosi akoJuda, aphuma ngalo, lakuwo wonke amasango eJerusalema,
20 Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
ubususithi kubo: Zwanini ilizwi leNkosi, lina makhosi akoJuda, loJuda wonke, labo bonke abahlali beJerusalema, abangena ngala amasango!
21 Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
Itsho njalo iNkosi: Ziqapheleni, lingathwali mthwalo ngosuku lwesabatha, kumbe liwungenise ngamasango eJerusalema.
22 Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
Futhi lingakhuphi umthwalo ezindlini zenu ngosuku lwesabatha, lingenzi loba yiwuphi umsebenzi; kodwa lungcweliseni usuku lwesabatha, njengalokhu ngalaya oyihlo.
23 Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
Kodwa kabalalelanga, kababekanga indlebe yabo, kodwa benza intamo yabo yaba lukhuni ukuze bangezwa, lokuze bangemukeli ukulaywa.
24 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
Kuzakuthi-ke uba lina lingilalela lokungilalela, itsho iNkosi, ukuthi lingangenisi mthwalo ngamasango alumuzi ngosuku lwesabatha, kodwa lilungcwelise usuku lwesabatha, ukuthi lingenzi loba yiwuphi umsebenzi ngalo;
25 Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
khona kuzangena ngamasango alumuzi amakhosi leziphathamandla abahlala esihlalweni sobukhosi sikaDavida, begade izinqola lamabhiza, wona leziphathamandla zawo, abantu bakoJuda, labahlali beJerusalema; lalumuzi uzahlalwa kuze kube nininini.
26 Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
Bazakuza-ke bevela emizini yakoJuda, lezindaweni ezizingelezele iJerusalema, lelizweni lakoBhenjamini, legcekeni, lezintabeni, lasezansi, beletha umnikelo wokutshiswa, lomhlatshelo, lomnikelo wokudla, lenhlaka, beletha umhlatshelo wokubonga, endlini yeNkosi.
27 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”
Kodwa uba lingangilaleli, ukwenza usuku lwesabatha lube ngcwele, ukuthi lingathwali mthwalo nxa lingena ngamasango eJerusalema ngosuku lwesabatha, khona ngizaphemba umlilo emasangweni ayo, ozaqothula izigodlo zeJerusalema, ongayikucitshwa.

< Jeremiah 17 >